A ti yí àwọn orúkọ kan padà nínú àpilẹ̀kọ yìí . Kì í ṣe ti ènìyàn tí ń rìn àní láti darí àwọn ìṣísẹ̀ ara rẹ̀ . ” Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló tẹ̀ ẹ́ jáde , àmọ́ wọn ò tẹ̀ ẹ́ jáde mọ́ . “ Gbogbo ayé wà lábẹ́ agbára ẹni burúkú náà . ” Jù bẹ́ẹ̀ lọ , ẹ má pe ẹnikẹ́ni ní baba yín lórí ilẹ̀ ayé , nítorí ọ̀kan ni Baba yín , Ẹni ti ọ̀run . Èmi yóò ṣe olùrànlọ́wọ́ kan fún un , gẹ́gẹ́ bí àṣekún rẹ̀ . ” ( Wo abẹ́ Ẹ̀KỌ́ BÍBÉLÌ > OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ ) Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà ni orúkọ Ọlọ́run . © 2016 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania Ó jẹ́ ara iṣẹ́ ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kárí ayé tá à ń fi ọrẹ àtinúwá tì lẹ́yìn . Tó o bá fẹ́ ṣètọrẹ , jọ̀wọ́ lọ sí ìkànnì wa www.jw.org . Bá ò bá fi hàn pé ó yàtọ̀ , inú Ìwé Mímọ́ ní Ìtumọ̀ Ayé Tuntun , la ti mú gbogbo ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a lò . “ Àníyàn ṣíṣe nínú ọkàn - àyà ènìyàn ni yóò mú un tẹ̀ ba , ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere ní ń mú un yọ̀ . ” Dájúdájú , èmi yóò fi okun fún ọ . © 2017 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania “ Àwọn olódodo ni yóò ni ilẹ̀ ayé , wọn yóò sì máa gbé títí láé lórí rẹ̀ . ” ​ — Sáàmù 37 : 29 . © 2018 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania ( b ) Àwọn ìbéèrè wo ni a óò gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? ( b ) Kí la óò jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé e ? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ , wò ó bóyá o lè dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e wọ̀nyí : Kí ni a óò gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Gẹ́gẹ́ bí ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ náà , “ ìwéwèé onínúure , ” irú àwọn ọrẹ báwọ̀nyí ń béèrè fún àwọn ìwéwèé díẹ̀ lọ́dọ̀ ẹni tí ó ń ṣètọrẹ . Ẹ kò lè sìnrú fún Ọlọ́run àti fún Ọrọ̀ . ” Jésù sọ pé : “ Kò sí ènìyàn kankan tí ó lè wá sọ́dọ̀ mi láìjẹ́ pé Baba , tí ó rán mi , fà á . ” Ṣùgbọ́n kí ẹni tí ó tóbi jù lọ láàárín yín jẹ́ òjíṣẹ́ yín . Kí ni a óò jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la fẹ́ gbé yẹ̀ wò ? Ìtìlẹ́yìn àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin mi nípa tẹ̀mí sì ti fún mi ní ìtùnú tó pọ̀ . Tó o bá wà lára wọn , a gbóṣùbà fún ọ . Nítorí mo gbà gbọ́ dájú pé kì í ṣe ikú tàbí ìyè tàbí àwọn áńgẹ́lì tàbí àwọn ìjọba tàbí àwọn ohun tí ó wà níhìn - ín nísinsìnyí tàbí àwọn ohun tí ń bọ̀ tàbí àwọn agbára tàbí ibi gíga tàbí ibi jíjìn tàbí ìṣẹ̀dá èyíkéyìí mìíràn ni yóò lè yà wá kúrò nínú ìfẹ́ Ọlọ́run tí ó wà nínú Kristi Jésù Olúwa wa . ” Ìwọ kì yóò jẹ́ kí ẹni ìdúróṣinṣin rẹ rí kòtò . ” ( b ) Kí la ó jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Bọ́ sínú ìdùnnú ọ̀gá rẹ . ” mo wà pẹ̀lú yín ní gbogbo àwọn ọjọ́ títí dé ìparí ètò àwọn nǹkan . ” ( b ) Kí la máa gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Ṣùgbọ́n a ṣí àkájọ ìwé mìíràn sílẹ̀ ; àkájọ ìwé ìyè ni . □ Kí ló ń ṣẹlẹ̀ sáwọn èèyàn tó kú ? Àwọn ìbéèrè wo la máa dáhùn nínú àpilẹ̀kọ́ tó tẹ̀ lé èyí ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wò la fẹ́ gbé yẹ̀ wò báyìí ? Kí la máa sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí ? Èyí ni àṣẹ títóbi jù lọ àti èkíní . ” Jésù sọ pé : “ Kí ìwọ nífẹ̀ẹ́ aládùúgbò rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ . ” ( Ka Mátíù 24 : 37 - 39 . ) A ní láti ṣiṣẹ́ lórí àdúrà tá a gbà . ( b ) Kí la máa gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí ? ( Ka 2 Tímótì 3 : 1 - 5 , 13 . ) ( Ka Sáàmù 40 : 8 - 10 . ) ( b ) Kí ni ìpinnu rẹ báyìí ? ( Ka Sáàmù 19 : 7 - 11 . ) ( Ka Éfésù 5 : 15 , 16 . ) Ẹ̀mí tìkára rẹ̀ ń jẹ́rìí pẹ̀lú ẹ̀mí wa pé àwa jẹ́ ọmọ Ọlọ́run . ” ( Ka 1 Kọ́ríńtì 10 : 13 . ) ( Ka 2 Kíróníkà 34 : 1 - 3 . ) • Kí nìdí tí Ọlọ́run fi dá ayé yìí ? ( Ka 1 Tímótì 6 : 17 - 19 . ) ( Ka Jákọ́bù 1 : 5 - 8 . ) ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? ( Ka 2 Kọ́ríńtì 5 : 14 , 15 . ) ( Ka Róòmù 13 : 1 , 2 . ) ( Ka 1 Kọ́ríńtì 2 : 10 . ) ( Ka 1 Kọ́ríńtì 6 : 9 - 11 . ) ( Ka 2 Kọ́ríńtì 13 : 5 . ) ( Ka 1 Kọ́ríńtì 15 : 58 . ) Dọ́káàsì “ pọ̀ gidigidi nínú àwọn iṣẹ́ rere àti àwọn ẹ̀bùn àánú . ” Kí la máa gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ yìí , kí sì nìdí ? ( Ka Òwe 3 : 5 , 6 . ) ( Ka Hébérù 11 : 24 - 27 . ) “ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè , ó sì ń sa agbára . ” — HÉB . Àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí fi Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wé dígí tí èèyàn lè fi wo ara rẹ̀ lọ́nà tí Jèhófà ń gbà wò ó . Mo bẹ̀rẹ̀ sí í bi ara mi pé , ṣé ohun tí mò ń rí pé mo jẹ́ yàtọ̀ sí nǹkan tí Jèhófà rí ni ? Mi ò kọ́kọ́ fara mọ́ òye tuntun tí mo ní nípa àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí . Èrò mi ṣì ni pé , Jèhófà kò lè nífẹ̀ẹ́ mi . Mo sì ń ṣiyè méjì pé , Jèhófà kò lè nífẹ̀ẹ́ mi , àmọ́ mo bẹ̀rẹ̀ sí í ronú lórí ẹbọ ìràpadà Jésù . Ó wá yé mi pé , ó ti pẹ́ gan - an tí Jèhófà ti ń ṣe sùúrù fún mi , tó ń fi ìfẹ́ hàn sí mi ní ọ̀pọ̀ ọ̀nà . Ńṣe ló dà bíi pé , mo ń sọ fún Jèhófà pé ìràpadà náà kò wúlò fún mi . Ṣó o ti fara balẹ̀ ka àwọn Ilé Ìṣọ́ tó jáde lẹ́nu àìpẹ́ yìí ? ( Ka 2 Kọ́ríńtì 1 : 3 , 4 . ) ( Ka Títù 2 : 3 - 5 . ) ( Ka Róòmù 7 : 21 - 23 . ) ( Ka Aísáyà 63 : 11 - 14 . ) ( Ka Sáàmù 1 : 1 - 3 . ) ( Ka Róòmù 7 : 21 - 25 . ) ( Ka 2 Pétérù 2 : 5 . ) ( Ka Aísáyà 48 : 17 , 18 . ) ( Ka Éfésù 4 : 1 - 3 . ) ( Ka Hébérù 13 : 7 , 17 . ) Àmọ́ , àjọ náà á dá owó náà pa dà bí ẹni tó ni ín bá béèrè fún un . Owó Ìbánigbófò : A lè kọ orúkọ àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò gẹ́gẹ́ bí ẹni tí yóò gba owó ìbánigbófò ẹ̀mí tàbí owó ìfẹ̀yìntì ẹni lẹ́nu iṣẹ́ . Ìpín Ìdókòwò , Ẹ̀tọ́ Orí Owó Ìdókòwò àti Ti Ètò Ẹ̀yáwó : A lè fi ẹ̀tọ́ ìpín ìdókòwò , ẹ̀tọ́ orí owó ìdókòwò àti ti ẹ̀yáwó ta àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò lọ́rẹ . ( Ka Hébérù 11 : 17 - 19 . ) Nígbà míì , Bíbélì máa ń lo òkè láti ṣàpẹẹrẹ àwọn ìjọba tàbí ìṣàkóso . Ẹ̀yin baba , ẹ má ṣe máa dá àwọn ọmọ yín lágara , kí wọ́n má bàa soríkodò . ” Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i , ka orí 3 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan - an ? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é ( Ka 2 Tímótì 1 : 7 . ) Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i , ka orí 8 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan - an ? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é ( Ka 1 Tẹsalóníkà 5 : 1 - 6 . ) Kí ìfẹ́ rẹ ṣẹ , gẹ́gẹ́ bí ti ọ̀run , lórí ilẹ̀ ayé pẹ̀lú . ” ( Ka Lúùkù 21 : 1 - 4 . ) ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Jùdíà bẹ̀rẹ̀ sí sá lọ sí àwọn òkè ńlá , kí àwọn tí wọ́n sì wà ní àárín rẹ̀ fi ibẹ̀ sílẹ̀ , kí àwọn tí wọ́n sì wà ní àwọn ibi ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ . ” Kí la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Èmi tìkára mi , Jèhófà , yóò mú un yára kánkán ní àkókò rẹ̀ . ” ( Ka Lúùkù 10 : 29 - 37 . ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Ṣùgbọ́n ní ti igi ìmọ̀ rere àti búburú , ìwọ kò gbọ́dọ̀ jẹ nínú rẹ̀ , nítorí ọjọ́ tí ìwọ bá jẹ nínú rẹ̀ , dájúdájú , ìwọ yóò kú . ” ( Ka Ìṣípayá 14 : 6 , 7 . ) ( Ka 1 Tẹsalóníkà 2 : 13 . ) Yóò sì fi òdodo ṣe ìdájọ́ àwọn ẹni rírẹlẹ̀ , yóò sì fi ìdúróṣánṣán fúnni ní ìbáwí àfitọ́nisọ́nà nítorí àwọn ọlọ́kàn tútù ilẹ̀ ayé . ” Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i , ka orí 10 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan - an ? , Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é “ Ìgbàgbọ́ ni ìfojúsọ́nà tí ó dáni lójú nípa àwọn ohun tí a ń retí . ” — HÉB . Jésù sọ pé : “ Ibi tí ìṣúra rẹ bá wà , ibẹ̀ ni ọkàn - àyà rẹ yóò wà pẹ̀lú . ” “ Aláyọ̀ ni àwọn ènìyàn tí Jèhófà jẹ́ Ọlọ́run wọn ! ” ​ — SM . ( Ka Jákọ́bù 5 : 14 - 16 . ) ( b ) Kí la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Pọ́ọ̀lù ṣàlàyé bí ọ̀rọ̀ yìí ṣe rí lára rẹ̀ , ó ní : “ Èmi jẹ́ ẹlẹ́ran ara , tí a ti tà sábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ . ( Ka Hébérù 10 : 24 , 25 . ) ( Ka 2 Kọ́ríńtì 8 : 13 - 15 . ) Nóà bá Ọlọ́run tòótọ́ rìn . ” ​ — Jẹ́n . Ìwé Òwe 14 : 15 sọ pé : “ Ẹnikẹ́ni tí ó jẹ́ aláìní ìrírí ń ní ìgbàgbọ́ nínú gbogbo ọ̀rọ̀ , ṣùgbọ́n afọgbọ́nhùwà máa ń ronú nípa àwọn ìṣísẹ̀ ara rẹ̀ . ” Nítorí àjàgà mi jẹ́ ti inú rere , ẹrù mi sì fúyẹ́ . ” Ẹ máa bá a lọ ní fífaradà á fún ara yín lẹ́nì kìíní - kejì , kí ẹ sì máa dárí ji ara yín fàlàlà lẹ́nì kìíní - kejì bí ẹnikẹ́ni bá ní ìdí fún ẹjọ́ lòdì sí ẹlòmíràn . Àní gẹ́gẹ́ bí Jèhófà ti dárí jì yín ní fàlàlà , bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin pẹ̀lú máa ṣe . Wàyí o , bí ojú ọ̀tún rẹ yẹn bá ń mú ọ kọsẹ̀ , yọ ọ́ jáde , kí o sì sọ ọ́ nù kúrò lọ́dọ̀ rẹ . ” Èmi yóò fi ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi dì ọ́ mú ṣinṣin ní ti tòótọ́ . ” KÍ LÀWỌN NǸKAN MÍÌ TÍ BÍBÉLÌ SỌ ? Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì gan - an pé ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará ? Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi kọ lẹ́tà sí àwọn Hébérù tó jẹ́ Kristẹni ? ( Ka Hébérù 10 : 36 - 39 . ) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká mọ ohun tó wà nínú ìwé Hébérù ? Kí ni ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wa ti ọdún 2016 , kí sì nìdí tó fi bá a mu wẹ́kú ? Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wa ti ọdún 2016 : “ Ẹ jẹ́ kí ìfẹ́ ará tí ẹ ní máa bá a lọ . ” — Hébérù 13 : 1 Ta ni àwa Kristẹni tòótọ́ máa ń fìfẹ́ ará hàn sí , kí sì nìdí ? ( a ) Kí nìdí tó ṣe pàtàkì jù lọ tó fi yẹ ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará ? ( b ) Sọ ìdí míì tó fi ṣe pàtàkì pé ká túbọ̀ máa nífẹ̀ẹ́ ara wa . Kí la gbọ́dọ̀ ṣe nísinsìnyí kí ìpọ́njú ńlá tó bẹ̀rẹ̀ ? ( a ) Àwọn nǹkan wo ló ń ṣẹlẹ̀ lónìí tó fi hàn pé ó yẹ ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará wa ? ( b ) Sọ ìrírí bí àwọn èèyàn Jèhófà ṣe fìfẹ́ hàn síra wọn ? Báwo la ṣe lè máa fi ‘ àwọn tí ń bẹ lẹ́wọ̀n sọ́kàn ’ ? ‘ Ẹ máa fi àwọn tí ń bẹ lẹ́wọ̀n sọ́kàn . ’ “ Kí ìgbéyàwó ní ọlá láàárín gbogbo ènìyàn . ” Báwo ni ìtẹ́lọ́rùn ṣe lè mú ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará ? Ẹ “ ní ìtẹ́lọ́rùn pẹ̀lú àwọn nǹkan ìsinsìnyí . ” Tá a bá jẹ́ “ onígboyà , ” báwo nìyẹn á ṣe mú ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará wa ? Kí ló lè jẹ́ ká túbọ̀ máa fìfẹ́ ará hàn sáwọn alàgbà ? “ Ẹ máa rántí àwọn tí ń mú ipò iwájú láàárín yín . ” Báwo la ṣe lè túbọ̀ máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará wa ? Kí ni ìfẹ́ tí Kristi ní sí wa ń mú ká ṣe ? Báwo ni ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní sí wa ṣe ń mú ká nífẹ̀ẹ́ àwọn ará wa ? Torí pé Ọlọ́run ń dárí jì wá , báwo nìyẹn ṣe máa mú ká máa dárí ji àwọn ará wa ? 1 , 2 . ( a ) Kí ni ‘ ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ aláìṣeé - ṣàpèjúwe ’ ti Ọlọ́run ní nínú ? ( Ka 2 Kọ́ríńtì 1 : 20 . ) 3 , 4 . ( a ) Báwo ló ṣe máa ń rí lára rẹ tí ẹnì kan bá fún ẹ lẹ́bùn ? ( b ) Ṣàpèjúwe bí ẹ̀bùn pàtàkì tí ẹnì kan fún ẹ ṣe lè yí ìgbésí ayé rẹ pa dà . Báwo ni ẹ̀bùn ìràpadà tí Ọlọ́run fún wa ṣe ṣeyebíye ju ẹ̀bùn èyíkéyìí lọ ? ( a ) Èwo lò ń fojú sọ́nà fún lára àwọn ìbùkún tá a máa rí látinú ẹ̀bùn tí Jèhófà fún wa ? ( b ) Sọ nǹkan mẹ́ta tí ẹ̀bùn Ọlọ́run máa mú ká ṣe . Báwo ló ṣe yẹ kí ìfẹ́ tí Kristi ní sí wa rí lára wa , kí ló sì yẹ kí ìyẹn mú ká ṣe ? Ẹ̀wẹ̀ , ẹni tí ó nífẹ̀ẹ́ mi ni Baba mi yóò nífẹ̀ẹ́ , ṣe ni èmi yóò sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ , èmi yóò sì fi ara mi hàn fún un kedere . ” — Jòhánù 14 : 21 ; 1 Jòhánù 5 : 3 . Àwọn ìbéèrè wo ló yẹ ká bi ara wa lásìkò Ìrántí Ikú Kristi ti ọdún yìí , kí sì ni ìdáhùn sí àwọn ìbéèrè náà máa mú ká ṣe ? ( Ka 1 Tímótì 2 : 9 , 10 . ) ( b ) Báwo ni ìfẹ́ tá a ní ṣe máa mú ká ran àwọn míì lọ́wọ́ nínú ìjọ ? Kí ni ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní sí wa tún máa mú ká ṣe ? Àpẹẹrẹ wo ni Jésù fi lélẹ̀ fún wa nípa bó ṣe yẹ ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn èèyàn ? Ṣé o lè ran arákùnrin tàbí arábìnrin kan tó ti dàgbà lọ́wọ́ lóde ẹ̀rí ? Àwọn ọ̀nà wo lo lè gbà fìfẹ́ hàn sáwọn ará ? ( Ka Lúùkù 14 : 12 - 14 . ) 16 , 17 . ( a ) Kí la rí kọ́ nínú àpèjúwe tí Jésù ṣe nípa ọba kan àti àwọn ẹrú rẹ̀ ? ( b ) Lẹ́yìn tó o ti ronú lórí àpèjúwe Jésù , kí lo pinnu láti ṣe ? Báwo ni ìfẹ́ tí arábìnrin kan ní sí Ọlọ́run ṣe mú kó fara da ìwà àìpé arábìnrin míì ? Màá fẹ́ mọ̀ ọ́n nígbà tó bá di ẹni pípé . ” Kí ni ‘ ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ aláìṣeé - ṣàpèjúwe ’ tí Ọlọ́run fún wa máa mú kó o ṣe ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 18 ) A ti yí àwọn orúkọ kan pa dà nínú àpilẹ̀kọ yìí . Kí ló mú kí ọjọ́ àjọyọ̀ Pẹ́ńtíkọ́sì ṣàrà ọ̀tọ̀ , báwo sì làwọn ohun tó ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ náà ṣe mú àwọn àsọtẹ́lẹ̀ inú Ìwé Mímọ́ ṣẹ ? ( a ) Kí nìdí tó fi yẹ ká ka ohun tó ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ àjọyọ̀ Pẹ́ńtíkọ́sì sí pàtàkì ? ( b ) Ìṣẹ̀lẹ̀ pàtàkì míì tó wáyé ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn wo ló ṣeé ṣe kó bọ́ sí ọjọ́ kan náà tí wọ́n ń ṣe àjọyọ̀ Pẹ́ńtíkọ́sì ? Báwo la ṣe mọ̀ pé kì í ṣe ọ̀nà kan náà ni Jèhófà gbà fẹ̀mí yan gbogbo àwọn ẹni àmì òróró ? Kí ni Jèhófà fún gbogbo àwọn ẹni àmì òróró , kí lèyí sì mú kó dá wọn lójú ? Kí ni olúkúlùkù ẹni àmì òróró gbọ́dọ̀ ṣe kí wọ́n tó lè gba èrè wọn ní ọ̀run ? Pétérù ṣàlàyé rẹ̀ lọ́nà yìí , ó ní : “ Fún ìdí yìí , ẹ̀yin ará , ẹ túbọ̀ máa sa gbogbo ipá yín láti mú pípè àti yíyàn yín dájú fún ara yín ; nítorí bí ẹ bá ń bá a nìṣó ní ṣíṣe nǹkan wọ̀nyí , ẹ kì yóò kùnà lọ́nàkọnà láé . Ní ti tòótọ́ , nípa báyìí ni a ó pèsè ìwọlé fún yín lọ́pọ̀ jaburata sínú ìjọba àìnípẹ̀kun ti Olúwa àti Olùgbàlà wa Jésù Kristi . ” ( b ) Báwo lẹnì kan ṣe máa mọ̀ pé Jèhófà ti yan òun láti lọ sọ́run ? Pọ́ọ̀lù sọ fún wọn pé : “ Ẹ kò gba ẹ̀mí ìsìnrú tí ó tún ń fa ìbẹ̀rù , ṣùgbọ́n ẹ̀yin gba ẹ̀mí ìsọdọmọ , ẹ̀mí tí ń mú kí a ké jáde pé : ‘ Ábà , Baba ! ’ Kí ló lè máa ṣe ẹni àmì òróró kan ní kàyéfì , àmọ́ kí ni kò jẹ́ ṣiyè méjì lé lórí ? Báwo ni ìrònú ẹnì kan ṣe máa ń yí pa dà nígbà tí Ọlọ́run bá fi ẹ̀mí mímọ́ yàn án , kí ló sì fà á ? Nígbà tí Ọlọ́run yàn wọ́n , ó fi ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ yí bí wọ́n ṣe ń ronú pa dà , ó sì tún yí èrè tí wọ́n á máa fojú sọ́nà fún pa dà . Kí ni kò fi hàn pé Ọlọ́run ti fi ẹ̀mí mímọ́ yan ẹnì kan ? Báwo la ṣe mọ̀ pé kì í ṣe gbogbo àwọn tó rí ẹ̀mí mímọ́ gbà ni Ọlọ́run ti yàn láti lọ sọ́run ? 17 , 18 . ( a ) Ìrètí wo ni ọ̀pọ̀ jù lọ lára àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà lónìí ní ? Báwo ni àsọtẹ́lẹ̀ inú Sekaráyà 8 : 23 ṣe ń ní ìmúṣẹ ? 1 , 2 . ( a ) Kí ni Jèhófà sọ pé á máa ṣẹlẹ̀ lákòókò wa yìí ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Kí nìdí tá ò fi lè fọwọ́ sọ̀yà pé ẹnì kan wà lára àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì tàbí kò sí lára wọn ? Ìkìlọ̀ wo ló yẹ káwọn ẹni àmì òróró ronú lé lórí dáadáa , kí sì nìdí ? Kí ni àwọn ẹni àmì òróró kì í retí , kí sì nìdí ? Kí nìdí tó fi yẹ kó o ṣọ́ra nípa ojú tó o fi ń wo àwọn tó ń jẹ búrẹ́dì tó sì ń mu wáìnì níbi Ìrántí Ikú Kristi ? ( Wo àpótí náà , “ Ìfẹ́ ‘ Kì Í Hùwà Lọ́nà Tí Kò Bójú Mu . ’ ” ) Jésù sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé : “ Arákùnrin ni gbogbo yín jẹ́ . ” Báwo lo ṣe lè fi hàn pé o bọ̀wọ̀ fún àwọn ẹni àmì òróró ? Tí a kì í bá “ kan sáárá ” sáwọn ẹni àmì òróró , báwo nìyẹn ṣe lè dáàbò bò wá ? Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa da ara wa láàmú bí àwọn tó ń jẹ búrẹ́dì tí wọ́n sì ń mu wáìnì níbi Ìrántí Ikú Kristi bá ń pọ̀ sí i ? “ Jèhófà mọ àwọn tí í ṣe tirẹ̀ . ” Kí ni Bíbélì sọ nípa iye àwọn ẹni àmì òróró tó máa wà láyé nígbà tí ìpọ́njú ńlá bá bẹ̀rẹ̀ ? Kí ló yẹ ká mọ̀ nípa àwọn ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì tí Jèhófà fẹ̀mí yàn ? Ìwọ̀nba díẹ̀ lára àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró tó wà ní ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní ni Jèhófà lò láti kọ Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì . ń mú ká túbọ̀ sún mọ́ Ọlọ́run àtàwọn ará wa ? Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Jèhófà ni Ẹni Gíga Jù Lọ , kí ló ní kí àwọn míì wá bá òun ṣe ? Iṣẹ́ pàtàkì wo ni Jèhófà ní kí Jésù bá òun ṣe ? Kí ni Jèhófà ní kí Ádámù ṣe , kí sì nìdí ? Fojú inú wo bí inú Ádámù á ṣe dùn tó bó ti ń ṣe iṣẹ́ yìí . Báwo làwọn míì ṣe bá Jèhófà ṣiṣẹ́ láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ ? ( a ) Iṣẹ́ wo la láǹfààní láti bá Jèhófà ṣe ? Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé : “ Ní bíbá a ṣiṣẹ́ pọ̀ , àwa ń pàrọwà fún yín pẹ̀lú pé kí ẹ má ṣe tẹ́wọ́ gba inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run kí ẹ sì tàsé ète rẹ̀ . ” Báwo ni àkọ́bí Ọmọ Ọlọ́run ṣe ṣàpèjúwe bí inú rẹ̀ ṣe dùn tó torí ó ń ṣiṣẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Bàbá rẹ̀ ? Kí nìdí tí iṣẹ́ ìwàásù fi ń fún wa láyọ̀ ? Kí làwọn kan sọ nípa béèyàn ṣe máa ń láyọ̀ tó bá ń bá Jèhófà ṣiṣẹ́ ? Arákùnrin Franco tóun náà ń sìn lórílẹ̀ - èdè Ítálì sọ ohun tó jọ èyí , ó ní : “ Jèhófà ń rán wa létí lójoojúmọ́ nípasẹ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ àtàwọn nǹkan míì tó fún wa pé òun nífẹ̀ẹ́ wa àti pé òun mọyì gbogbo ohun tá à ń ṣe fún òun , bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ohun tá à ń ṣe yìí lè má fi bẹ́ẹ̀ já mọ́ nǹkan kan lójú tiwa . Ìdí nìyí tí bí mo ṣe ń bá Ọlọ́run ṣiṣẹ́ fi ń múnú mi dùn gan - an , tó sì tún ń jẹ́ kí ìgbésí ayé mi nítumọ̀ . ” Àjọṣe wo ló wà láàárín Jèhófà àti Jésù , kí sì nìdí ? Kí nìdí tí iṣẹ́ ìwàásù fi ń mú ká túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà àtàwọn ará ? Jésù sọ nínú àdúrà rẹ̀ pé : “ Kí wọ́n lè jẹ́ ọ̀kan gan - an gẹ́gẹ́ bí àwa ti jẹ́ . ” Àá máa rí ìdí tó fi bọ́gbọ́n mu pé ká gbẹ́kẹ̀ lé e ká sì máa tẹ̀ lé àwọn ìtọ́ni tó ń fún wa . Kí nìdí tá a fi máa túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà àtàwọn ará wa nínú ayé tuntun ju ti ìsinsìnyí lọ ? Kí ni arákùnrin kan tó ń gbé nílẹ̀ Ọsirélíà sọ nípa iṣẹ́ ìwàásù ? Arákùnrin Joel tó ń gbé nílẹ̀ Ọsirélíà sọ pé : “ Iṣẹ́ ìwàásù ti jẹ́ kí n túbọ̀ wà lójúfò . Ó ń jẹ́ kí n mọ onírúurú ìṣòro tó ń bá àwọn èèyàn fínra , ó sì ń jẹ́ kí n máa rántí àwọn àǹfààní tí mo ti rí bí mo ṣe ń fi àwọn ìlànà Bíbélì sílò nínú ìgbésí ayé mi . Iṣẹ́ ìwàásù ń mú kí n túbọ̀ lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ , ó ti jẹ́ kí n gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà kí n sì fọkàn tán àwọn arákùnrin àti arábìnrin mi . ” Kí ni bá ò ṣe jáwọ́ wíwàásù fi hàn ? Ọjọ́ mélòó lo máa ṣèyẹn dà ? Báwo ni iṣẹ́ ìwàásù tá à ń ṣe ṣe ń mú ohun tí Ọlọ́run ní lọ́kàn fáráyé ṣẹ ? Báwo ni iṣẹ́ ìwàásù ṣe ń mú ká pa àṣẹ Ọlọ́run mọ́ ? Èkejì , tí ó dà bí rẹ̀ , nìyí , ‘ Kí ìwọ nífẹ̀ẹ́ aládùúgbò rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ . ’ ” Ojú wo lo fi ń wo àǹfààní tó o ní láti máa wàásù ìhìn rere ? Ọlọ́run lè dá ṣe iṣẹ́ yìí fúnra rẹ̀ , àmọ́ torí pé ó nífẹ̀ẹ́ wa , ó pè wá sí iṣẹ́ ọ̀hún . Iṣẹ́ yìí ń fún wa láyọ̀ , ó ń dáàbò bò wá , ó sì ń jẹ́ ká túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà àtàwọn ará wa Ó ń fi ìhìn rere tu àwọn èèyàn nínú pé , láìpẹ́ , Ìjọba Ọlọ́run tó ti ń ṣàkóso ní ọ̀run , yóò fòpin sí gbogbo ìwà ibi , á sì sọ ilẹ̀ ayé di Párádísè . Ìwé ìròyìn yìí ń gbani níyànjú láti nígbàgbọ́ nínú Jésù Kristi tó kú ká lè ní ìyè àìnípẹ̀kun . Jésù sì ti ń ṣàkóso báyìí gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run . Láti ọdún 1879 la ti ń tẹ ìwé ìròyìn yìí déédéé , kì í sì í dá sí ọ̀ràn ìṣèlú . Orí Bíbélì ni gbogbo ohun tó ń sọ dá lé . Mọ̀lẹ́bí tó sún mọ́ ìdílé Bebe bí iṣan ọrùn ló sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Bebe . Àmọ́ kàkà kí ọ̀rọ̀ náà tù ú nínú , ńṣe ló tún dá kún ọgbẹ́ ọkàn rẹ̀ torí pé òun àti bàbá rẹ̀ sún mọ́ ara wọn gan - an . Gbogbo ìgbà ni Bebe máa ń sọ lọ́kàn ara rẹ̀ pé : “ Ikú bàbá mi yìí ò dáa . ” Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún , ó kọ ìṣẹ̀lẹ̀ yìí sínú ìwé kan , èyí sì fi hàn pé ọgbẹ́ ọkàn rẹ̀ kò tíì sàn . Bíi ti Bebe , ó máa ń pẹ́ kéèyàn tó lè gbé ìbànújẹ́ tí ikú ń fà kúrò lára , pàápàá tó bá jẹ́ pé ẹni tó sún mọ́ wa pẹ́kípẹ́kí ló kú . Bíbélì tiẹ̀ dìídì pé ikú ní “ ọ̀tá ìkẹyìn . ” Ìgbà téèyàn kò ronú rẹ̀ ni ikú máa ń ṣọṣẹ́ , kò sì sí ohun tá a lè ṣe tí ikú bá dé . Ó máa ń dà bíi pé àwọn tá a fẹ́ràn jù ló ń pa . Kò sì sẹ́ni tó bọ́ lọ́wọ́ ikú . Torí náà , ó lè má rọrùn láti gbé e kúrò lọ́kàn nígbà tẹ́ni tá a fẹ́ràn bá kú . Ó ṣeé ṣe kó o máa ronú pé : ‘ Báwo ló ṣe máa ń pẹ́ tó kéèyàn tó lè gbé ìbànújẹ́ náà kúrò lọ́kàn ? Báwo ni mo ṣe lè tu ẹni téèyàn rẹ̀ kú nínú ? Ṣé ìrètí kankan wà fún àwọn èèyàn wa tó ti kú ? ’ Ṣé àìsàn ti dá ẹ gúnlẹ̀ rí ? Bí àpẹẹrẹ , wo bí Ábúráhámù ṣe hùwà nígbà tí ìyàwó rẹ̀ kú . Bíbélì sọ pé : “ Ábúráhámù sì wọlé láti pohùn réré ẹkún Sárà àti láti sunkún lórí rẹ̀ . ” Ẹsẹ Bíbélì yìí fi hàn pé ó pẹ́ díẹ̀ kí ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ tó fúyẹ́ . “ Ọ̀pọ̀ ọjọ́ ” ni ó fi ṣọ̀fọ̀ , kò sì sí mọ̀lẹ́bí rẹ̀ kankan tó lè tù ú nínú . Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún , ikú ọmọkùnrin rẹ̀ Jósẹ́fù ṣì wúwo lọ́kàn rẹ̀ . — Jẹ́nẹ́sísì 23 : 2 ; 37 : 34 , 35 ; 42 : 36 ; 45 : 28 . “ Robert ọkọ mi kú ní July 9 , 2008 . Ó ti lé lọ́dún mẹ́fà báyìí tí ọkọ mi ti kú , síbẹ̀ ọgbẹ́ ọkàn yẹn kò tíì kúrò lọ́kàn mi . Mi ò sì rò pé ìbànújẹ́ náà lè tán lára mi . ” — Gail , ẹni ọgọ́ta [ 60 ] ọdún . “ Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti pé ọdún méjìdínlógún [ 18 ] tí ìyàwó mi ti kú , mo ṣì ń ṣàárò rẹ̀ , mi ò tíì gbé àdánù náà kúrò lára mi . Nígbàkigbà tí mo bá rí ohun tó rẹwà , mo máa ń rántí ìyàwó mi , mo sì máa ń ronú bí inú rẹ̀ ì bá ṣe dùn tó ká sọ pé òun náà rí ohun tí mo rí . ” — Etienne , ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin [ 84 ] . Òótọ́ kan ni pé ó máa ń dùn wá wọra tí a bá pàdánù ẹnì kan , kì í sì í kúrò lọ́kàn wa bọ̀rọ̀ . Bí ẹnì kọ̀ọ̀kan sì ṣe máa ń fi ẹ̀dùn ọkàn hàn yàtọ̀ síra , torí náà kò bọ́gbọ́n mu ká máa ṣàríwísí àwọn míì torí bí wọ́n ṣe ṣe nígbà tí èèyàn wọn kú . Lẹ́sẹ̀ kan náà , kò yẹ ká máa dá ara wa lẹ́bi tá a bá bara jẹ́ gan - an nígbà téèyàn wa bá kú . Bí a ṣe sọ nínú àpilẹ̀kọ tí àkòrí rẹ̀ jẹ́ “ Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn ” nínú ìwé ìròyìn yìí , lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Ísákì ṣì ń ṣọ̀fọ̀ ikú Sárà ìyá rẹ̀ . — Jẹ́nẹ́sísì 24 : 67 . Bí àpẹẹrẹ , àwọn kan á sọ pé o kò gbọ́dọ̀ sunkún tàbí kó o bara jẹ́ lọ́nàkọnà . Àwọ́n míì á sọ pé àfi kó o sun ẹkún àsun - ùn - dákẹ́ kó lè hàn pé ó dùn ẹ́ . Àmọ́ ṣá o , Bíbélì sọ bá a ṣe lè fara da ọgbẹ́ ọkàn , ìwádìí táwọn èèyàn sì ṣe lẹ́nu àìpẹ́ yìí fi hàn pé òótọ́ ni Bíbélì sọ . Láwọn ilẹ̀ kan , wọ́n gbà pé ọ̀lẹ ọkùnrin ló máa ń sunkún . Àmọ́ , ṣé ó yẹ kójú máa ti èèyàn láti sunkún , kódà tó bá jẹ́ ní gbangba ? Àwọn onímọ̀ nípa ọpọlọ gbà pé sísunkún jẹ́ ọ̀nà kan téèyàn ń gbà fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn . Tó o bá sì fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ hàn , ó máa jẹ́ kó o lè gbé ọ̀ràn náà kúrò lọ́kàn , láìka bí ikú ẹni náà ṣe dùn ẹ́ tó . Tá a bá pa ẹ̀dùn ọkàn náà mọ́ra , ńṣe ló máa dá kún ìbànújẹ́ náà . Bíbélì kò fara mọ́ èrò àwọn kan pé kò dáa kéèyàn sunkún tàbí pé ọ̀lẹ ọkùnrin ló máa ń sunkún . Nígbà tí Lásárù ọ̀rẹ́ rẹ̀ kú , Jésù sunkún ní gbangba , bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lágbára láti jí i dìde . — Jòhánù 11 : 33 - 35 . Ọ̀pọ̀ nǹkan ló lè mú kí ẹni tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ máa kanra . Irú bí ìgbà tí ẹnì kan tí wọ́n bọ̀wọ̀ fún bá sọ ọ̀rọ̀ láìronú tàbí sọ ohun tí kì í ṣe òótọ́ . Ọkùnrin kan lórílẹ̀ èdè South Africa tó ń jẹ́ Mike sọ pé : “ Ọmọ ọdún mẹ́rìnlá péré ni mí nígbà tí bàbá mi kú . Lọ́jọ́ ìsìnkú , òjíṣẹ́ ìjọ Anglican kan sọ pé , Ọlọ́run nílò àwọn èèyàn rere , ó sì máa ń yára mú wọn lọ . * Èyí múnú bí mi gan - an torí pé a ṣì nílò ìrànlọ́wọ́ bàbá mi . Ẹni tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ náà lè máa sọ léraléra pé , ‘ Ká ní mo ti ṣe báyìí ni , ì bá máà kú . ’ Tó o bá ń kanra tàbí tí ò ń dá ara rẹ lẹ́bi , ó máa dáa kó o má ṣe pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ra . Kàkà bẹ́ẹ̀ , ńṣe ni kó o fọ̀rọ̀ náà lọ ọ̀rẹ́ rẹ tó máa fara balẹ̀ gbọ́ ẹ tó sì máa fi ẹ́ lọ́kàn balẹ̀ pé ọ̀pọ̀ àwọn tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ ló máa ń ronú bẹ́ẹ̀ . Bíbélì sọ pé : “ Alábàákẹ́gbẹ́ tòótọ́ a máa nífẹ̀ẹ́ ẹni ní gbogbo ìgbà , ó sì jẹ́ arákùnrin tí a bí fún ìgbà tí wàhálà bá wà . ” — Òwe 17 : 17 . Ọ̀rẹ́ tó dáa jù tí ẹni tó ń ṣọ̀fọ̀ lè ní ni Ẹlẹ́dàá wa , ìyẹn Jèhófà Ọlọ́run . O lè tú ọkàn rẹ jáde sí Ọlọ́run nínú àdúrà nítorí pé ‘ ó bìkítà fún ẹ . ’ Bákan náà , Ọlọ́run ṣèlérí pé gbogbo àwọn tó bá gbàdúrà sí òun fún ìrànlọ́wọ́ máa ní “ àlàáfíà Ọlọ́run tí ó ta gbogbo ìrònú yọ . ” Ọlọ́run tún máa ń ràn wá lọ́wọ́ kí ọkàn wa lè fúyẹ́ nípasẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ ìtùnú tó wà nínú Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ . Irú àwọn ẹsẹ Bíbélì báyìí lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ pàápàá tó o bá dá wà lọ́wọ́ alẹ́ , tí o kò sì rí oorun sùn . — Aísáyà 57 : 15 . Ẹni ogójì [ 40 ] ọdún ni ọkùnrin kan tá a máa pe orúkọ rẹ̀ ní Jack . Ó ní : “ Tí mo bá ti gbàdúrà sí Jèhófà , kì í ṣe mí bíi pé mo dá wà mọ́ . Nígbà míì tí oorun bá dá lójú mi láàárín òru , mo máa ń ka àwọn ọ̀rọ̀ ìtùnú nínú Bíbélì , màá sì ronú lé wọn lórí . Lẹ́yìn náà , màá wá sọ ẹdùn ọkàn mi fún Ọlọ́run , ìyẹn sì máa ń mú kí ọkàn mi tutù pẹ̀sẹ̀ . Ara mi á wá balẹ̀ , èyí sì máa ń jẹ́ kí n rí oorun sùn pa dà . ” Àìsàn kan gbẹ̀mí ìyá ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Vanessa . Àdúrà ló ran òun náà lọ́wọ́ . Ó sọ pé : “ Nígbà tí nǹkan bá le koko , mo máa ń ké pe orúkọ Ọlọ́run , màá sì bú sẹ́kún . Jèhófà máa ń gbọ́ àdúrà mi , ó sì máa ń fún mi lókun tí mo nílò . ” Àwọn tó máa ń gba àwọn tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ nímọ̀ràn sọ pé ó máa ń dáa kí àwọn tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ máa ran àwọn ẹlòmíì lọ́wọ́ tàbí kí wọ́n yọ̀ǹda ara wọn láti ran àwọn aráàlú lọ́wọ́ . Àwọn nǹkan yìí máa jẹ́ kó o láyọ̀ , á sì mú kí ọkàn rẹ fúyẹ́ . Ọ̀pọ̀ Kristẹni tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ ti rí i pé ríran àwọn èèyàn lọ́wọ́ ti mú kí ara túbọ̀ tù wọ́n . — 2 Kọ́ríńtì 1 : 3 , 4 . Ọlọ́run mọ ohun tó ń dùn ẹ́ lọ́kàn . ​ — Sáàmù 55 : 22 ; 1 Pétérù 5 : 7 . Ọlọ́run ṣe tán láti gbọ́ àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ . ​ — Sáàmù 86 : 5 ; 1 Tẹsalóníkà 5 : 17 . Ó wu Ọlọ́run láti tún rí àwọn tó ti kú . ​ — Jóòbù 14 : 13 - 15 . Ọlọ́run ṣe ìlérí pé òun máa jí àwọn òkú dìde . ​ — Aísáyà 26 : 19 ; Jòhánù 5 : 28 , 29 . Ṣé ó ti ṣe ẹ́ rí pé o kò mọ ohun tó o máa sẹ nígbà tí ọ̀fọ̀ ṣẹ ẹnì kan tó sún mọ́ ẹ ? Nígbà míì o lè má mọ ohun tó o máa sọ , kó o wá kúkú dákẹ́ láìṣe ohunkóhun . Àmọ́ , àwọn nǹkan kan wà tó o lè ṣe fún ẹni tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ náà . Lọ́pọ̀ ìgbà , ohun tí àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ nílò kò ju pé kó o wà lọ́dọ̀ wọn , kó o sì kí wọn pé “ Ẹ pẹ̀lẹ́ o , ẹ kú ọ̀rọ̀ èèyàn . ” Láwọn ilẹ̀ kan , gbígbá ẹni náà mọ́ra tàbí kéèyàn rọra fọwọ́ kàn án máa fi hàn pé ò ń bá a kẹ́dùn . Ohun tó wá dáa jù ni pé kó o bá wọn ṣe àwọn iṣẹ́ ilé kan , bóyá àwọn tí wọn ò lè ṣe fúnra wọn lásìkò yẹn . Irú bíi síse oúnjẹ , títọ́jú àwọn ọmọ tàbí kó o bá wọn ṣètò ìsìnkú tí wọ́n bá fẹ́ bẹ́ẹ̀ . Irú àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀ máa ṣe wọ́n láǹfààní ju kéèyàn kàn máa sọ̀rọ̀ ṣáá . Bí àkókò ti ń lọ , o lè sọ̀rọ̀ nípa ẹni tó kú náà , irú bí ìwà rere tẹ́ni náà ní àti àkókò alárinrin tẹ́ ẹ jọ gbádùn . Irú àwọn ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ tiẹ̀ lè mú kí ẹni tí ọ̀fọ̀ ṣẹ̀ náà tújú ká . Bí àpẹẹrẹ , Pam tí ọkọ rẹ̀ tó ń jẹ́ Ian kú lọ́dún mẹ́fà sẹ́yìn sọ pé : “ Àwọn èèyàn sábà máa ń sọ ohun rere tí lan ṣe tí mi ò tiẹ̀ mọ̀ nípa rẹ̀ rárá , èyí sì máa ń múnú mi dùn . ” Àwọn olùṣèwádìí ròyìn pé àwọn èèyàn máa ń rọ́ lọ kí ẹni tí ọ̀fọ̀ ṣẹ gbàrà tí ìṣẹ̀lẹ̀ náà bá wáyé . Torí náà , sapá láti máa kàn sí ẹni tó ń ṣọ̀fọ̀ náà lóòrèkóòrè lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà . * Ọ̀pọ̀ àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ máa ń mọ rírì rẹ̀ táwọn èèyàn bá kàn sí wọn kí ẹdùn ọkàn wọn lè fúyẹ́ . Wo àpẹẹrẹ ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Kaori lórílẹ̀ - èdè Japan . Ìbànújẹ́ dorí rẹ̀ kodò nígbà tí ìyá rẹ̀ kú , tí ẹ̀gbọ́n rẹ̀ náà sì tún kú ní nǹkan bí ọdún kan àti oṣù mẹ́ta lẹ́yìn náà . Àmọ́ , ó rí ìtìlẹyìn látọ̀dọ̀ àwọn ọ̀rẹ́ tó dúró tì í . Ritsuko jẹ́ ọ̀kan lára wọn . Ritsuko dàgbà ju Kaori lọ dáadáa . Ó sọ fún Kaori pé kó jẹ́ káwọn jọ máa ṣọ̀rẹ́ . Mi ò fẹ́ kí ẹnikẹ́ni gba ipò ìyá mi , mi ò tiẹ̀ rò pé ẹnikẹ́ni lè ṣe bí ìyá fún mi . Àmọ́ , torí bí màmá yìí ṣe ń ṣe sí mi , mo wá bẹ̀rẹ̀ sí í sún mọ́ ọn . Ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ la jọ máa ń lọ wàásù , tá a sì jọ máa ń lọ sí ìpàdé Kristẹni . Ó máa ń pè mí pé kí n wá mu tíì lọ́dọ̀ òun , ó máa ń gbé oúnjẹ wá fún mi , ó sì máa ń fi lẹ́tà àti káàdì ránṣẹ́ sí mi . Ìwà rere tí màmá yìí ń hù ní ipa rere lórí mi . ” Lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí , òun àti ọkọ rẹ̀ jẹ́ òjíṣẹ́ tó ń fi ọ̀pọ̀ àkókò wàásù . Kaori sọ pé : “ Màmá yìí kò fọ̀rọ̀ mi ṣeré rárá . Tí mo bá lọ sílé , mó máa ń lọ kí i , mo sì máa ń gbádùn àwọn ọ̀rọ̀ tó ń fúnni ní ìṣírí tó máa ń sọ . ” Ẹlòmíì tó jàǹfààní látọ̀dọ̀ àwọn ọ̀rẹ́ adúrótini ni Poli , tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà lórílẹ̀ - èdè Cyprus . Èèyàn dáadáa ni ọkọ Poli , tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Sozos . Ọwọ́ pàtàkì ló fi mú ojúṣe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí alábòójútó nínú ìjọ . Àmọ́ , kókó kan tó yọ nínú ọpọlọ rẹ̀ ṣekú pa á lẹ́ni ọdún mẹ́tàléláàádọ́ta [ 53 ] . Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í dara pọ̀ mọ́ ọ̀kan lára ìjọ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà níbẹ̀ . Poli sọ pé : “ Àwọn ọ̀rẹ́ wa ní ìjọ tá a ṣẹ̀ṣẹ̀ dé yìí kò mọ ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa tàbí ipò tá a wà . Síbẹ̀ wọ́n máa ń sún mọ́ wa , wọ́n máa ń sọ̀rọ̀ tútù fún wa , wọ́n sì máa ń ràn wá lọ́wọ́ . Ìrànlọ́wọ́ ńlá gbáà ni èyí jẹ́ fún ọmọ mi lákòókò tó nílò bàbá rẹ̀ gan - an yìí . Àwọn tó ń mú ipò iwájú nínú ìjọ kò fọ̀rọ̀ Daniel ṣeré rárá . Ọ̀kan tiẹ̀ wà lára wọn tó máa ń mú Daniel jáde tó bá fẹ́ lọ sọ́dọ̀ àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tàbí nígbà tó bá fẹ́ lọ gbá bọ́ọ̀lù . ” Nǹkan ti ń lọ dáadáa fún Poli àti ọmọ rẹ̀ báyìí . Kò sí àní - àní pé ọ̀pọ̀ ọ̀nà la lè gbà ran àwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ lọ́wọ́ ká sì tù wọ́n nínú . Àwọn ohun tí Ọlọ́run ṣèlérí nípa ọjọ́ ọ̀la tó wà nínú Bíbélì pẹ̀lú máa ń tuni nínú . Àwọn kan tiẹ̀ máa ń kọ déètì ọjọ́ tí ẹni náà kú sórí kàlẹ́ńdà wọn , kí wọ́n lè rántí láti tu ẹni tó ń ṣọ̀fọ̀ náà nínú nígbà tó nílò ìtùnú . Ṣé o rántí Gail tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní àpilẹ̀kọ tó ṣáájú , ó ń rò ó pé bóyá ni òun máa lè gbé ikú ọkọ òun kúrò lọ́kàn . Àmọ́ , ó ń retí ọjọ́ tó máa rí Rob ọkọ rẹ̀ nínú ayé tuntun tí Ọlọ́run ṣèlérí . Mo káàánú àwọn kan tí èèyàn wọn ti kú , àmọ́ tí wọn kò mọ̀ pé àwọn ṣì tún lè rí wọn pa dà nígbà àjíǹde . ” Láìpẹ́ , Ọlọ́run máa jí Jóòbù àti ọ̀kẹ́ àìmọye àwọn míì dìde , nígbà tó bá sọ ayé yìí di Párádísè . Bíbélì mú un dá wa lójú nínú ìwé Ìṣe 24 : 15 pé : “ Àjíǹde . . . yóò wà . ” Jésù fi wá lọ́kàn balẹ̀ pé : “ Kí ẹnu má yà yín sí èyí , nítorí pé wákàtí náà ń bọ̀ , nínú èyí tí gbogbo àwọn tí wọ́n wà nínú ibojì ìrántí yóò gbọ́ ohùn rẹ̀ , wọn yóò sì jáde wá . ” Nígbà tó bá rí i pé òun pa dà ní “ okun inú ti ìgbà èwe ” tí “ ara rẹ̀ jà yọ̀yọ̀ ju ti ìgbà èwe . ” Ohun kan náà ló máa ṣẹlẹ̀ sí gbogbo àwọn tó bá fi ìmọrírì hàn fún ohun tí Ọlọ́run fìfẹ́ pèsè fún wa , ìyẹn ni bó ṣe máa jí àwọn òkú dìde pa dà sí ayé . Tí ìwọ náà bá ń ṣọ̀fọ̀ èèyàn rẹ kan tó kú , àwọn ohun tá a ti jíròrò yìí lè má gbé ìbànújẹ́ náà kúrò lọ́kàn rẹ pátápátá . Àmọ́ tó o bá ń ronú lórí àwọn ìlérí Ọlọ́run tó wà nínú Bíbélì , wà á nírètí pé ọ̀la ń bọ̀ wá dáa , wàá sì lókun láti máa fara dà á nìṣó . — 1 Tẹsalóníkà 4 : 13 . Ṣé wà á fẹ́ mọ̀ sí i nípa bó o ṣe lè fara da ìbànújẹ́ ? Tàbí o ní àwọn ìbéèrè míì tó fara pẹ́ ẹ , irú bí “ Kí nìdí tí Ọlọ́run fi fàyè gba ìwà ibi àti ìjìyà ? ” Jọ̀ọ́ lọ sórí ìkànnì wa , www.jw.org / yo , kó o sì rí bí Bíbélì ṣe fún wa ní ìdáhùn tó tuni nínú , tó sì gbéṣẹ́ lónìí . “ [ Ọlọ́run ] yóò sì nu omijé gbogbo nù kúrò ní ojú wọn , ikú kì yóò sì sí mọ́ . ” ​ — Ìṣípayá 21 : 3 , 4 . Ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ yìí sọ nípa bí Ọlọ́run ṣe máa mú ìlérí yìí ṣẹ àti àǹfààní tó máa ṣe fún ẹ . Mo sọ fún sójà náà pé mo ti lọ sẹ́wọ̀n rí torí mo kọ̀ jálẹ̀ pé mi ò ní jagun . ÌLÚ Crooksville , ìpínlẹ̀ Ohio lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà ni wọ́n bí mi sí lọ́dún 1926 . Bàbá àti ìyá wa ò fẹ́ràn ìsìn , àmọ́ wọ́n máa ń sọ fáwa ọmọ wọn mẹ́jẹ̀ẹ̀jọ pé ká máa lọ sí ṣọ́ọ̀ṣì . Margaret Walker ( arábìnrin kejì láti apá òsì ) ló kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ Láàárín àkókò yẹn , obìnrin Ẹlẹ́rìí Jèhófà kan wà tá a jọ ń gbé ládùúgbò , Margaret Walker lorúkọ ẹ̀ , ó máa ń wá wàásù fún màmá mi nílé wa . Àmọ́ mo fara pa mọ́ síbì kan , mò ń fetí kọ́ ohun tí wọ́n ń sọ . Lẹ́yìn ìgbà mélòó kan tí Margaret ti ń wá , ó bi mí pé , “ Ǹjẹ́ o mọ orúkọ Ọlọ́run ? ” Mo ní , “ Hábà , ta ni ò mọ̀yẹn , Ọlọ́run ni kẹ̀ ! ” Ó ní , “ Lọ gbé Bíbélì ẹ , kó o ka Sáàmù 83 : 18 . ” Mo kà á lóòótọ́ , mo wá rí i pé Jèhófà lorúkọ Ọlọ́run . Mo bá sáré lọ bá àwọn ọ̀rẹ́ mi , mo sọ fún wọn pé , “ Tẹ́ ẹ bá délé lálẹ́ yìí , ẹ ṣí Bíbélì yín , kẹ́ ẹ ka Sáàmù 83 : 18 , ẹ máa rí orúkọ Ọlọ́run níbẹ̀ . ” Ẹ̀ ẹ́ ní mo ti yáa bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù nìyẹn . Wọ́n kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì , mo sì ṣèrìbọmi lọ́dún 1941 . Kò pẹ́ sígbà yẹn tí wọ́n fi ní kí n máa darí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìwé ìjọ . Mo ní kí ìyá mi , àwọn ẹ̀gbọ́n àtàwọn àbúrò mi náà máa wá sí ìkẹ́kọ̀ọ́ ìwé ìjọ tí mò ń darí . Nígbà míì , tí Mọ́mì bá ń lọ sípàdé , Dádì á sáré lé wọn mú , wọ́n á sì fà wọ́n pa dà sílé . Àmọ́ Mọ́mì á yọ́ gba ẹ̀yìnkùlé ní tiwọn , wọ́n á sì gbabẹ̀ lọ sípàdé . Mo wá sọ fáwọn sójà tó wà níbẹ̀ pé èmi ò ní wọṣẹ́ ológun ní tèmi o . Adájọ́ sọ fún mi pé : “ Tí wọ́n bá fi dídàá mi , ẹ̀wọ̀n gbére ni màá dá fún ẹ . Mo ní : “ Olúwa Mi , òjíṣẹ́ Ọlọ́run ni mí . Ṣe ni mo máa ń wàásù láti ilé dé ilé , mo sì ti wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fún ọ̀pọ̀ èèyàn . ” Adájọ́ wá sọ fún ìgbìmọ̀ ìgbẹ́jọ́ pé : “ Kì í ṣe torí ká lè mọ̀ bóyá òjíṣẹ́ Ọlọ́run ni ọkùnrin yìí tàbí kì í ṣe òjíṣẹ́ lẹ ṣe wà níbí . Ohun tẹ́ ẹ wá ṣe níbí ni pé kẹ́ ẹ sọ bóyá ó lọ síbi tí wọ́n ti ní kó wá wọṣẹ́ ológun àbí kò lọ . ” Mo gbàdúrà sí Jèhófà pé : “ Mi ò lè wà nínú ẹ̀wọ̀n fún ọdún márùn - ún . Lọ́jọ́ kejì , àwọn ẹ̀ṣọ́ ọgbà ẹ̀wọ̀n náà ṣí mi sílẹ̀ kí n lè rìn yí ká ọgbà náà . Mo rìn lọ síbi tí ọkùnrin kan wà , Paul lorúkọ ẹ̀ , ó ga gan - an , ó sì tún nígẹ̀ , a jọ dúró sójú fèrèsé kan . Ó ní , “ Kúrú - n - béte ! Kí lo wá ṣe ńbí ? ” Mo ní , “ Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni mí . ” Mo ní , “ Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà kì í jagun , a kì í sì í pààyàn . ” Mo ní , “ Rárá , kò mú ọpọlọ dání . ” Ó wá sọ fún mi pé , “ Mo ti lo ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún [ 15 ] lọ́gbà ẹ̀wọ̀n kan , ibẹ̀ ni mo sì ti ka àwọn kan lára àwọn ìwé yín . ” Mo wà lára àwọn Ẹlẹ́rìí tí wọ́n fi sẹ́wọ̀n nílùú Ashland , ìpínlẹ̀ Kentucky torí pé a ò wọṣẹ́ ológun Bá a ṣe ṣètò iṣẹ́ ìwàásù wa lọ́nà tó wà létòlétò nìyẹn . Mò ń ronú nípa màmá mi , àwọn ẹ̀gbọ́n mi àtàwọn àbúrò mi , torí Dádì ti sọ fún mi pé , “ Tí mo bá ṣáà ti rọ́gbọ́n dá sọ́rọ̀ tìẹ , kékeré ni tàwọn tó kù . ” Àmọ́ , ìròyìn ayọ̀ kan ni mo bá nílé lẹ́yìn tí wọ́n dá mi sílẹ̀ lọ́gbà ẹ̀wọ̀n , ó sì yà mí lẹ́nu gan - an . Mo ní , “ Ìyẹn dáa , àmọ́ mi ò ní wọṣẹ́ ológun . ” Mo sọ ohun tó wà nínú 2 Tímótì 2 : 3 fún un , mo wá sọ fún un pé , “ Ọmọ ogun Kristi ni mí . ” Ó kọ́kọ́ dákẹ́ lọ gbári , lẹ́yìn náà , ó wá sọ pé , “ O lè máa lọ . ” Ní àkókò díẹ̀ lẹ́yìn náà , mo lọ sí ìpàdé tí wọ́n máa ń ṣe pẹ̀lú àwọn tó fẹ́ láti sìn ní Bẹ́tẹ́lì ní àpéjọ àgbègbè tó wáyé ní ìlú Cincinnati , ìpínlẹ̀ Ohio . Mo tún ṣiṣẹ́ láwọn Gbọ̀ngàn Àpéjọ tó wà nílùú New York City . Mo ti láwọn ọ̀rẹ́ rẹpẹtẹ ní Bẹ́tẹ́lì àti nínú ìjọ . Mo gbọ́ èdè Mandarin Chinese díẹ̀ , mo sì máa ń wàásù fáwọn ọmọ ilẹ̀ Ṣáínà tó ń kọjá ní òpópónà . Láwọn àárọ̀ ọjọ́ míì , mo máa ń fi ìwé ìròyìn tó tó ọgbọ̀n [ 30 ] tàbí ogójì [ 40 ] síta . Èmi rèé ní ìlú Brooklyn , ìpínlẹ̀ New York , níbi tí mo ti ń wàásù fáwọn ọmọ ilẹ̀ Ṣáínà Mo tiẹ̀ ti ṣe ìpadàbẹ̀wò rí ní orílẹ̀ - èdè Ṣáínà ! Ó gbà á , ó wá sọ pé Katie lorúkọ òun . Látìgbà yẹn , ó máa ń yà lọ́dọ̀ mi tó bá ń kọjá lọ . Mo kọ́ ọ lórúkọ tí wọ́n ń pe àwọn èso lóríṣiríṣi àtàwọn ewébẹ̀ lédè Gẹ̀ẹ́sì , ó sì máa ń sọ àwọn ọ̀rọ̀ náà tẹ̀ lé mi . Mo tún máa ń ṣàlàyé àwọn ẹsẹ Bíbélì fún un , ó sì gba ìwé Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan - an ? Àmọ́ lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ mélòó kan , mi ò rí i mọ́ . Ní ọ̀sẹ̀ tó tẹ̀ lé e , ó yà lọ́dọ̀ mi bó ti ń kọjá lọ , ó gbé fóònú rẹ̀ fún mi , ó ní , “ Ẹ bá ẹnì kan sọ̀rọ̀ ní Ṣáínà . ” Mo ní , “ Mi ò mọ èèyàn kankan ní Ṣáínà . ” Àmọ́ , ó ní kí n ṣáà gbà , mo bá gba fóònù náà , mo ní , “ Ẹ ǹlẹ́ o , Robison ló ń sọ̀rọ̀ o . ” Ẹni tó wà lórí fóònù náà wá sọ pé , “ Robby , èmi Katie ni . Jọ̀ọ́ bá mi kọ́ òun náà bó o ṣe kọ́ mi . ” Mo ní , “ Katie , fọkàn balẹ̀ , màá ṣe gbogbo ohun tí mo lè ṣe . O ṣeun tó o jẹ́ kí n mọ ibi tó o wà . ” Mo bá àbúrò Katie sọ̀rọ̀ , àmọ́ kò pẹ́ lẹ́yìn náà , kó tó di pé mi ò rí i mọ́ . Ó dájú pé ayọ̀ ọ̀hún á pọ̀ nígbà tí àwa àtàwọn èèyàn wa bá jọ ń sin Jèhófà títí láé ! Báwo làwọn ohun tí Ábúráhámù kọ́ nípa Jèhófà àtàwọn ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i ṣe fún ìgbàgbọ́ rẹ̀ lókun ? Báwo ni Ábúráhámù ṣe mú kí àjọṣe tó ní pẹ̀lú Ọlọ́run lágbára sí i ? Báwo lo ṣe lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà kó o sì tipa bẹ́ẹ̀ fìwà jọ Ábúráhámù ? 1 , 2 . ( a ) Báwo la ṣe mọ̀ pé àwa èèyàn lè di ọ̀rẹ́ Ọlọ́run ? 3 , 4 . ( a ) Kí ló ṣeé ṣe kó jẹ́ àdánwò ìgbàgbọ́ tó lágbára jù lọ tí Ábúráhámù kojú ? Ọ̀nà wo ló ṣeé ṣe kí Ábúráhámù gbà mọ Jèhófà , kí sì làwọn ohun tó kọ́ nípa Jèhófà mú kó ṣe ? Báwo la ṣe lè ní ìmọ̀ àti ìrírí táá mú kí àjọṣe wa pẹ̀lú Jèhófà túbọ̀ lágbára ? 9 , 10 . ( a ) Kí ni kì í jẹ́ kí okùn ọ̀rẹ́ tètè já ? ( b ) Kí ló fi hàn pé Ábúráhámù mọyì àjọṣe tó ní pẹ̀lú Jèhófà àti pé kò fẹ́ kí àjọṣe náà bà jẹ́ ? Ábúráhámù mọyì àjọṣe tó ní pẹ̀lú Jèhófà kò sì jẹ́ kó bà jẹ́ . Kí ló fà á tí Ábúráhámù ò fi fẹ́ kí Jèhófà pa ìlú Sódómù àti Gòmórà run , báwo sì ni Jèhófà ṣe ràn án lọ́wọ́ ? 12 , 13 . ( a ) Ọ̀nà míì wo tún ni àwọn ohun tí Ábúráhámù kọ́ nípa Jèhófà àtàwọn ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i gbà ràn án lọ́wọ́ ? ( b ) Kí ló fi hàn pé Ábúráhámù ní ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà ? Ábúráhámù àti Sárà mọ Jèhófà , wọ́n sì jọ́sìn rẹ̀ Ábúráhámù kú “ ní ọjọ́ ogbó gidi gan - an , ó darúgbó , ó sì ní ìtẹ́lọ́rùn ” Kí nìdí tó fi lè dá wa lójú pé Ábúráhámù ò kábàámọ̀ bó ṣe ṣègbọràn sí Jèhófà jálẹ̀ gbogbo ìgbésí ayé rẹ̀ ? Kí lo pinnu láti ṣe , kí la sì máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Àwa náà nílò ìmọ̀ àti ìrírí bíi tiẹ̀ . ( Ka Hébérù 6 : 10 - 12 . ) Nínú àpilẹ̀kọ tó kàn , a máa jíròrò àpẹẹrẹ àwọn olóòótọ́ èèyàn mẹ́ta míì táwọn náà di ọ̀rẹ́ Ọlọ́run . Kí la lè rí kọ́ látinú àjọṣe tí Rúùtù ní pẹ̀lú Ọlọ́run ? Kí ló mú kí Hesekáyà Ọba di ọ̀rẹ́ Jèhófà ? ? Àwọn ànímọ́ wo ni Màríà ìyá Jésù ní tó mú kó di ọ̀rẹ́ Jèhófà Ọlọ́run ? 1 - 3 . ( a ) Kí ló mú kó dá wa lójú pé a lè di ọ̀rẹ́ Ọlọ́run ? ( b ) Àwọn wo la máa sọ̀rọ̀ wọn nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Ìpinnu tó lágbára wo ni Rúùtù ní láti ṣe , kí ló sì mú kí ìpinnu náà ṣòro ṣe ? ( a ) Ìpinnu tó mọ́gbọ́n dání wo ni Rúùtù ṣe ? ( b ) Kí nìdí tí Bóásì fi sọ pé Rúùtù ń wá ibi ìsádi lábẹ́ ìyẹ́ apá Jèhófà ? Kí ló lè ran àwọn tí wọn ò tíì fẹ́ ya ara wọn sí mímọ́ fún Jèhófà lọ́wọ́ ? 9 , 10 . ( a ) Kí ni ì bá ti mú kí Hesekáyà bínú sí Jèhófà ? ( b ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa bínú sí Ọlọ́run ? ( d ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká lérò pé irú ilé tá a ti jáde ló máa pinnu irú èèyàn tá a máa jẹ́ ? Ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀dọ́ ló ti wá sínú òtítọ́ láìka irú ilé tí wọ́n ti wá sí ( Wo ìpínrọ̀ 9 , 10 ) Kí ló mú kí Hesekáyà jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọba tó dáa jù ní Júdà ? ( Ka 2 Àwọn Ọba 18 : 5 , 6 . ) Bíi ti Hesekáyà , báwo lọ̀pọ̀ èèyàn ṣe ń fi hàn lónìí pé ọ̀rẹ́ Jèhófà làwọn ? Kí nìdí tó fi dà bíi pé iṣẹ́ tí Jèhófà gbé lé Màríà lọ́wọ́ ti nira jù , síbẹ̀ kí ló sọ fún Gébúrẹ́lì ? Báwo la ṣe mọ̀ pé Màríà máa ń fetí sílẹ̀ dáadáa ? Ní ìgbà méjèèjì yìí , Màríà fetí sílẹ̀ dáadáa , kò gbàgbé àwọn ohun tó gbọ́ , ó sì fara balẹ̀ ronú lé wọn lórí . — Ka Lúùkù 2 : 16 - 19 , 49 , 51 . Kí la lè rí kọ́ nínú àwọn ohun tí Màríà sọ ? Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ Màríà ? Kí ló dá wa lójú bá a ṣe ń tẹ̀ lé àwọn àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ títayọ tó wa nínú Bíbélì ? ṢÓ O rántí ọjọ́ tí inú ẹ dùn jù lọ ? Ṣé ọjọ́ tó o ṣe ìgbéyàwó ni àbí ọjọ́ tó o bí àkọ́bí rẹ ? Kò sí àní àní pé o ti ní ayọ̀ púpọ̀ láti ìgbà tó o ti ṣe ìrìbọmi . Àwọn ìdí wo la ní láti máa fi ayọ̀ sin Jèhófà nìṣó ? Rántí ohun tí Jésù sọ pé : “ Ẹ wá sọ́dọ̀ mi , gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe làálàá , tí a sì di ẹrù wọ̀ lọ́rùn , dájúdájú , èmi yóò sì tù yín lára . Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín , kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ mi , nítorí onínú tútù àti ẹni rírẹlẹ̀ ní ọkàn - àyà ni èmi , ẹ ó sì rí ìtura fún ọkàn yín . À ń jọ́sìn Olùfúnni - ní - Ìyè wa , Ọlọ́run aláyọ̀ . Wo àpẹẹrẹ Héctor , ogójì [ 40 ] ọdún ló fi sin Jèhófà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn alábòójútó arìnrìn - àjò . Ó sọ pé : “ Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ojoojúmọ́ ni ìlera ìyàwó mi ń burú sí i , kò sì rọrùn láti tọ́jú rẹ̀ , mi ò jẹ́ kíyẹn gba ayọ̀ tí mo ní lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run lọ́wọ́ mi . Bí mo ṣe mọ̀ pé ó ní ìdí tí Jèhófà fi dá àwa èèyàn , òun ló sì fún mi ní ìwàláàyè , ìyẹn ti tó ìdí fún mi láti nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ kí n sì máa sìn ín tọkàntọkàn . Mo máa ń sapá kí ìtara tí mo ní fún iṣẹ́ ìwàásù má bàa dín kù , mo sì máa ń fi ìrètí Ìjọba Ọlọ́run sọ́kàn ní gbogbo ìgbà kí n má bàa pàdánù ayọ̀ tí mo ní . ” Jèhófà ti fún wa lẹ́bùn ìràpadà tó ń mú ká máa láyọ̀ . Lóòótọ́ , “ Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ ayé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí ó fi fi Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo fúnni , kí olúkúlùkù ẹni tí ó bá ń lo ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ má bàa pa run , ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun . ” Jesús jẹ́ kí ohun ìní tara díẹ̀ tẹ́ òun lọ́rùn , ó sì fayọ̀ sin Jèhófà fún ọ̀pọ̀ ọdún Torí owó ni mo ṣe ń ṣe é . Mo wá kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà àti bó ṣe fi Ọmọ rẹ̀ ọ̀wọ́n ṣe ìràpadà fún wa . Bó ṣe di pé ó ń wù mí látọkànwá láti sin Jèhófà nìyẹn . Torí náà , mo ṣe ìyàsímímọ́ , mo sì kọ̀wé fi iṣẹ́ sílẹ̀ lẹ́yìn ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n [ 28 ] tí mo ti ń ṣiṣẹ́ ní ilé iṣẹ́ náà , mo wá pinnu láti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ alákòókò - kíkún ní pẹrẹu . ” Ṣó o rántí bí ìgbésí ayé rẹ ṣe rí kó o tó wá mọ Jèhófà ? Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rán àwọn Kristẹni tó wà nílùú Róòmù létí pé wọ́n “ jẹ́ ẹrú ẹ̀ṣẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí , ” àmọ́ wọ́n ti wá di “ ẹrú fún òdodo . ” “ Àwọn ọdún tí mo láyọ̀ jù lọ làwọn ọdún tí mo fi sin Jèhófà . ” ​ — Jaime Jaime wá sọ pé , “ ní kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀ , mo rí i pé Ọlọ́run kan wà tó jẹ́ aláàánú , Bàbá onífẹ̀ẹ́ sì tún ni . Ààbò ni àwọn ìlànà òdodo Jèhófà jẹ́ fún mi . Ká ní mi ò tíì yí pa dà ni , wọ́n lè ti pa mí bíi tàwọn ọ̀rẹ́ mi kan tá a jọ ń kànṣẹ́ . Àwọn ọdún tí mo láyọ̀ jù lọ làwọn ọdún tí mo fi sin Jèhófà . ” Báwo ni Jónátánì ọmọ Sọ́ọ̀lù Ọba ṣe jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà ? Báwo la ṣe lè jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run bá a bá tiẹ̀ rò pé kò yẹ ká bọ̀wọ̀ fún ẹnì kan tó wà nípò àṣẹ ? Báwo la ṣe lè jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà bí ẹnì kan tiẹ̀ ṣì wá lóye tàbí tó ṣàìdáa sí wa ? Kí ló mú kí àjọṣe tó wà láàárín Dáfídì àti Jónátánì jẹ́ àpẹẹrẹ ìdúróṣinṣin téèyàn lè tẹ̀ lé ? Kí ló ṣe pàtàkì sí Jónátánì ju jíjẹ́ adúróṣinṣin sí Dáfídì lọ , báwo la sì ṣe mọ̀ ? ( a ) Kí ló máa mú ká láyọ̀ kí ọkàn wa sì balẹ̀ ? Nǹkan ò rọgbọ fún Jónátánì àtàwọn ọmọ Ísírẹ́lì . Kí ló fi hàn pé Jónátánì ò fi Jèhófà sílẹ̀ ? Tá a bá ń bọ̀wọ̀ fáwọn tó wà nípò àṣẹ , báwo nìyẹn á ṣe fi hàn pé a jẹ́ adúróṣinṣin ? Báwo ni ìfẹ́ tá a ní fún Ọlọ́run ṣe máa mú ká pinnu pé a máa jẹ́ adúróṣinṣin sí i ? Tá a bá jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run , báwo nìyẹn ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ láti fara da ìṣòro ìdílé ? Bí arákùnrin kan bá hùwà tí ò dáa sí wa , kí ló yẹ ká ṣe ? Àwọn ìgbà wo ló pọn dandan pé ká jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 9 ) A ti yí àwọn orúkọ kan pa dà . Kí nìdí tí èrò tí Jónátánì ní nípa Dáfídì fi yàtọ̀ sí ti Ábínérì ? Àwọn ànímọ́ wo ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run , báwo ló sì ṣe máa ràn wá lọ́wọ́ ? Báwo ni Dáfídì ṣe fi hàn pé òun jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run ? ( a ) Kí ló mú kí Dáfídì jẹ́ àpẹẹrẹ ìdúróṣinṣin ? ( b ) Àwọn àpẹẹrẹ míì wo la máa jíròrò ? Kí la rí kọ́ látinú àṣìṣe tí Ábíṣáì ṣe ? Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a máa ń fẹ́ jẹ́ adúróṣinṣin sí àwọn mẹ́ńbà ìdílé wa àtàwọn ọ̀rẹ́ wa , kí nìdí tó fi yẹ ká ṣọ́ra ? Báwo ni arábìnrin kan ṣe jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà nígbà tí nǹkan le koko ? Àwọn ànímọ́ wo ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run ? Kí la kọ́ látinú ohun tí Bíbélì sọ nípa Ábínérì , Ábúsálómù àti Bárúkù ? Ṣùgbọ́n ní tìrẹ , ìwọ ń wá àwọn ohun ńláńlá fún ara rẹ . Kí nìdí tá ò fi lè jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run tá a bá jẹ́ onímọtara ẹni nìkan ? Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ àdúrà àti ẹkún , ohun tí mo ṣe gan - an nìyẹn . Nígbà tí Dáfídì ṣẹ̀ , báwo ni Nátánì ṣe jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run àti sí Dáfídì ? Báwo lo ṣe lè jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà àtàwọn ọ̀rẹ́ tàbí mọ̀lẹ́bí rẹ ? Kí nìdí tí Húṣáì fi gbọ́dọ̀ jẹ́ onígboyà tó bá fẹ́ jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà ? Kí nìdí tá a fi gbọ́dọ̀ jẹ́ onígboyà tá a bá fẹ́ jẹ́ adúróṣinṣin ? Taro sọ pé : “ Inú bí àwọn òbí mi débi pé ọ̀pọ̀ ọdún ni wọn ò fi gbà kí n wá kí àwọn nílé . Ìwà wọn ti yí pa dà báyìí , mo sì lè lọ kí wọn nígbà tí mo bá fẹ́ . ” — Ka Òwe 29 : 25 . [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 7 ) A ti yí àwọn orúkọ kan pa dà . KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | KÍ NÌDÍ TÍ JÉSÙ FI JÌYÀ TÓ SÌ KÚ ? Wọ́n pa Jésù ará Násárétì nígbà ìrúwé ọdún 33 Sànmánì Kristẹni . Ẹ̀sùn èké tí wọ́n fi kàn án ni pé ó dìtẹ̀ sí ìjọba , wọ́n sì lù ú ní àlùbami kí wọ́n tó kàn án mọ́gi . Àmọ́ , Ọlọ́run jí i dìde , ó sì pa dà sí ọ̀run lẹ́yìn ogójì [ 40 ] ọjọ́ tó jíǹde . Inú ìwé Ìhìn Rere Mátíù , Máàkù , Lúùkù àti Jòhánù ni ìtàn yìí wà . Lọ́wọ́ kejì , tí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ yìí bá wáyé lóòótọ́ , á jẹ́ pé ọ̀la ṣì ń bọ̀ wá dáa fún àwa èèyàn , a sì máa ní láti sọ nípa rẹ̀ fún àwọn ẹlòmíì . Torí náà , ṣé òótọ́ pọ́ńbélé lohun tí àwọn ìwé Ìhìn Rere sọ nípa Jésù àbí ìtàn àròsọ lásán ni ? Àwọn ìwé Ìhìn Rere yìí kò dà bí àwọn ìwé ìtàn àròsọ , torí pé ó ṣe àwọn àkọsílẹ̀ tó péye àti àwọn àlàyé tó kún rẹ́rẹ́ . Bí àpẹẹrẹ , wọ́n sọ orúkọ oríṣiríṣi ìlú tó ṣì wà títí dòní . Wọ́n tún sọ nípa àwọn èèyàn tó gbé ayé nígbà yẹn , tí àwọn òpìtàn ayé àtijọ́ náà sì sọ̀rọ̀ nípa wọn . — Lúùkù 3 : 1 , 2 , 23 . Àwọn òǹkọ̀wé ní ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní àti ìkejì pàápàá sọ̀rọ̀ nípa Jésù . * Ohun tí àwọn tó kọ ìwé Ìhìn Rere sọ nípa bí wọ́n ṣe pa Jésù bá ọ̀nà tí àwọn ará Róòmù máa ń gbà pa àwọn èèyàn nígbà yẹn mu . Láfikún sí i , kò sí àbùmọ́ tàbí àyọkúrò èyíkéyìí nínú ohun tí wọ́n kọ . Kódà , wọ́n sọ ìwà tó kù díẹ̀ káàtó tí àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù fúnra wọn hù . Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ gbà pé Jésù gbáyé ó sì kú , síbẹ̀ àwọn kan ò gbà pé Jésù jíǹde . Kódà , àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ kò kọ́kọ́ gbà gbọ́ nígbà tí wọ́n gbọ́ pé Jésù ti jíǹde . Àmọ́ wọ́n kò ṣiyèméjì mọ́ nígbà tí wọ́n rí Jésù ní àsìkò ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lẹ́yìn tó jíǹde . Ó tiẹ̀ nígbà kan tí Jésù fara han àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó ju ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta [ 500 ] lọ . — 1 Kọ́ríńtì 15 : 6 . Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù mọ̀ pé àwọn lè fẹ̀wọ̀n gbára tàbí kí wọ́n pa àwọn , síbẹ̀ wọ́n fi ìgboyà sọ nípa àjíǹde Jésù fún gbogbo èèyàn , kódà fún àwọn tó ṣekú pa Jésù . Ṣé ó máa ṣeé ṣe fún àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ láti ní irú ìgboyà bẹ́ẹ̀ tí kò bá dá wọn lójú pé Jésù ti jíǹde ? Torí pé Jésù jíǹde lóòótọ́ ló mú kí ẹ̀sìn Kristẹni lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ nígbà yẹn àti lóde òní . Àwọn ẹ̀rí fi hàn pé òótọ́ tí kò ṣeé já ní koro ni àwọn àkọsílẹ̀ nípa ikú àti àjíǹde Jésù tó wà nínú àwọn ìwé Ìhìn Rere . Tá a bá fara balẹ̀ ka àwọn ìwé Ìhìn Rere yìí , ó máa dá wa lójú pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ lóòótọ́ . Ìgbàgbọ́ tá a sì ní máa túbọ̀ lágbára sí i tá a bá mọ ìdí tí wọ́n fi ṣẹlẹ̀ . Tacitus , tí wọ́n bí ní nǹkan bí ọdún 55 Sànmánì Kristẹni kọ̀wé pé “ Kristi táwọn Kristẹni fi sọ ara wọn lórúkọ ni Pọ́ńtíù Pílátù tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn baálẹ̀ wa dájọ́ ikú fún tí wọ́n sì pa nígbà ìjọba Tìbéríù . ” Àwọn míì tó tún mẹ́nu kan Jésù ni Suetonius tó gbáyé ní ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní ; òpìtàn Júù náà Josephus tó gbáyé ní ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní àti Pliny Kékeré tó jẹ́ gómìnà Bítíníà tó gbáyé ní ìbẹ̀rẹ̀ ọgọ́rùn - ún ọdún kejì . Àti pé Jésù ni àwọn ọ̀tá tó pọ̀ , kò sì dájú pé àwọn wọ̀nyí máa kọ ohun táá mú kí àwọn èèyàn gba Jésù gbọ́ . Nígbà tí Pétérù tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn àpọ́sítélì ń sọ nípa àjíǹde Jésù , ó ní : “ Ọlọ́run gbé Ẹni yìí dìde ní ọjọ́ kẹta , ó sì yọ̀ǹda fún un láti fara hàn kedere , kì í ṣe fún gbogbo ènìyàn , bí kò ṣe fún àwọn ẹlẹ́rìí tí Ọlọ́run ti yàn ṣáájú , fún àwa , tí a bá a jẹ , tí a sì bá a mu lẹ́yìn tí ó dìde kúrò nínú òkú . ” Ìwé Ìhìn Rere Mátíù sọ pé nígbà táwọn ọ̀tá Jésù gbọ́ pé ó ti jíǹde , ńṣe ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í wá bí wọ́n ṣe máa bo ìròyìn náà mọ́lẹ̀ . — Mátíù 28 : 11 - 15 . Ṣé ìyẹn wá túmọ̀ sí pé Jésù kò fẹ́ kí àwọn èèyàn mọ̀ nípa àjíǹde rẹ̀ ni ? Rárá o , torí Pétérù sọ pé : “ Ó pa àṣẹ ìtọ́ni fún wa láti wàásù fún àwọn ènìyàn àti láti jẹ́rìí kúnnákúnná pé ẹni tí Ọlọ́run ti fàṣẹ gbé kalẹ̀ nìyí pé kí ó jẹ́ onídàájọ́ alààyè àti òkú . ” Ohun táwọn Kristẹni tòótọ́ ti ṣe látìgbà náà títí dòní nìyẹn . — Ìṣe 10 : 42 . “ Ẹ̀ṣẹ̀ ti tipasẹ̀ ènìyàn kan [ Ádámù ] wọ ayé àti ikú nípasẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ . ” ​ — Róòmù 5 : 12 Kí lo máa sọ tí wọ́n bá bi ẹ́ pé , “ Ṣé o fẹ́ wà láàyè títí lọ fáàbàdà ? ” Àmọ́ , bí ohun tí kò ṣeé ṣe nírú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ máa jọ lójú wọn . Wọ́n máa ń sọ pé awáyé máà kú ò sí . Ká sọ pé wọ́n bi ẹ́ ní ìbéèrè yẹn lọ́nà míì , pé , “ Ṣé o ti ṣe tán tó o fẹ́ kú ? ” Ó dájú pé ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa dáhùn pé rárá o . Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé Ọlọ́run dá wa lọ́nà táá fi wù wá láti máa wà láàyè . Kódà ó sọ pé , “ àkókò tí ó lọ kánrin ni ó ti fi sínú ọkàn - àyà wọn . ” — Oníwàásù 3 : 11 . Àmọ́ ní báyìí , àwa èèyàn ń kú . Ǹjẹ́ Ọlọ́run ti ṣe ohunkóhun láti gbà wá lọ́wọ́ ikú ? Bíbélì fún wa láwọn ìdáhùn tó ń fini lọ́kàn balẹ̀ , àwọn ìdáhùn náà sì jẹ́ ká mọ ìdí tí Jésù fi jìyà tó sì kú . Orí mẹ́ta àkọ́kọ́ nínú ìwé Jẹ́nẹ́sísì jẹ́ ká mọ̀ pé Ọlọ́run fún àwọn òbí wa àkọ́kọ́ , ìyẹn Ádámù àti Éfà , láǹfààní láti wà láàyè títí láé . Ó sì sọ ohun tí wọ́n gbọ́dọ̀ ṣe kí wọ́n lè máa wà láàyè nìṣó . Àkọsílẹ̀ náà sọ bí wọ́n ṣe ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run , tí wọ́n sì pàdánù àǹfààní yẹn . Torí pé Bíbélì kàn sọ ìtàn náà fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́ , àwọn kan sọ pé ìtàn àròsọ lásán ni . Kí wá ni àbájáde àìgbọràn Ádámù ? Bíbélì dáhùn pé : “ Ẹ̀ṣẹ̀ ti tipasẹ̀ ènìyàn kan wọ ayé àti ikú nípasẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ , ikú sì tipa báyìí tàn dé ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí pé gbogbo wọn ti dẹ́ṣẹ̀ . ” Ó tipa bẹ́ẹ̀ pàdánù àǹfààní tó ní láti wà láàyè títí láé , ó sì kú nígbẹ̀yìn - gbẹ́yín . Torí pé àtọmọdọ́mọ Ádámù ni wá , a ti jogún ẹ̀ṣẹ̀ látọ̀dọ̀ rẹ̀ . Àmọ́ , ǹjẹ́ Ọlọ́run ti ṣe ohunkóhun láti gbà wá lọ́wọ́ ikú ? Ọlọ́run ṣètò láti ra ohun tí Ádámù gbé sọnù pa dà fún àwọn àtọmọdọ́mọ rẹ̀ , ìyẹn ni àǹfààní láti wà láàyè títí lọ fáàbàdà . Ìwé Róòmù 6 : 23 sọ pé : “ Owó ọ̀yà tí ẹ̀ṣẹ̀ máa ń san ni ikú . ” Èyí fi hàn pé ikú ni èrè ẹ̀ṣẹ̀ . Bẹ́ẹ̀ ni àwa náà jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ , ìdí sì nìyẹn tá a fi ń kú . Àmọ́ , kì í ṣe ẹ̀bi wa pé a jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ torí pé ńṣe la jogún ẹ̀ṣẹ̀ látọ̀dọ̀ àwọn òbí wa àkọ́kọ́ . Ṣùgbọ́n torí pé Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ wa , ó rán Jésù Ọmọ rẹ̀ kó lè wá san ‘ owó ọ̀yà ẹ̀ṣẹ̀ ’ náà nítorí wa . Ádámù tó jẹ́ ẹni pípé ṣàìgbọràn , èyí ló fa ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú . Torí náà , ká tó lè bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú , a nílò ẹni pípé tó máa jẹ́ onígbọràn títí dójú ikú . Bíbélì ṣàlàyé rẹ̀ lọ́nà yìí : “ Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ pé nípasẹ̀ àìgbọràn ènìyàn kan ọ̀pọ̀ ènìyàn ni a sọ di ẹlẹ́ṣẹ̀ , bákan náà pẹ̀lú ni ó jẹ́ pé nípasẹ̀ ìgbọràn ènìyàn kan , ọ̀pọ̀ ènìyàn ni a ó sọ di olódodo . ” Ó fi ọ̀run sílẹ̀ , ó di èèyàn tí kò lẹ́ṣẹ̀ * , ó sì kú fún wa . Nípa bẹ́ẹ̀ , ó ṣeé ṣe fún wa láti rí ojúure Ọlọ́run , ká sì nírètí láti wà láàyè títí lọ fáàbàdà . Kí wá nìdí tó fi pọn dandan kí Jésù kú kó tó lè gbà wá lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú ? Ṣé Ọlọ́run ò kàn lè sọ pé kí àwa àtọmọdọ́mọ Ádámù máa wà láàyè títí lọ ? Tí Ọlọ́run bá gbójú fo ìdájọ́ òdodo nínú ọ̀rọ̀ yìí , èyí lè mú ká máa ronú pé bóyá ni Ọlọ́run ò ni gbójú fo ìdájọ́ òdodo nínú àwọn ọ̀rọ̀ míì tó ṣe pàtàkì . Bí àpẹẹrẹ , ṣé Ọlọ́run máa ṣe ìdájọ́ tó yẹ tó bá fẹ́ pinnu àwọn tó máa wà láàyè títí láé nínú àwa àtọmọdọ́mọ Ádámù ? Ṣé ọkàn wa máa balẹ̀ pé Ọlọ́run máa mú àwọn ìlérí rẹ̀ ṣẹ ? Àmọ́ , Ọlọ́run ò gbójú fo ìdájọ́ òdodo nínú bó ṣe ṣètò ìgbàlà fún wa . Èyí sì jẹ́ kó dá wa lójú pé gbogbo ìgbà ni Ọlọ́run máa ṣe ohun tó tọ́ . Jésù sọ nínú ìwé Jòhánù 3 : 16 pé : “ Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ ayé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí ó fi fi Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo fúnni , kí olúkúlùkù ẹni tí ó bá ń lo ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ má bàa pa run , ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun . ” Ikú Jésù jẹ́ ká rí i pé Ọlọ́run kì í bo ìdájọ́ òdodo mọ́lẹ̀ , àmọ́ ní pàtàkì ó jẹ́ ká rí i pé ìfẹ́ tó jinlẹ̀ ni Ọlọ́run ní fún àwa èèyàn . Ṣùgbọ́n , kí nìdí tí Jésù fi jẹ adúrú ìyà tó jẹ láyé tó sì tún wá kú ikú oró bí àwọn ìwé Ìhìn Rere ṣe sọ ? Sátánì Èṣù sọ pé kò sẹ́ni tó máa jẹ́ olóòótọ́ sí Ọlọ́run tó bá rí àdánwò , àmọ́ bí Jésù ṣe jẹ adúrú ìyà yẹn títí tó fi kú fi hàn pé irọ́ gbuu ni Èṣù pa . Ohun tí Sátánì sọ yìí jọ òótọ́ nígbà tó tan Ádámù tó jẹ́ ẹni pípé láti dẹ́ṣẹ̀ . Àmọ́ , Jésù tóun náà jẹ́ ẹni pípé bíi ti Ádámù jẹ́ olóòótọ́ láìka adúrú ìyà tó jẹ . Jésù tipa bẹ́ẹ̀ fi hàn pé Ádámù náà lè jẹ́ olóòótọ́ sí Ọlọ́run ká sọ pé ó pinnu láti ṣe bẹ́ẹ̀ . Bí Jésù ṣe fara da àdánwò jẹ́ àpẹẹrẹ tó yẹ ká tẹ̀ lé lónìí . Ọlọ́run wá san ọmọ rẹ̀ lẹ́san torí ìgbọràn rẹ̀ nípa fífún un ní àìleèkú ní ọ̀run . Jésù sọ ohun tá a gbọ́dọ̀ ṣe , ó ní : “ Èyí túmọ̀ sí ìyè àìnípẹ̀kun , gbígbà tí wọ́n bá ń gba ìmọ̀ ìwọ , Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà sínú , àti ti ẹni tí ìwọ rán jáde , Jésù Kristi . ” — Jòhánù 17 : 3 . Àwọn tó ṣe ìwé ìròyìn yìí ń rọ̀ ẹ́ pé kó o kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà Ọlọ́run tòótọ́ àti Jésù Kristi Ọmọ rẹ̀ . Inú àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ládùúgbò rẹ máa dùn láti ràn ẹ́ lọ́wọ́ . O sì tún lè rí ìsọfúnni tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ lórí ìkànnì wa , ìyẹn www.jw.org / yo . Wo àkòrí tá a pè ní “ The Historical Character of Genesis , ” nínú ìwé Insight on the Scriptures , Apá kìíní , ojú ìwé 922 . Ọlọ́run fi ẹ̀mí Ọmọ rẹ̀ sínú Màríà , ó sì lóyún . Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run sì dáàbò bo Jésù kó máa bàa jogún ẹ̀ṣẹ̀ látara Màríà . — Lúùkù 1 : 31 , 35 . Ní alẹ́ ọjọ́ tó ṣáájú ikú rẹ̀ , Jésù kó àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ jọ , ó si fi Ìrántí Ikú rẹ̀ lélẹ̀ . Ó sọ fún wọn pé : “ Ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi . ” Ọdọọdún ni àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń pé jọ láti pa àṣẹ yìí mọ́ ní àyájọ́ ọjọ́ tí Jésù kú . Lọ́dún yìí , ọjọ́ Wednesday , March 23 la máa ṣe Ìrántí Ikú Jésù lẹ́yìn tí oòrùn bá wọ̀ . Ọ̀fẹ́ ni ìjókòó , a kò sì ní gbégbá owó . Jọ̀wọ́ , béèrè aago tí wọ́n máa ṣe é àti ibi tí wọ́n ti máa ṣe é lọ́wọ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó bá wà ládùúgbò rẹ . O sì lè wò ó lórí ìkànnì wa , ìyẹn www.jw.org / yo . ṢÉ WÀÁ SỌ PÉ Èṣù jẹ́ . . . Èrò ibi tó wà lọ́kàn èèyàn ? Èṣù bá Jésù sọ̀rọ̀ , ó sì “ dẹ ẹ́ wò . ” Áńgẹ́lì mímọ́ ni Èṣù nígbà tí Ọlọ́run dá a , àmọ́ ‘ kò dúró ṣinṣin nínú òtítọ́ . ’ Ó di òpùrọ́ , ó sì ta ko Ọlọ́run . Àwọn áńgẹ́lì míì gbè sẹ́yìn Sátánì . — Ìṣípayá 12 : 9 . Èṣù ti mú kí ọ̀pọ̀ èèyàn gbà pé òun kò sí . ​ — 2 Kọ́ríńtì 4 : 4 . ÀWỌN KAN SỌ PÉ ẹ̀tàn lásán ni pé Èṣù lágbára lórí àwọn èèyàn . Èṣù máa ń tan àwọn èèyàn jẹ , àmọ́ kò lè darí gbogbo èèyàn . Èṣù máa ń díbọ́n kó lè mú káwọn èèyàn gba ohun tó fẹ́ . — 2 Kọ́ríńtì 11 : 14 . Láwọn ìgbà míì , àwọn ẹ̀mí Èṣù máa ń darí àwọn èèyàn kan . — Mátíù 12 : 22 . Ọlọ́run lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti “ kọ ojú ìjà sí Èṣù . ” — Jákọ́bù 4 : 7 . “ Ta ni nínú yín tí ó fẹ́ kọ́ ilé gogoro kan tí kò ní kọ́kọ́ jókòó , kí ó sì gbéṣirò lé ìnáwó náà , láti rí i bí òun bá ní tó láti parí rẹ̀ ? ” ​ — LÚÙKÙ 14 : 28 . Kí ló túmọ̀ sí pé kéèyàn dàgbà dénú , kí sì ni Dáníẹ́lì ṣe tó fi hàn pé ó dàgbà dénú ? Báwo lo ṣe máa mọ̀ bí ìpinnu tó o ṣe láti ṣe ìrìbọmi bá tinú ọkàn rẹ wá ? Kí ni ìyàsímímọ́ , báwo sì ni ìyàsímímọ́ àti ìrìbọmi ṣe tan mọ́ra ? 1 , 2 . ( a ) Kí ló ń mú káwọn èèyàn Ọlọ́run láyọ̀ lónìí ? ( b ) Báwo làwọn òbí tó jẹ́ Kristẹni àtàwọn alàgbà ṣe lè ran àwọn ọ̀dọ́ lọ́wọ́ kí wọ́n lè lóye ohun tí ìrìbọmi túmọ̀ sí ? Àmọ́ , mo fẹ́ bi ẹ́ ní ìbéèrè kan , ‘ Kí nìdí tó o fi fẹ́ ṣèrìbọmi ? ’ ” ( Ka Lúùkù 14 : 27 - 30 . ) ( a ) Kí ni ọ̀rọ̀ Jésù àti Pétérù kọ́ wa nípa bí ìrìbọmi ti ṣe pàtàkì tó ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò , kí sì nìdí ? ( 2 ) Ṣó wá látọkàn mi pé kí n ṣèrìbọmi ? ( 3 ) Ṣé mo mọ ohun tó túmọ̀ sí láti ya ara mi sí mímọ́ fún Jèhófà ? 4 , 5 . ( a ) Kí nìdí tó fi jẹ́ pé kì í ṣe àwọn àgbàlagbà nìkan ni ìrìbọmi wà fún ? ( b ) Tá a bá sọ pé Kristẹni kan dàgbà dénú , kí ló túmọ̀ sí ? 6 , 7 . ( a ) Ìṣòro wo ni Dáníẹ́lì ní nígbà tó wà nílùú Bábílónì ? Ọ̀dọ́ kan tó dàgbà dénú kò ní máa ṣe bí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run ní Gbọ̀ngàn Ìjọba , kó wá dé iléèwé kó máa ṣohun táyé ń fẹ́ ( Wo ìpínrọ̀ 8 ) Kò ní máa ṣe bí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run ní Gbọ̀ngàn Ìjọba , kó wá dé iléèwé kó máa ṣohun táyé ń fẹ́ . 9 , 10 . ( a ) Bí ọ̀dọ́ kan bá ń ronú nípa ohun tó ṣe nípa àwọn àdánwò kan tó ṣẹ̀ṣẹ̀ dojú kọ , báwo nìyẹn ṣe lè ràn án lọ́wọ́ ? 11 , 12 . ( a ) Kí ló yẹ kó dá ẹnì kan tó fẹ́ ṣèrìbọmi lójú ? ( b ) Kí ló máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti máa fi ojú tí Jèhófà fi ń wo ìrìbọmi wò ó ? Báwo lo ṣe máa mọ̀ tó bá jẹ́ pé òótọ́ ló tọkàn ẹ wá pé kó o ṣèrìbọmi ? Ó kó àwọn ìwé mọ́tò náà fún ẹ , ó wá sọ pé : “ Mọ́tò yìí ti di tìẹ . ” 18 , 19 . ( a ) Báwo ni ohun tí Rose àti Christopher sọ ṣe fi hàn pé téèyàn bá ṣèrìbọmi , ó máa rí ọ̀pọ̀ ìbùkún gbà ? ( b ) Báwo ni àǹfààní tá a ní láti ṣèrìbọmi ṣe rí lára rẹ ? Ohun tí mo láǹfààní láti máa ṣe fún Jèhófà àti ètò rẹ̀ ń fún mi láyọ̀ . ” Kí ló túmọ̀ sí láti ‘ yí ẹnì kan lérò padà láti gbà gbọ́ ’ ? Kí ni “ ìṣe ìwà mímọ́ , ” kí sì ni “ àwọn iṣẹ́ ìfọkànsin Ọlọ́run ” ? Tó o bá ń ronú lórí ìràpadà , báwo nìyẹn ṣe máa mú kó o túbọ̀ mọ rírì ohun tí Jèhófà ṣe fún ẹ ? 1 , 2 . ( a ) Ṣàlàyé ìdí tí ìrìbọmi fi gba àròjinlẹ̀ . ( b ) Kí ló yẹ kó dá ẹnì kan lójú kó tó ṣèrìbọmi , kí sì nìdí ? Ẹ̀kọ́ wo làwọn ọ̀dọ́ lè rí kọ́ lára Tímótì ? Sọ bí ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ náà , “ Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan - an ? ” Arábìnrin kan tí ò tíì pé ọmọ ogún ọdún sọ pé : “ Kí n tó ṣèrìbọmi , mo kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì , mo sì rí i pé ìsìn tòótọ́ nìyí . Ojoojúmọ́ sì lohun tí mo gbà gbọ́ túbọ̀ ń dá mi lójú . ” Kí nìdí tá a fi lè retí pé kí Kristẹni kan tó ti ṣèrìbọmi máa ṣe ohun tó bá ẹ̀kọ́ tó ń kọ́ mu ? Bíbélì sọ pé : “ Ìgbàgbọ́ , bí kò bá ní àwọn iṣẹ́ , jẹ́ òkú nínú ara rẹ̀ . ” Kí ni “ ìṣe ìwà mímọ́ ” ? Bí àpẹẹrẹ , ronú lórí ìwà tó o hù lẹ́nu àìpẹ́ yìí . Kí ni díẹ̀ lára “ àwọn iṣẹ́ ìfọkànsin Ọlọ́run , ” ojú wo ló sì yẹ kó o máa fi wò wọ́n ? Kí ló lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti máa ṣe “ àwọn iṣẹ́ ìfọkànsin Ọlọ́run , ” báwo làwọn ọ̀dọ́ kan sì ṣe jàǹfààní látinú ẹ̀ ? “ Àwọn nǹkan wo lo máa ń ṣe tó o bá ń dá kẹ́kọ̀ọ́ ? ” “ Ṣó o máa ń lọ sóde ẹ̀rí báwọn òbí ẹ ò bá tiẹ̀ lọ ? ” Arábìnrin ọ̀dọ́ kan tó ń jẹ́ Tilda sọ pé : “ Àwọn ìbéèrè àtàwọn àbá náà ràn mí lọ́wọ́ láti pinnu ohun tí mo fẹ́ ṣe . Ọ̀kọ̀ọ̀kan lọwọ́ mi tẹ àwọn àfojúsùn mi , mo sì ṣèrìbọmi ní ọdún kan lẹ́yìn náà . ” Ṣé wàá ṣì máa sin Jèhófà bí dádì àti mọ́mì ẹ bá láwọn ò sìn ín mọ́ ? Kí nìdí tí ìyàsímímọ́ fi jẹ́ ìpinnu téèyàn máa ń dá ṣe ? 16 , 17 . ( a ) Kí lohun tó yẹ kó mú kéèyàn fẹ́ di Kristẹni ? ( b ) Àpèjúwe wo lo lè fi ṣàlàyé ìdí tó fi yẹ kó o mọ rírì ìràpadà ? Jésù wá dá a lóhùn pé : “ Kí ìwọ nífẹ̀ẹ́ Jèhófà Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn - àyà rẹ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti pẹ̀lú gbogbo èrò inú rẹ . ” ( Ka 2 Kọ́ríńtì 5 : 14 , 15 ; 1 Jòhánù 4 : 9 , 19 . ) 18 , 19 . ( a ) Kí nìdí tí kò fi yẹ kó o máa bẹ̀rù láti ya ara rẹ sí mímọ́ fún Jèhófà ? ( b ) Báwo ni ìjọsìn Jèhófà ṣe ń mú kí ìgbésí ayé rẹ dára sí i ? Kí ló máa ran ọ̀dọ́ kan tó fẹ́ ṣe ìyàsímímọ́ àti ìrìbọmi lọ́wọ́ kí àjọṣe tó ní pẹ̀lú Jèhófà lè lágbára sí i ? “ Báwo Ni Mo Ṣe Lè Mú Kí Àdúrà Mi Sunwọ̀n Sí i ? ” ​ — January – March 2009 “ Báwo Ni Mo Ṣe Lè Mú Kí Bíbélì Kíkà Gbádùn Mọ́ Mi ? ” ​ — April – June 2009 “ Irú Èèyàn Wo Gan - an Ni Mo Jẹ́ ? ” ​ — January – March 2012 “ Báwo Ni Mo Ṣe Lè Gbádùn Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ? ” ​ — April – June 2012 “ Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kí N Máa Lọ Sáwọn Ìpàdé Kristẹni ? ” ​ — July – September 2012 Báwo ni iṣẹ́ ìwàásù tá à ń ṣe ṣe ń fi hàn pé a wà níṣọ̀kan ? Kí ni díẹ̀ lára àwọn ohun tá a lè ṣe kí ìjọ wa lè máa wà níṣọ̀kan ? Báwo làwọn tọkọtaya ṣe lè ṣera wọn lọ́kan ? Kí ló fi hàn pé àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run máa ń fọwọ́ sowọ́ pọ̀ ? ( a ) Kí ló wúni lórí nípa àwọn Kristẹni tó wà ní ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 12 : 4 - 6 , 12 . ) Kí ni bá a ṣe ń ṣiṣẹ́ pa pọ̀ ti yọrí sí ? 8 , 9 . ( a ) Kí ni Pọ́ọ̀lù fi ṣàpèjúwe bó ti ṣe pàtàkì tó pé káwọn Kristẹni wà níṣọ̀kan ? ( b ) Báwo la ṣe lè máa fọwọ́ sowọ́ pọ̀ nínú ìjọ ? ( Ka Éfésù 4 : 15 , 16 . ) Báwo làwọn ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ ṣe ń pa kún ìṣọ̀kan tó wà nínú ìjọ ? Kí ló lè mú kí ìdílé túbọ̀ ṣera wọn lọ́kan ? Ìjọsìn Ìdílé máa ń mú kí tọmọdé tàgbà túbọ̀ nífẹ̀ẹ́ ara wọn ( Wo ìpínrọ̀ 12 , 15 ) Ṣe ni Sátánì ń gbógun ti ìdílé lónìí . Kí làwa èèyàn Jèhófà ń retí ? Ìtọ́sọ́nà wo ni Jèhófà fún àwọn èèyàn rẹ̀ nígbà ayé Nóà àti nígbà ayé Mósè ? Ìtọ́ni tuntun wo ni Ọlọ́run fún àwọn Kristẹni ? ? Báwo la ṣe lè fi hàn pé à ń wá ìtọ́sọ́nà Ọlọ́run ? 1 , 2 . ( a ) Ìkìlọ̀ wo ló ti gba ọ̀pọ̀ ẹ̀mí là ? Kí ló ti aráyé sọ́nà ìparun ? ( a ) Kí nìdí tó fi pọn dandan pé kí Ọlọ́run fún àwọn èèyàn ní ìtọ́ni tuntun lẹ́yìn Ìkún - omi ? ( b ) Báwo ni ìtọ́ni tuntun tí Ọlọ́run fáwọn èèyàn lẹ́yìn Ìkún - omi ṣe jẹ́ ká mọ ojú tó fi ń wo ẹ̀mí ? Kí la máa gbé yẹ̀ wò , kí sì nìdí ? Kí nìdí tó fi yẹ káwọn ọmọ Ísírẹ́lì pa Òfin Mósè mọ́ , ọwọ́ wo ló sì yẹ kí wọ́n fi mú un ? ( a ) Ṣàlàyé ìdí tí Jèhófà fi fáwọn èèyàn rẹ̀ ní ìtọ́sọ́nà . ( b ) Ọ̀nà wo ni Òfin gbà jẹ́ amọ̀nà fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì ? Kí nìdí tó fi yẹ ká ka àwọn ìlànà tó wà nínú Òfin Mósè sí pàtàkì ? Ohun mìíràn wo ló mú kí Ọlọ́run fún àwọn èèyàn rẹ̀ ní àwọn ìtọ́ni tuntun ? Lẹ́ẹ̀kan sí i , ipò táwọn èèyàn Ọlọ́run wà tún ti yàtọ̀ sí ti tẹ́lẹ̀ . Wọ́n di ìjọ Kristẹni , Jèhófà sì bá wọn dá májẹ̀mú tuntun . Ohun méjì wo ni “ òfin Kristi ” dá lé ? 13 , 14 . ( a ) Kí ni ìtumọ̀ “ àṣẹ tuntun ” tí Jésù pa fún wa ? ( b ) Kí la rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ Jésù ? ( Ka Jòhánù 13 : 34 , 35 . ) Ipò wo làwa èèyàn Ọlọ́run bára wa lónìí , báwo sì ni Jèhófà ṣe ń tọ́ wa sọ́nà ? Ojú wo ló yẹ ká máa fi wo àwọn ìtọ́ni tá à ń rí gbà ? Ṣó o máa ń wo àwọn ìtọ́ni yẹn bí èyí tó ń wá látọ̀dọ̀ Ọlọ́run ? Àwọn àkájọ ìwé wo la máa ṣí sílẹ̀ , báwo la sì ṣe máa jàǹfààní nínú wọn ? Àpilẹ̀kọ yìí tún máa jẹ́ ká mọ iṣẹ́ tí ìfaradà gbọ́dọ̀ ṣe pé pérépéré nínú gbogbo wa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan . Báwo ni àpẹẹrẹ Jẹ́fútà àti ọmọbìnrin rẹ̀ ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ kí ayé búburú yìí má bàa kó èèràn ràn wá ? Bí aáwọ̀ bá wà láàárín ìwọ àti ẹnì kan , àwọn ìlànà Bíbélì wo lo lè fi yanjú ẹ̀ ? Kí lo ti rí kọ́ nínú àpilẹ̀kọ yìí táá mú kó o máa yááfì àwọn nǹkan torí Ìjọba Ọlọ́run ? Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí Jẹ́fútà togun dé ? Wọ́n fẹ́ rí ojúure Jèhófà , ohunkóhun téèyàn bá sì yááfì kó lè rójú rere Ọlọ́run tó bẹ́ẹ̀ , ó jù bẹ́ẹ̀ lọ . 4 , 5 . ( a ) Àṣẹ wo ni Jèhófà pa fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì nígbà tí wọ́n dé Ilẹ̀ Ìlérí ? ( b ) Bí Sáàmù 106 ṣe sọ , kí ni àìgbọràn àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yọrí sí ? Àwọn nǹkan wo ló lè kéèràn ràn wá lónìí , kí la sì gbọ́dọ̀ ṣe ? ( a ) Kí làwọn èèyàn ṣe fún Jẹ́fútà ? 8 , 9 . ( a ) Àwọn ìlànà inú Òfin Mósè wo ló ṣeé ṣe kó ran Jẹ́fútà lọ́wọ́ ? ( b ) Kí ni Jẹ́fútà kà sí pàtàkì jù ? Ẹ̀kọ́ wo la lè rí kọ́ lára Jẹ́fútà ? Ẹ̀jẹ́ wo ni Jẹ́fútà jẹ́ fún Jèhófà , kí sì ni ẹ̀jẹ́ náà túmọ̀ sí ? Kí làwọn ọ̀rọ̀ tí Jẹ́fútà sọ nínú Àwọn Onídàájọ́ 11 : 35 jẹ́ ká mọ̀ nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀ ? Ẹ̀jẹ́ wo ni ọ̀pọ̀ lára wa jẹ́ fún Jèhófà , báwo la sì ṣe lè mú ẹ̀jẹ́ náà ṣẹ ? Kí ni ọmọbìnrin Jẹ́fútà sọ nígbà tó gbọ́ ìlérí tí bàbá rẹ̀ ṣe ? ( a ) Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ Jẹ́fútà àti ọmọbìnrin rẹ̀ ? ( b ) Báwo lọ̀rọ̀ inú Hébérù 6 : 10 - 12 ṣe fún ẹ níṣìírí láti máa yááfì àwọn nǹkan torí iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run ? Kí ló mú kí Jẹ́fútà borí àwọn àdánwò tó kojú ? Kí ló túmọ̀ sí láti “ jẹ́ kí ìfaradà ṣe iṣẹ́ rẹ̀ pé pérépéré ” ? 1 , 2 . ( a ) Kí la lè rí kọ́ nínú ìfaradà Gídíónì àtàwọn ọmọ ogun rẹ̀ ? Sátánì , ayé búburú yìí àti àìpé tiwa fúnra wa làwọn ọ̀tá tá à ń bá jà . Kí nìdí tá a fi lè sọ pé ìfẹ́ ló ń mú ká ní ìfaradà ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 13 : 4 , 7 . ) Ìfẹ́ tá a ní sáwọn ará wa ló ń mú ká máa fara da àwọn kùdìẹ̀ - kudiẹ wọn . Kí nìdí tó fi jẹ́ pé Jèhófà ló wà nípò tó dára jù lọ láti ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní ìfaradà ? Jèhófà ni “ Ọlọ́run tí ń pèsè ìfaradà àti ìtùnú . ” Jèhófà ṣèlérí pé tá a bá ké pe òun pé kóun ràn wá lọ́wọ́ ká lè fara dà á , òun á “ ṣe ọ̀nà àbájáde ” fún wa . Ṣàlàyé ìdí tá a fi nílò oúnjẹ tẹ̀mí ká tó lè ní ìfaradà . 8 , 9 . ( a ) Bí Jóòbù 2 : 4 , 5 ṣe sọ , kí ló yẹ ká máa rántí tá a bá dojú kọ àdánwò ? ( b ) Kí lo lè máa fojú inú yàwòrán ẹ̀ tó o bá dojú kọ àdánwò ? Ṣé Sátánì ti wá yí èrò tó ní nípa wa pa dà ? Kí nìdí tó fi yẹ ká máa ronú lórí àpẹẹrẹ “ àwọn tí wọ́n lo ìfaradà ” ? Kí la rí kọ́ lára àwọn kérúbù tí Jèhófà ní kó máa ṣọ́ ọgbà Édẹ́nì ? Báwo ni Jóòbù ṣe borí àwọn àdánwò tó kojú ? Jóòbù “ darúgbó , ó sì kún tẹ́rùn - tẹ́rùn fún ọjọ́ . ” — Jóòbù 42 : 10 , 17 . Bí 2 Kọ́ríńtì 1 : 6 ṣe sọ , báwo ni ìfaradà Pọ́ọ̀lù ṣe ran àwọn míì lọ́wọ́ ? ( Ka 2 Kọ́ríńtì 1 : 6 . ) 15 , 16 . ( a ) “ Iṣẹ́ ” wo ni ìfaradà gbọ́dọ̀ ṣe pé pérépéré ? ( b ) Sọ àpẹẹrẹ bá a ṣe lè “ jẹ́ kí ìfaradà ṣe iṣẹ́ rẹ̀ pé pérépéré . ” Bá a ṣe ń fara da àdánwò ń mú ká túbọ̀ máa hùwà tó yẹ Kristẹni ( Wo ìpínrọ̀ 15 , 16 ) 17 , 18 . ( a ) Sọ àpèjúwe kan tó fi hàn pé ó ṣe pàtàkì ká fara dà á títí dé òpin . ( b ) Bí òpin ti ń sún mọ́lé , kí ló dá wa lójú ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 11 ) Wàá tún rí bí àwọn èèyàn Ọlọ́run ṣe fara dà á láwọn ọjọ́ wa yìí . [ 2 ] ( ìpínrọ̀ 12 ) Bíbélì ò sọ iye àwọn kérúbù tí Jèhófà gbé iṣẹ́ yìí fún . “ Kí a má máa kọ ìpéjọpọ̀ ara wa sílẹ̀ . ” — HÉBÉRÙ 10 : 24 , 25 . bá a ṣe ń ran àwọn míì lọ́wọ́ tá a bá lọ sípàdé . 1 - 3 . ( a ) Báwo làwọn Kristẹni ṣe fi hàn pé àwọn ò fọ̀rọ̀ ìpàdé lílọ ṣeré ? ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí . ) ( b ) Kí la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Ìpàdé yẹn fún mi lókun , ó sì gbé ìgbàgbọ́ mi ró . ” Ọ̀nà wo ni bá a ṣe máa ń pàdé pọ̀ ń gbà ràn wá lọ́wọ́ láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà ? Báwo la ṣe ń rí ìṣírí gbà láwọn ìpàdé ìjọ , báwo ni wọ́n sì ṣe ń fún wa lókun ? ( Ka Ìṣe 15 : 30 - 32 . ) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì gan - an pé ká máa lọ sípàdé ? Táwọn ará bá ń rí wa nípàdé , tí wọ́n ń tẹ́tí sí ìdáhùn wa , tí wọ́n sì ń gbọ́ bá a ṣe ń kọrin , báwo nìyẹn ṣe máa ń ràn wọ́n lọ́wọ́ ? ( Tún wo àpótí náà “ Ara Máa Ń Tù Ú Lẹ́yìn Ìpàdé . ” ) 9 , 10 . ( a ) Ṣàlàyé bí ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ nínú Jòhánù 10 : 16 ṣe mú ká lóye ìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa pàdé pọ̀ pẹ̀lú àwọn ará wa . ( b ) Tá a bá ń lọ sípàdé déédéé , báwo la ṣe lè ran ẹnì kan tí ìdílé rẹ̀ ti pa tì lọ́wọ́ ? “ LẸ́NU àìpẹ́ yìí , ara mi ò yá , torí náà ó ṣòro fún mi láti máa lọ sípàdé . Àmọ́ , tí mo bá ṣáà ti débẹ̀ , mo máa ń gbádùn oúnjẹ tẹ̀mí tí Jèhófà ti pèsè sílẹ̀ . Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹsẹ̀ ń dùn mí , mo ní àrùn ọkàn , mo sì tún ní àìsàn ìtọ̀ ṣúgà , ara máa ń tù mí tí n bá máa fi kúrò níbẹ̀ . “ Nígbà tá a kọ́kọ́ kọ orin 68 níjọ wa , ìyẹn ‘ Àdúrà Ẹni Rírẹlẹ̀ , ’ ṣe ni mo bú sẹ́kún . Ẹ̀rọ tí mo fi ń gbọ́ràn jẹ́ kí n gbọ́ ohùn àwọn ará dáadáa , èmi náà sì kọ orin náà pẹ̀lú wọn . Tá a bá ń lọ sípàdé , báwo nìyẹn ṣe máa mú ká fún Jèhófà lóhun tó tọ́ sí i ? Jèhófà ń rí gbogbo ipá tá à ń sà ká lè wà ní gbogbo ìpàdé , ó sì mọyì rẹ̀ Ọ̀nà wo là ń gbà sún mọ́ Jèhófà àti Jésù nípàdé ? Tá a bá ń lọ sípàdé , báwo nìyẹn ṣe ń fi hàn pé a fẹ́ máa pa àṣẹ Ọlọ́run mọ́ ? 16 , 17 . ( a ) Báwo la ṣe mọ̀ pé ọwọ́ pàtàkì làwọn Kristẹni ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní fi mú pípé jọ pọ̀ déédéé ? ( b ) Báwo ló ṣe máa ń wu Arákùnrin George Gangas tó pé kó wà pẹ̀lú àwọn ará nípàdé ? Tí kò bá sídìí míì , ó máa ń wù mí pé kí n wà lára àwọn tó kọ́kọ́ dé Gbọ̀ngàn Ìjọba , kí n sì tún wà lára àwọn tó máa gbẹ̀yìn síbẹ̀ . Mo máa ń ní ayọ̀ àtọkànwá tí mo bá ń bá àwọn ará sọ̀rọ̀ . Tí mo bá wà láàárín wọn , ara mi máa ń balẹ̀ pẹ̀sẹ̀ , àfi bíi pé àárín ìdílé mi gan - an ni mo wà , nínú Párádísè tẹ̀mí . Báwo ló ṣe máa ń wù ẹ́ tó pé kó o wà nípàdé , kí lo sì ti pinnu pé wàá ṣe ? [ 2 ] ( ìpínrọ̀ 3 ) Wo àpótí náà , “ Ìdí Tó Fi Yẹ Ká Máa Lọ Sípàdé . ” Wọ́n máa ń gbọ́ ìhìn rere nígboro táwọn ará bá ń wàásù láwọn ibi tí èrò pọ̀ sí Apá òsì : Ilé àwọn ajẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé tó wà nílùú Zaragoza , lórílẹ̀ - èdè Sípéènì ; apá ọ̀tún : Bíbélì ìtumọ̀ Nácar - Colunga Mi ò mọ̀ bóyá ohun tó tọ́ ni mò ń ṣe àbí bẹ́ẹ̀ kọ́ . Mo rántí pé mo gbàdúrà pé , “ Jèhófà mo dúpẹ́ o , pé o ò jẹ́ kọ́rọ̀ mi sú ẹ , o sì tún fún mi láǹfààní láti kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ tó wà nínú Bíbélì , ohun tí mò ń fi gbogbo ìgbésí ayé wá nìyẹn . ” Kí làwọn ọmọ ìjọ mi àtàwọn ẹbí mi máa sọ ? ” Mo wá sọ fún un pé : “ Kí ni Ọlọ́run náà á sọ ? ” Oṣù méjì ṣáájú ọjọ́ tó máa ṣèrìbọmi ló kú . Kí ló yẹ ká ṣe tí kò bá rọrùn fún wa láti má ṣe dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun ? Kí la lè rí kọ́ lára àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà tí kò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun ? Báwo la ṣe lè máa pa àṣẹ Ọlọ́run àti ti ìjọba mọ́ ? A kì í dá sí ohunkóhun tó ní í ṣe pẹ̀lú òṣèlú . ( b ) Kí nìdí tó fi yẹ ká pinnu báyìí pé a ò ní dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun ? Èyí sì ti mú kó ṣeé ṣe fún wa láti wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run fáwọn èèyàn . Tí kò bá rọrùn láti má ṣe dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun , báwo la ṣe lè jẹ́ “ oníṣọ̀ọ́ra ” àti “ ọlọ́rùn - mímọ́ ” ? ( Ka Mátíù 10 : 16 , 17 . ) Kí ló yẹ ká máa ṣọ́ra fún tá a bá ń sọ̀rọ̀ ? Báwo la ṣe lè rí i dájú pé a ò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun tá a bá gbọ́ ohun táwọn ilé iṣẹ́ ìròyìn ń gbé jáde ? 12 , 13 . ( a ) Kí lèrò Jèhófà nípa àwa èèyàn ? ( b ) Báwo la ṣe máa mọ̀ tá a bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í fi orílẹ̀ - èdè wa yangàn ? Báwo ni àdúrà ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ , àpẹẹrẹ wo la sì rí nínú Bíbélì tó fi hàn pé àdúrà máa ń ràn wá lọ́wọ́ ? Báwo ni Bíbélì ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ ká má bàa dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun ? ( Tún wo àpótí náà “ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Fún Ìgbàgbọ́ Wọn Lókun . ” ) Kí la lè rí kọ́ lára àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà tí kò dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun ? ( Ka Dáníẹ́lì 3 : 16 - 18 . ) 18 , 19 . ( a ) Báwo làwọn ará inú ìjọ rẹ ṣe lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti má ṣe dá sí ọ̀rọ̀ òṣèlú tàbí ogun ? “ Bí mo ṣe ń ṣàṣàrò lórí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ bí Òwe 27 : 11 , Mátíù 26 : 52 àti Jòhánù 13 : 35 ti mú kí n túbọ̀ pinnu pé mi ò ní wọṣẹ́ ológun . Àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí náà ló sì fi mí lọ́kàn balẹ̀ nígbà tí wọ́n gbé mi lọ sílé ẹjọ́ . ” — Andriy , láti orílẹ̀ - èdè Ukraine . “ Mi ò gbà gbé ohun tí Aísáyà 2 : 4 sọ , ìyẹn sì ràn mí lọ́wọ́ láti má ṣe lọ́wọ́ sí ogun kódà nígbà tí wọ́n fẹ́ fipá mú mi . Ṣe ni mò ń fojú inú yàwòrán bí gbogbo nǹkan á ṣe pa lọ́lọ́ nínú ayé tuntun , nígbà tí kò ní sẹ́ni tó máa gbé ohun ìjà ogun láti fi pa ẹlòmíràn . ” — Wilmer , láti orílẹ̀ - èdè Kòlóńbíà . “ Ẹ . . . pa àlàáfíà mọ́ láàárín ara yín lẹ́nì kìíní - kejì . ” — MÁÀKÙ 9 : 50 . Ìmọ̀ràn wo ni Jésù fún wa ká lè máa fìfẹ́ yanjú aáwọ̀ ? Àwọn ìbéèrè wo ni Kristẹni kan lè bi ara rẹ̀ tó bá fẹ́ pinnu bó ṣe yẹ kó máa yanjú aáwọ̀ pẹ̀lú àwọn míì ? Báwo la ṣe lè fi ohun mẹ́ta tí Bíbélì là lẹ́sẹẹsẹ nínú Mátíù 18 : 15 - 17 sílò tá a bá fẹ́ yanjú aáwọ̀ ? Àwọn aáwọ̀ wo ni Bíbélì sọ̀rọ̀ wọn nínú Jẹ́nẹ́sísì , kí sì nìdí tó fi yẹ ká fiyè sí wọn ? Èrò burúkú wo ló ti tàn kálẹ̀ lónìí , kí ló sì ti yọrí sí ? Kí ni Jésù sọ pé kí àwọn tó ń tẹ́tí sí i ṣe kí aáwọ̀ má bàa máa wáyé ? 6 , 7 . ( a ) Kí nìdí tó fi yẹ ká tètè máa yanjú aáwọ̀ ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wo ló yẹ káwa ìránṣẹ́ Jèhófà bi ara wa ? Baba wa ọ̀run máa gbọ́ irú àdúrà tá a fẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ gbà . — 1 Jòh . 5 : 14 , 15 . Kí ló yẹ ká ṣe tẹ́nì kan bá ṣẹ̀ wá ? ( Ka Òwe 10 : 12 ; 1 Pétérù 4 : 8 . ) ( a ) Báwo lọ̀rọ̀ àbùkù tí wọ́n sọ nípa arábìnrin kan ṣe rí lára rẹ̀ ? ( b ) Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wo ló ran arábìnrin yìí lọ́wọ́ ? 11 , 12 . ( a ) Kí ló yẹ kí Kristẹni kan ṣe tó bá rò pé arákùnrin òun ‘ ní ohun kan lòdì sí òun ’ ? 14 , 15 . ( a ) Àwọn ìgbà wo la lè fi ìmọ̀ràn tó wà nínú Mátíù 18 : 15 - 17 sílò ? ( b ) Ìgbésẹ̀ mẹ́ta wo ni Jésù ní ká gbé , kí ló sì yẹ ká fi sọ́kàn tá a bá fẹ́ lọ bá ẹni tó ṣẹ̀ wá ? Kí ló fi hàn pé ìmọ̀ràn onífẹ̀ẹ́ lohun tí Jésù ní ká ṣe àti pé ó máa ń jẹ́ kí aáwọ̀ tètè yanjú ? Àwọn ìbùkún wo la máa gbádùn tá a bá ń “ wá àlàáfíà ” pẹ̀lú àwọn ẹlòmíì ? ohun tí wọ́n ń wàásù àti ìdí tí wọ́n fi ń wàásù ? Àwọn ìbéèrè wo ló jẹ yọ torí ohun tí Jésù sọ nínú Mátíù 24 : 14 ? Ní ìbámu pẹ̀lú ohun tó wà nínú Mátíù 28 : 19 , 20 , kí lohun mẹ́rin táwọn ọmọlẹ́yìn Jésù gbọ́dọ̀ ṣe ? Irú iṣẹ́ wo ni iṣẹ́ “ apẹja ènìyàn ” ? ( Ka Mátíù 4 : 18 - 22 . ) Àwọn ìbéèrè mẹ́rin wo ló pọn dandan ká dáhùn , kí sì nìdí ? Kí ló mú kó dá ẹ lójú pé ohun tó yẹ káwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà wàásù rẹ̀ gan - an ni wọ́n ń wàásù rẹ̀ ? Báwo la ṣe mọ̀ pé àwọn àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì kì í wàásù ohun tó yẹ kí wọ́n wàásù ? Kí ni kò yẹ kó jẹ́ ìdí tá a fi ń wàásù ? ( Ka Ìṣe 20 : 33 - 35 . ) Báwo làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe fi hàn pé ìfẹ́ tí wọ́n ní sí Jèhófà àtàwọn aládùúgbò wọn ló ń mú kí wọ́n wàásù ? Àwọn ọ̀nà wo ni Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ gbà wàásù ? Tó bá dọ̀rọ̀ ká wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run , ìyàtọ̀ wo ló wà láàárín àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà àti àwọn ṣọ́ọ̀ṣì Kirisẹ́ńdọ̀mù ? Àwọn nìkan ló ń wàásù pé Jésù ti di Ọba , ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso látọdún 1914 . Ibo ló yẹ kí iṣẹ́ ìwàásù náà gbòòrò dé ? Kí ló fi hàn pé àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ti mú àsọtẹ́lẹ̀ Jésù ṣẹ ní ti bó ṣe yẹ kí iṣẹ́ ìwàásù náà gbòòrò tó ? Ìkànnì wa wà ní èdè tó ju àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀rin [ 750 ] lọ . Báwo la ṣe mọ̀ pé ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run wà lára àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ? 17 , 18 . ( a ) Kí ló mú kó dá wa lójú pé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà là ń wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run lónìí ? ( b ) Kí ló mú kó ṣeé ṣe fún wa láti máa bá iṣẹ́ náà nìṣó ? Torí pé ohun tó yẹ ká wàásù là ń wàásù , ìyẹn ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run . Kí ló lè mú ká máa ronú pé àwọn ìtẹ̀jáde wa kan ò wúlò fún wa ? Àwọn àbá wo ló lè ràn wá lọ́wọ́ ká lè máa ka Bíbélì lọ́nà tó máa gbà yé wa dáadáa ? Báwo la ṣe lè jàǹfààní látinú kíka àwọn ìtẹ̀jáde tá a ṣe fáwọn ọ̀dọ́ àtèyí tá a ṣe fáwọn tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà ? 1 , 2 . ( a ) Ojú wo làwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi ń wo Bíbélì ? ( b ) Ìwé wo lo fẹ́ràn jù nínú Bíbélì ? 3 , 4 . ( a ) Ojú wo la fi ń wo àwọn ìtẹ̀jáde wa ? ( b ) Àwọn ìtẹ̀jáde wo ló wà fáwọn kan pàtó tá a tún máa ń rí gbà ? Kí ló dá wa lójú pé Jèhófà mọyì rẹ̀ ? Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa ka Bíbélì bíi pé àwa gan - an ni wọ́n ń bá sọ̀rọ̀ ? 8 , 9 . ( a ) Tá a bá ń ka Bíbélì , àwọn ìbéèrè wo ló yẹ ká bi ara wa ? ( b ) Kí làwọn ohun tí Jèhófà ní káwọn tó fẹ́ di alàgbà kúnjú ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ká mọ̀ nípa Jèhófà ? Báwo ni mo ṣe lè fi ohun tí mo kà yìí ran ẹlòmíì lọ́wọ́ ? ’ ( Ka 1 Tímótì 3 : 2 - 7 . ) 10 , 11 . ( a ) Tá a bá ń ka àwọn ohun tí Jèhófà ní káwọn tó fẹ́ di alàgbà kúnjú ìwọ̀n rẹ̀ , báwo la ṣe lè máa fi ohun tá a kà náà sílò nígbèésí ayé wa ? ( b ) Báwo la ṣe lè fi ran ẹlòmíì lọ́wọ́ ? 12 , 13 . ( a ) Irú àwọn ìwádìí wo la lè fi àwọn ohun èlò ìwádìí tá a ní ṣe ? ( b ) Sọ àpẹẹrẹ kan tó jẹ́ ká rí bí àwọn ìsọfúnni kan ṣe lè jẹ́ ká lóye àwọn ẹ̀kọ́ kan tá ò lè tètè rí nínú ẹsẹ Bíbélì tá à ń kà . Báwo làwọn ìtẹ̀jáde tó wà fáwọn ọ̀dọ́ ṣe ń ràn wọ́n lọ́wọ́ , báwo làwọn míì sì ṣe ń jàǹfààní látinú wọn ? Kí nìdí tó fi yẹ káwọn àgbàlagbà máa ka àwọn ìtẹ̀jáde tó wà fáwọn ọ̀dọ́ ? Kí làwọn ìtẹ̀jáde wa tún máa ń ran àwọn ọ̀dọ́ lọ́wọ́ láti ṣe ? ( Ka Oníwàásù 12 : 1 , 13 . ) Báwo Ni Mo Ṣe Lè Mú Kí Bíbélì Kíkà Gbádùn Mọ́ Mi ? ” Àǹfààní wo la máa rí tá a bá ń ka àwọn ìtẹ̀jáde tó wà fáwọn tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí ? Báwo la ṣe lè fi hàn pé a mọ rírì oúnjẹ tẹ̀mí tí Jèhófà ń pèsè fún wa ? Ipa wo làwọn ìpinnu tá a bá ṣe máa ní lórí wa àti àwọn ẹlòmíì ? ? Bí kò bá sí àṣẹ tàbí òfin kan pàtó nínú Bíbélì nípa ohun kan , báwo la ṣe lè mọ ohun tó máa múnú Jèhófà dùn ? Báwo la ṣe lè túbọ̀ mọ èrò Jèhófà ? Kí ni díẹ̀ lára àwọn òfin tó wà nínú Bíbélì , àǹfààní wo la sì ń rí bá a ṣe ń pa wọ́n mọ́ ? 2 , 3 . ( a ) Kí nìdí tó fi jẹ́ pé kì í ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ ni Bíbélì ti sọ ohun tá a gbọ́dọ̀ ṣe ? Ipa wo làwọn ìpinnu tá a bá ṣe lè ní lórí àwa fúnra wa àtàwọn míì ? Bí kò bá sí òfin pàtó kan nípa ohun tá a fẹ́ ṣe , báwo la ṣe lè mọ ohun tí Jèhófà fẹ́ ? Báwo ni Jésù ṣe mọ ohun tí Jèhófà fẹ́ kó ṣe ? ( Ka Mátíù 4 : 2 - 4 . ) Ṣàkíyèsí rẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà rẹ , òun fúnra rẹ̀ yóò sì mú àwọn ipa ọ̀nà rẹ tọ́ . Àwọn ìbéèrè wo la lè bi ara wa tá a bá ń ka Bíbélì tàbí tá à ń dá kẹ́kọ̀ọ́ ? Báwo ni ìpàdé àtàwọn ìtẹ̀jáde wa ṣe lè mú ká mọ èrò Jèhófà nípa àwọn nǹkan ? Sọ apẹẹrẹ kan tó jẹ́ ká rí i pé èèyàn lè ṣèpinnu tó bọ́gbọ́n mu téèyàn bá ronú nípa ojú tí Jèhófà á fi wo ọ̀rọ̀ náà . ( Ka Lúùkù 18 : 29 , 30 . ) Báwo lo ṣe lè mọ̀ bóyá inú Jèhófà á dùn sí irú àwọn aṣọ kan ? ( d ) Kí ló yẹ ká a ṣe tá a bá fẹ́ ṣèpinnu tó lágbára ? ( Ka Jẹ́nẹ́sísì 6 : 5 , 6 . ) Èrè wo la máa rí tá a bá ń ṣe àwọn ìpinnu tó ń múnú Jèhófà dùn ? Òótọ́ kan ni pé títí láé làá máa róhun tuntun kọ́ nípa Jèhófà . Kí nìdí tó fi yẹ ká máa ṣe àwọn ìyípadà tó yẹ kódà lẹ́yìn tá a ti ṣèrìbọmi ? Kí nìdí tí Jèhófà fi retí pé ká sapá ká lè borí àwọn kùdìẹ̀ - kudiẹ wa ? Kí ló yẹ ká ṣe kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lè máa tún ìgbésí ayé wa ṣe lójoojúmọ́ ? 1 - 3 . ( a ) Àwọn ìyípadà wo ló lè ṣòro fún wa láti ṣe lẹ́yìn tá a ṣèrìbọmi ? ( b ) Tó bá ṣòro fún wa láti ṣe àwọn ìyípadà , àwọn ìbéèrè wo la lè bi ara wa ? Báwo ni mo ṣe lè túbọ̀ jẹ́ kí Bíbélì máa tún ìgbésí ayé mi ṣe ? ’ Àwọn ìwà wo la ti fi sílẹ̀ ká tó ṣèrìbọmi , àmọ́ àwọn ìwà wo ló lè ṣòro fún wa láti borí ? 6 , 7 . ( a ) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé aláìpé ni wá , kí ló mú kó ṣeé ṣe fún wa láti di ọ̀rẹ́ Jèhófà ? ( b ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa lọ́ tìkọ̀ ká tó bẹ Jèhófà fún ìdáríjì ? Kí ló mú kó dá wa lójú pé a ṣì lè máa sapá láti gbé àkópọ̀ ìwà tuntun wọ̀ ? Kí la gbọ́dọ̀ ṣe tá a bá fẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run máa tún ìgbésí ayé wa ṣe , àwọn ìbéèrè wo la sì lè bi ara wa ? Kí nìdí tí Jèhófà fi retí pé ká sapá ká lè borí àwọn kùdìẹ̀ - kudiẹ wa ? Kí la lè ṣe tá a bá fẹ́ ní àwọn ànímọ́ tí Jèhófà nífẹ̀ẹ́ sí ? ( Wo àpótí náà “ Bíbélì àti Àdúrà Yí Ìgbésí Ayé Wọn Pa Dà . ” ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká rẹ̀wẹ̀sì tá ò bá tètè ní àwọn ànímọ́ tó yẹ Kristẹni ? Tá a bá jẹ́ olóòótọ́ , kí la lè máa fojú sọ́nà fún ? Kí ló mú kó dá wa lójú pé Bíbélì lágbára láti yí ìgbésí ayé wa pa dà ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 1 ) A ti yí orúkọ rẹ̀ pa dà . Russell : “ Bí mo ṣe ń gbàdúrà sí Jèhófà nígbà gbogbo tí mo sì ń ka Bíbélì lójoojúmọ́ ti ràn mí lọ́wọ́ . Ríronú lórí ìmọ̀ràn táwọn alàgbà gbà mí àti ohun tó wà nínú 2 Pétérù 2 : 11 ti mú kí n ṣàtúnṣe tó yẹ . ” Maria Victoria : “ Mo gbàdúrà sí Jèhófà pé kó jẹ́ kí n lè máa ṣọ́ ohun tí mò ń sọ . Mo wá rí i pé kò yẹ kí n bá àwọn tó ń ṣòfófó rìn mọ́ . Sáàmù 64 : 1 - 4 jẹ́ kí n mọ̀ pé á dáa kí n kíyè sára kó má lọ jẹ́ pé àwọn èèyàn á máa bẹ Jèhófà pé kó gba àwọn lọ́wọ́ mi ! Mo sì ti wá mọ̀ pé tí mi ò bá dẹ́kun àtimáa ṣòfófó , mi ò ní jẹ́ àpẹẹrẹ tó dáa fáwọn ẹlòmíì , màá sì máa kó ẹ̀gàn bá orúkọ Jèhófà . ” Linda : “ Mo máa ń ka àwọn ìwé àṣàrò kúkúrú wa dáadáa kí n lè mọ bí màá ṣe lò wọ́n . Bí mo ṣe ń bá àwọn tó mọ bá a ṣe ń wàásù lónírúurú ọ̀nà ṣiṣẹ́ lóde ẹ̀rí sì ti ràn mí lọ́wọ́ . Gbogbo ìgbà ni mo sì máa ń gbàdúrà sí Jèhófà pé kó ràn mí lọ́wọ́ . ” Gbogbo wa la máa ń ṣe ohun tó lè dun àwọn míì . bí Jèhófà ṣe ń pinnu àwọn tó máa mọ ? bí Ọlọ́run ṣe ń mọ àwọn tó fara wọn sábẹ́ rẹ̀ ? Báwo la ṣe lè fìwà jọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó ronú pìwà dà ? Báwo ni Jèhófà ṣe ń pinnu àwọn tó máa fà wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀ ? ( Ka 1 Sámúẹ́lì 16 : 7b . ) Tá a bá gbà pé Jèhófà ni Amọ̀kòkò wa , irú ojú wo ló yẹ ká máa fi wo ( a ) àwọn èèyàn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa ? Kò pẹ́ sígbà yẹn , mo bá ìdílé kan pàdé níbì kan tí mo lọ , bí ìdílé yẹn ṣe ń ṣe wú mi lórí gan - an . Kò pẹ́ ni mo wá mọ̀ pé Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni wọ́n , ó sì yà mí lẹ́nu gan - an ! Ìwà wọn jọ mí lójú débi pé mo gbà pé á dáa kí n tún inú rò nípa ojú tí mo fi ń wo àwọn Ẹlẹ́rìí . Mo wá rí i pé àìmọ̀kan àti àhesọ lásán ló fà á tí mo fi ń fojú burúkú wò wọ́n , mi ò mọ irú ẹni tí wọ́n jẹ́ gan - an . ” ( Ka Hébérù 12 : ​ 5 , 6 , 11 . ) Báwo ni Jèhófà ṣe ń kọ́ wa lónìí ? Báwo ni ẹ̀kọ́ náà á ṣe máa bá a nìṣó lọ́jọ́ iwájú ? A sì ti kọ́ bá a ṣe ń fìfẹ́ hàn sáwọn ẹlòmíì . Kí ni Jésù ṣe tó fi hàn pé ó ní sùúrù , ó sì mọṣẹ́ bíi ti Jèhófà , Amọ̀kòkò Ńlá náà ? ( Ka Sáàmù 103 : ​ 10 - 14 . ) Báwo ni Dáfídì ṣe fi hàn pé òun ṣeé mọ ? Báwo la ṣe lè fara wé e ? Báwo ni Jèhófà ṣe ń lo ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ àti ìjọ Kristẹni láti mọ wá ? Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Jèhófà lágbára láti fi wá mọ ohun tó fẹ́ , báwo ló ṣe ń fún wa lómìnira láti yan ohun tá a fẹ́ ? Báwo làwọn tá à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ṣe máa ń fi hàn pé àwọn fẹ́ kí Jèhófà mọ àwọn ? ( a ) Kí ló múnú rẹ dùn nípa bí Jèhófà , Amọ̀kòkò wa ṣe ń mọ wá ? ( b ) Àwọn nǹkan míì wo la tún máa jíròrò nípa bí Jèhófà ṣe ń mọ wá nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Awọn ìwà wo ló lè mú kéèyàn máa kọtí ikún sí ìmọ̀ràn Jèhófà ? Àwọn ànímọ́ wo ló yẹ ká ní kí Ọlọ́run lè máa mọ wá nìṣó ? Báwo làwọn òbí tó jẹ́ Kristẹni ṣe lè fi hàn pé Jèhófà ni Amọ̀kòkò àwọn ? Kí nìdí tí Ọlọ́run fi pe Dáníẹ́lì ní “ ọkùnrin fífani - lọ́kàn - mọ́ra gidigidi ” ? Ìwé Òwe 4 : 23 sọ pé , “ Ju gbogbo ohun mìíràn tí a ní láti ṣọ́ , fi ìṣọ́ ṣọ́ ọkàn - àyà rẹ , nítorí láti inú rẹ̀ ni àwọn orísun ìyè ti wá . ” ( Ka 2 Kíróníkà 26 : ​ 3 - 5 , 16 - 21 . ) Kí ló lè ṣẹlẹ̀ tá a bá gbà kí ìgbéraga wọ̀ wá lẹ́wù ? Arákùnrin kan sọ pé òun bá ìwàkiwà tòun débi pé ẹ̀rí ọkàn òun ò gún òun ní kẹ́ṣẹ́ mọ́ . 7 , 8 . ( a ) Báwo làwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe jẹ́ kí àìnígbàgbọ́ sọ wọ́n di alágídí ? ( b ) Kí la rí kọ́ nínú ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn ? Kí nìdí tó fi yẹ ká máa “ dán ” ara wa wò bóyá a ṣì wà nínú ìgbàgbọ́ , ọ̀nà wo la sì lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ? Kí ló máa mú ká dà bí amọ̀ rírọ̀ lọ́wọ́ Jèhófà ? Báwo ni Jèhófà ṣe máa ń lo ìjọ Kristẹni láti mọ ẹnì kan bí ipò onítọ̀hún bá ṣe gbà ? Àwọn ànímọ́ wo ni iṣẹ́ ìwàásù ń mú ká ní , àǹfààní wo nìyẹn sì máa ń mú wá ? Kí làwọn òbí gbọ́dọ̀ ṣe tí wọ́n bá fẹ́ kí àwọn ọmọ wọn gbẹ̀kọ́ ? Báwo làwọn òbí ṣe lè fi hàn pé àwọn fọkàn tán Ọlọ́run tó bá di pé a yọ ọmọ wọn lẹ́gbẹ́ ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 5 : ​ 11 , 13 . ) Kí nìdí tó fi yẹ ká jẹ́ kí Jèhófà máa darí gbogbo ohun tá a bá ń ṣe nígbèésí ayé wa ? Àǹfààní wo nìyẹn sì máa ṣe wá ? Ọ̀nà wo ni Jèhófà Ọlọ́run wa gbà jẹ́ “ Jèhófà kan ṣoṣo ” ? Báwo la ṣe lè máa sin Jèhófà lọ́nà táá fi hàn pé a gbà pé ó jẹ́ “ Jèhófà kan ṣoṣo ” ? Kí la lè ṣe láti pa kún àlàáfíà àti ìṣọ̀kan tó wà láàárín wa ? ( b ) Kí nìdí tí Mósè fi sọ̀rọ̀ yìí ? 4 , 5 . ( a ) Kí ni ọ̀rọ̀ náà “ Jèhófà kan ṣoṣo ” túmọ̀ sí ? ( b ) Báwo ni Jèhófà ṣe yàtọ̀ sáwọn ọlọ́run míì ? Báwo ni Jèhófà ṣe fi hàn pé òun jẹ́ “ ọ̀kan ṣoṣo ” ? 8 , 9 . ( a ) Kí ni Jèhófà ní kí àwọn olùjọsìn rẹ̀ ṣe ? ( b ) Báwo ni Jésù ṣe fi hàn pé ọ̀rọ̀ pàtàkì ni Mósè sọ ? ( Ka Máàkù 12 : ​ 28 - 31 . ) 10 , 11 . ( a ) Báwo la ṣe lè fi hàn pé Jèhófà nìkan là ń sìn ? ( b ) Báwo làwọn ọ̀dọ́ Hébérù tó wà ní Bábílónì ṣe fi hàn pé Jèhófà nìkan làwọn ń sìn ? Torí pé Jèhófà nìkan là ń sìn , kí la gbọ́dọ̀ ṣọ́ra fún ? Àwọn nǹkan wo ló lè paná ìfẹ́ tá a ní fún Ọlọ́run ? Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi rán àwọn Kristẹni létí pé Jèhófà kan ṣoṣo ni wọ́n ń sìn ? 16 , 17 . ( a ) Àsọtẹ́lẹ̀ wo ló ń nímùúṣẹ lónìí , kí sì ni àbájáde rẹ̀ ? ( b ) Kí ló lè ba ìṣọ̀kan tó wà láàárín wa jẹ́ ? 18 , 19 . ( a ) Ìmọ̀ràn wo ló wà nínú Éfésù 4 : ​ 1 - 3 ? ( b ) Kí la lè ṣe láti mú kí ìjọ wà ní ìṣọ̀kan ? Kí la gbọ́dọ̀ máa ṣe ká lè fi hàn pé “ Jèhófà Ọlọ́run wa , Jèhófà kan ṣoṣo ni ” ? Ọ̀pọ̀ àwọn abúlé tí wọ́n ti ń pẹja ló wà ní etíkun Trinidad àti Tobago . Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń lo àǹfààní yẹn láti wàásù fún àwọn apẹja tí wọ́n bá rí Báwo ni Bíbélì ṣe fi hàn pé gbogbo wa jẹ́ aláìpé ? Kí la lè ṣe nípa àwọn àṣìṣe wa àti tàwọn ẹlòmíì ? Kí ni Bíbélì sọ tẹ́lẹ̀ nípa bí àwa èèyàn Jèhófà ṣe máa pọ̀ tó ? ( Ka Míkà 4 : ​ 1 , 3 . ) Èyí mú kí “ ọrùn [ wa ] mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn gbogbo . ” ​ —⁠ Ìṣe 20 :⁠ 26 . Kí nìdí tí ìtẹ̀síwájú tó ń bá àwọn èèyàn Jèhófà fi jọni lójú ? Kí ló lè mú káwọn kan ṣe ohun tó dùn wá ? ( Ka Róòmù 5 : ​ 12 , 19 . ) Ká sọ pé ìgbà ayé Élì àtàwọn ọmọ rẹ̀ lo gbáyé , kí lo ò bá ṣe ? Báwo ni Élì ṣe gbọ̀jẹ̀gẹ́ fáwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ? Ẹ̀ṣẹ̀ burúkú wo ni Dáfídì dá , kí sì ni Ọlọ́run ṣe nípa rẹ̀ ? ( a ) Báwo ni àpọ́sítélì Pétérù ṣe yẹhùn lórí ohun tó sọ ? ( b ) Kí nìdí tí Jèhófà fi ń bá a lọ láti lo Pétérù fún ọ̀pọ̀ iṣẹ́ kódà lẹ́yìn tó ṣàṣìṣe ? Kí ló mú kó dá ẹ lójú pé onídàájọ́ òdodo ni Ọlọ́run ? Kí ni Jésù mọ̀ nípa àṣìṣe tí Júdásì Ísíkáríótù àti Pétérù ṣe ? Àsọtẹ́lẹ̀ wo ni Bíbélì sọ nípa àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà lákòókò yìí ? Ọwọ́ wo ló yẹ ká fi mú àṣìṣe àwọn míì ? 13 , 14 . ( a ) Kí nìdí tó fi yẹ ká máa ṣe sùúrù fún ara wa ? ( b ) Ìlérí wo ló yẹ ká máa rántí ? Kí ni Jésù ní ká ṣe táwọn míì bá ṣe ohun tó dùn wá ? Kí lo máa ṣe táwọn míì bá ṣẹ̀ ọ́ ? ( Ka Mátíù 5 : ​ 23 , 24 . ) Àní gẹ́gẹ́ bí Jèhófà ti dárí jì yín ní fàlàlà , bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin pẹ̀lú máa ṣe . ” Kò ṣòro rárá láti dáhùn àwọn ìbéèrè yẹn . Ẹ̀yin náà ẹ wo ohun tí Bíbélì sọ nípa ọgbọ́n àti ìfòyemọ̀ . Ìwé Òwe 3 : ​ 13 - 15 sọ pé : “ Aláyọ̀ ni ènìyàn tí ó ti wá ọgbọ́n rí , àti ènìyàn tí ó ní ìfòyemọ̀ , nítorí níní in gẹ́gẹ́ bí èrè sàn ju níní fàdákà gẹ́gẹ́ bí èrè , níní in gẹ́gẹ́ bí èso sì sàn ju níní wúrà pàápàá . Ó ṣe iyebíye ju iyùn , a kò sì lè mú gbogbo àwọn nǹkan mìíràn tí í ṣe inú dídùn rẹ bá a dọ́gba . ” Àpẹẹrẹ rere ni Jésù Kristi jẹ́ tó bá di pé ká jẹ́ olóòótọ́ . Torí pé èmi ni máníjà iléeṣẹ́ náà , ọ̀gá mi retí pé kí n máa fáwọn aṣojú ìjọba ní ẹ̀gúnjẹ kí wọ́n lè gbójú fo èrú tá à ń ṣe nílé iṣẹ́ náà . Torí náà , ojú oníjìbìtì làwọn tá a jọ ń ṣiṣẹ́ àtàwọn aṣojú ìjọba fi ń wò mí . Nígbà tí mo kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ , mo jẹ́ kí ọ̀gá mi mọ̀ pé mi ò ní lè máa ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ mọ́ , bí mo ṣe fiṣẹ́ náà sílẹ̀ nìyẹn bó tilẹ̀ jẹ́ pé owó gidi ni wọ́n ń san fún mi . Àwọn ọmọkùnrin mi méjèèjì rí ẹ̀kọ́ rere kọ́ lára mi , mo sì ti láǹfààní láti máa bójú tó àwọn iṣẹ́ kan nínú ìjọ . Àwọn aṣojú ìjọba tó máa ń ṣàyẹ̀wò àkọsílẹ̀ owó orí àtàwọn tá a jọ ń ṣòwò sì ti wá mọyì mi torí wọ́n mọ̀ pé mo ti di olóòótọ́ èèyàn báyìí . ” Rúùtù tẹ̀ lé ìyá ọkọ rẹ̀ lọ sí Ísírẹ́lì , níbi táá ti lè máa jọ́sìn Ọlọ́run tòótọ́ . 1 : 16 . Ọ̀nà tó ga lọ́lá jù lọ wo ni Jèhófà gbà fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí aráyé ? Báwo la ṣe lè fi hàn pé inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí là ń jẹ́ kó darí wa dípò ẹ̀ṣẹ̀ ? Àwọn nǹkan wo là ń gbádùn torí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Jèhófà ? 1 , 2 . ( a ) Sọ àkàwé tí Jésù ṣe nípa ọkùnrin kan tó ní ọgbà àjàrà . ( b ) Báwo ni ìtàn yìí ṣe jẹ́ ká mọ ohun tó túmọ̀ sí láti jẹ́ ọ̀làwọ́ àtẹni tó ń fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn ? Kí ló dé tí ẹ̀ ń jowú torí pé mò ń ṣoore fáwọn èèyàn ? ’ — Mát . ( Ka 2 Kọ́ríńtì 6 : 1 . ) Kí nìdí tí Jèhófà fi fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí aráyé ? Kí ló túmọ̀ sí nígbà tí Bíbélì sọ pé Jèhófà ń fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí rẹ̀ hàn ní “ onírúurú ọ̀nà ” ? Àpọ́sítélì Pétérù sọ pé : “ Níwọ̀n yíyẹ gẹ́gẹ́ bí olúkúlùkù ti rí ẹ̀bùn kan gbà , ẹ lò ó fún ṣíṣe ìránṣẹ́ fún ara yín lẹ́nì kìíní - kejì gẹ́gẹ́ bí ìríjú àtàtà fún inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run tí a fi hàn ní onírúurú ọ̀nà . ” Àpọ́sítélì Jòhánù sọ pé : “ Gbogbo wa ti gbà láti inú ẹ̀kún rẹ̀ , àní inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí lórí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí . ” Àǹfààní wo là ń rí torí pé Jèhófà ń fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí wa ? ( Ka 1 Jòhánù 1 : 8 , 9 . ) Kí ni inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run ń mú ká gbádùn ? Àwọn àǹfààní tá à ń rí bí Jèhófà ṣe ń fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí wa : À ń gbọ́ ìhìn rere ( Wo ìpínrọ̀ 11 ) Kí làwọn ẹni àmì òróró ń ṣe kí àwọn “ àgùntàn mìíràn ” lè di olódodo ? A lè gbàdúrà sí Ọlọ́run ( Wo ìpínrọ̀ 12 ) Báwo ni inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí ṣe kan àdúrà ? Báwo ni inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí ṣe ń ràn wá lọ́wọ́ “ ní àkókò tí ó tọ́ ” ? Báwo ni inú rere Jèhófà ṣe ń tù wá nínú ? Ìrètí wo la ní lọ́lá inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run ? ( Ka Sáàmù 49 : 7 , 8 . ) Báwo làwọn Kristẹni ayé ọjọ́un ṣe ṣi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run lò ? Kí ló yẹ ká ṣe torí pé Jèhófà ń fi inú rere hàn sí wa ? Iṣẹ́ pàtàkì wo la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 2 ) Wo ọ̀rọ̀ náà “ Undeserved kindness ” nínú àfikún tá a pè ní “ Glossary of Bible Terms ” nínú Bíbélì Ìwé Mímọ́ ní Ìtumọ̀ Ayé Tuntun tá a tún ṣe lédè Gẹ̀ẹ́sì lọ́dún 2013 . “ Jẹ́rìí kúnnákúnná sí ìhìn rere nípa inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run . ” — ÌṢE 20 : 24 . Tá a bá mọyì inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Jèhófà , kí ló yẹ ká ṣe ? Báwo ni “ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run ” ṣe mú ká mọ̀ nípa inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run ? Báwo ni Jèhófà ṣe máa fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí aráyé nínú ayé tuntun ? Báwo ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ṣe fi hàn pé òun mọyì inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run ? TỌKÀNTỌKÀN ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi sọ pé inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí tí Ọlọ́run fi hàn sí òun kò já sí asán . ( Ka 1 Kọ́ríńtì 15 : 9 , 10 . ) ( Ka Éfésù 3 : 5 - 8 . ) Kí nìdí tá a fi lè sọ pé ọ̀kan náà ni “ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run ” àti ìhìn rere nípa “ inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run ” ? Ǹjẹ́ a lè sọ pé ìhìn rere nípa inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run là ń kéde tá a bá sọ fáwọn èèyàn nípa ìràpadà ? Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé kí aráyé bá Ọlọ́run rẹ́ ? Àpọ́sítélì Jòhánù sọ pé : “ Ẹni tí ó bá ń lo ìgbàgbọ́ nínú Ọmọ ní ìyè àìnípẹ̀kun ; ẹni tí ó bá ń ṣàìgbọràn sí Ọmọ kì yóò rí ìyè , ṣùgbọ́n ìrunú Ọlọ́run wà lórí rẹ̀ . ” 9 , 10 . ( a ) Iṣẹ́ wo ni Kristi gbé lé àwọn ẹni àmì òróró tó jẹ́ arákùnrin rẹ̀ lọ́wọ́ ? Nítorí náà , àwa jẹ́ ikọ̀ tí ń dípò fún Kristi , bí ẹni pé Ọlọ́run ń pàrọwà nípasẹ̀ wa . Kí nìdí tó fi jẹ́ ìròyìn ayọ̀ pé àwọn èèyàn lè gbàdúrà sí Jèhófà ? Ìdí tí ọ̀pọ̀ èèyàn fi ń gbàdúrà ni pé kí ara lè tù wọ́n , wọ́n ò gbà pé Ọlọ́run ń gbọ́ àdúrà . Ó yẹ kírú àwọn èèyàn bẹ́ẹ̀ mọ̀ pé “ Olùgbọ́ àdúrà ” ni Jèhófà . Dáfídì tó wà lára àwọn tó kọ Sáàmù sọ pé : “ Ìwọ Olùgbọ́ àdúrà , àní ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn ènìyàn ẹlẹ́ran ara gbogbo yóò wá . Jésù sọ fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé : “ Bí ẹ bá béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi , èmi yóò ṣe é dájúdájú . ” 13 , 14 . ( a ) Àwọn àǹfààní àgbàyanu wo làwọn ẹni àmì òróró ṣì máa gbádùn lọ́jọ́ iwájú ? ( b ) Iṣẹ́ ńlá wo làwọn ẹni àmì òróró máa ṣe fún aráyé ? Báwo ni Jèhófà ṣe máa fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sáwọn “ àgùntàn mìíràn ” lọ́jọ́ iwájú ? Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ti kú láìmọ Jèhófà Ọlọ́run . Jòhánù sọ pé : “ Mo sì rí àwọn òkú , ẹni ńlá àti ẹni kékeré , tí wọ́n dúró níwájú ìtẹ́ náà , a sì ṣí àwọn àkájọ ìwé sílẹ̀ . A sì ṣèdájọ́ àwọn òkú láti inú nǹkan tí a kọ sínú àwọn àkájọ ìwé náà ní ìbámu pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ wọn . Òkun sì jọ̀wọ́ àwọn òkú tí ń bẹ nínú rẹ̀ lọ́wọ́ , ikú àti Hédíìsì sì jọ̀wọ́ àwọn òkú tí ń bẹ nínú wọn lọ́wọ́ , a sì ṣèdájọ́ wọn lẹ́nì kọ̀ọ̀kan ní ìbámu pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ wọn . ” Kókó wo ló yẹ ká máa fi sọ́kàn tá a bá ń wàásù fáwọn èèyàn ? Bíbélì sọ pé : “ A óò dá ìṣẹ̀dá tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìsọdẹrú fún ìdíbàjẹ́ , yóò sì ní òmìnira ológo ti àwọn ọmọ Ọlọ́run . ” Pẹ̀lúpẹ̀lù , ó wí pé : “ Kọ̀wé rẹ̀ , nítorí pé ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ṣeé gbíyè lé , wọ́n sì jẹ́ òótọ́ . ” Tá a bá ń fìtara wàásù ìhìn rere yìí fáwọn èèyàn , ṣe là ń polongo inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Jèhófà ! “ Ẹ máa wá ìjọba [ Ọlọ́run ] nígbà gbogbo , a ó sì fi nǹkan wọ̀nyí kún un fún yín . ” — LÚÙKÙ 12 : 31 . Ìyàtọ̀ wo ló wà láàárín àwọn ohun tá a fẹ́ àtàwọn ohun tá a nílò ? Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa wá bá a ṣe máa kó ohun ìní jọ ? Kí ló mú kó dá ẹ lójú pé Jèhófà máa pèsè àwọn ohun tó o nílò lójoojúmọ́ fún ẹ ? Báwo ni Sátánì ṣe máa ń lo “ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ojú ” ? Rántí ìkìlọ̀ tí àpọ́sítélì Jòhánù fún wa pé : ‘ Ayé àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ ń kọjá lọ . ” Kí ló lè ṣẹlẹ̀ sáwọn tó ń fi gbogbo ìgbésí ayé wọn kó ohun ìní jọ ? Kí la máa jíròrò báyìí , kí sì nìdí ? 8 , 9 . ( a ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa ṣàníyàn jù nípa àwọn nǹkan tá a nílò ? ( b ) Kí ni Jésù mọ̀ nípa àwa èèyàn àtàwọn ohun tá a nílò ? Nígbà tí Jésù kọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ bí wọ́n á ṣe máa gbàdúrà , kí ló sọ pé ó yẹ kó ṣe pàtàkì jù nígbèésí ayé wọn ? Kí la rí kọ́ látinú bí Jèhófà ṣe ń tọ́jú àwọn ẹyẹ ? Ẹ jẹ́ ká “ ṣàkíyèsí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run . ” Kí ló fi hàn pé a níye lórí ju àwọn ẹyẹ lọ ? ( Fi wé Lúùkù 12 : 6 , 7 . ) 15 , 16 . ( a ) Kí la rí kọ́ látinú bí Jèhófà ṣe ń bójú tó àwọn òdòdó ? ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí . ) ( b ) Àwọn ìbéèrè wo ló yẹ ká bi ara wa , kí sì nìdí ? Kí ni Jèhófà mọ̀ nípa ẹnì kọ̀ọ̀kan wa , kí ló sì máa ṣe nípa rẹ̀ ? Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa da ara wa láàmú nípa ohun tó lè ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú ? Ṣé o lè máa ṣọ́wó ná tàbí kó o dín iṣẹ́ rẹ kù kó o lè ráyè fún iṣẹ́ ìsìn Jèhófà ? ( a ) Kí làwọn nǹkan tó o lè máa lé lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà ? ( b ) Báwo lo ṣe lè mú kí ohun ìní díẹ̀ tẹ́ ẹ lọ́rùn ? Kí ló máa mú kó o túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà ? Ṣàpèjúwe ìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká wà lójúfò sí àkókò tá a wà yìí àtohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyìíká wa . Kí nìdí tí Jésù fi sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé kí wọ́n máa ṣọ́nà ? Kí nìdí tá a fi ń fọwọ́ pàtàkì mú ìkìlọ̀ Jésù ? ( a ) Kí ló mú ká gbà pé Jésù ti mọ ìgbà tí ogun Amágẹ́dọ́nì máa jà ? ( b ) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a ò mọ ìgbà tí ìpọ́njú ńlá máa bẹ̀rẹ̀ , kí ló dá wa lójú ? Nígbà tí Jésù wà láyé , ó sọ pé : “ Ní ti ọjọ́ àti wákàtí yẹn , kò sí ẹnì kankan tí ó mọ̀ ọ́n , àwọn áńgẹ́lì ọ̀run tàbí Ọmọ pàápàá kò mọ̀ ọ́n , bí kò ṣe Baba nìkan . ” ( Ka Hábákúkù 2 : 1 - 3 . ) Sọ àpẹẹrẹ kan tó fi hàn pé àsọtẹ́lẹ̀ Jèhófà máa ń ṣẹ lásìkò pàtó tó ní lọ́kàn . Àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Jèhófà máa ń ṣẹ lásìkò pàtó tó ní lọ́kàn . Nígbà tó yá , Jèhófà sọ fún Ábúráhámù pé : “ Kí o mọ̀ dájú pé irú - ọmọ rẹ yóò di àtìpó ní ilẹ̀ kan tí kì í ṣe tiwọn , wọn yóò sì ní láti sìn wọ́n , àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣẹ́ wọn níṣẹ̀ẹ́ dájúdájú fún irínwó [ 400 ] ọdún . ” Kí ló jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà máa dáàbò bo àwọn èèyàn rẹ̀ ? 7 , 8 . ( a ) Kí ni iṣẹ́ àwọn ẹ̀ṣọ́ láyé àtijọ́ , ẹ̀kọ́ wo sì ni èyí kọ́ wa ? ( b ) Kí ló lè ṣẹlẹ̀ táwọn ẹ̀ṣọ́ bá sùn lọ lẹ́nu iṣẹ́ wọn ? Kí ni ọ̀pọ̀ èèyàn ò mọ̀ lónìí ? 10 , 11 . ( a ) Kí ló yẹ ká ṣọ́ra fún , kí sì nìdí ? ( b ) Kí ló mú kó o gbà pé Èṣù ti fọ́ àwọn èèyàn lójú kí wọ́n má bàa kọbi ara sí àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì ? Kí nìdí tí kò fi yẹ ká jẹ́ kí Èṣù tàn wá jẹ ? Jésù kìlọ̀ pé : “ Ẹ wà ní ìmúratán , nítorí pé ní wákàtí tí ẹ kò ronú pé ó lè jẹ́ ni Ọmọ ènìyàn ń bọ̀ . ” Àkóbá wo ni ẹ̀mí ayé ń ṣe fún àwọn èèyàn ? Ìkìlọ̀ wo ló wà nínú Lúùkù 21 : 34 , 35 ? ( Ka Lúùkù 21 : 34 , 35 . ) Báwo ni ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wọn ṣe lè ṣẹlẹ̀ sáwa náà ? Báwo la ṣe lè wà lójúfò bí Jésù ṣe sọ nínú Lúùkù 21 : 36 ? 4 : 7 . Báwo la ṣe lè gbara dì fún ohun tó ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 14 ) Wo orí 21 nínú ìwé Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso ! Lọ́jọ́ kan tá a wà ní àpéjọ , arákùnrin kan bi mí pé ṣé màá fẹ́ wàásù . Bí àwa méjèèjì ṣe lọ síbi tá a ti máa wàásù nìyẹn . Inú Gbọ̀ngàn kan ni wọ́n ti ń ṣèpàdé , ọ̀kan lára àwọn arábìnrin tó wà nípàdé náà sì máa ń fi Bíbélì àti ìwé Duru Ọlọrun kọ́ àwa ọmọdé lẹ́kọ̀ọ́ . Nígbà tí mo wà lọ́dọ̀ọ́ , mo gbádùn kí n máa fi Bíbélì kọ́ àwọn èèyàn nípa ohun tí Ọlọ́run máa ṣe fáráyé . Arákùnrin náà wá ní ká dúró díẹ̀ , ó ní ká jókòó sórí igi gẹdú kan . Lẹ́yìn náà , ó sọ pé : “ Ta ló fún ẹ láṣẹ láti máa pèèyàn ní ewúrẹ́ ? Jèhófà ló máa ṣèyẹn , tiwa ni pé ká wàásù ìhìn rere fáwọn èèyàn . ” Mo tún kẹ́kọ̀ọ́ lára arákùnrin míì pé téèyàn bá fẹ́ máa láyọ̀ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ , àfi kó máa ní sùúrù , kó sì ní ìfaradà . Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún , sùúrù rẹ̀ sèso rere torí pé ìyàwó ẹ̀ ṣèrìbọmi , ó sì di Ẹlẹ́rìí Jèhófà . Lẹ́yìn tógun parí , mo lọ ṣe aṣáájú - ọ̀nà lápá gúúsù orílẹ̀ - èdè Ireland fún ọdún méjì . A ò mọ̀ pé àwọn àlùfáà lẹ́nu gan - an níbẹ̀ , wọ́n máa ń dá àwọn èèyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ tí wọ́n bá gbàwé wa . Inú mi dùn gan - an torí pé mi ò wọ ọkọ̀ ojú omi rí . Àwọn erékùṣù yìí fẹ̀ gan - an , tá a bá mú un láti àwọn erékùṣù tó wà nítòsí Puerto Rico sí orílẹ̀ - èdè Trinidad , ó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ọgọ́rùn mẹ́jọ [ 800 ] kìlómítà . Àwa míṣọ́nnárì tá a jọ ń lo ọkọ̀ ojú omi Sibia rèé ( láti apá òsì sí apá ọ̀tún ) : Ron Parkin , Dick Ryde , Gust Maki , àti Stanley Carter Ọ̀pọ̀ ìgbà ni wọ́n máa ń fún wa ní ẹja tútù , èso píà àti ẹ̀pà . Wọ́n á gbé àtùpà elépo wọn dání , iná àtùpà náà á wá máa ṣe yẹ - yẹ̀ - yẹ . Inú wa dùn gan - an pé ọ̀pọ̀ wọn ló ṣe iṣẹ́ náà bí iṣẹ́ . Nígbà tá a débẹ̀ , mo pàdé arábìnrin kan tó ń jẹ́ Maxine Boyd . Lẹ́yìn tá a lo ọ̀sẹ̀ mẹ́ta , mo kọnu ìfẹ́ sí i , ó sì gbà . Ìgbà tó máa di ọ̀sẹ̀ kẹfà , a ṣègbéyàwó . Lẹ́yìn ìgbéyàwó wa , ètò Ọlọ́run ní káwa méjèèjì máa sìn lórílẹ̀ - èdè Puerto Rico , bó ṣe di pé mi ò bá wọn pa dà nínú ọkọ̀ ojú omi tuntun tá a pààrọ̀ nìyẹn . Bí àpẹẹrẹ , ní abúlé kan tí wọ́n ń pè ní Potala Pastillo , ìdílé méjì kan wà tí wọ́n jẹ́ ará , tí wọ́n sì láwọn ọmọ tó pọ̀ . Tá a bá bẹ ìjọ wọn wò , mo máa ń fi fèrè kọrin fún àwọn ọmọ náà . A ra bàtà fún un , ó sì bá wa jáde . Bí arábìnrin kan tó ṣẹ̀ṣẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ jáde ní Ilé Ẹ̀kọ́ Gílíádì ṣe wá kí wa nìyẹn , ó ń múra àtilọ sí orílẹ̀ - èdè Ecuador tí wọ́n ti ní kó lọ máa sìn . Ó wá bi wá pé : “ Ẹ ò mọ̀ mí mọ́ o ? Ọmọ ọjọ́sí ọ̀hún rèé . ” Níbẹ̀rẹ̀ , èmi àti Arákùnrin Lennart Johnson la máa ń ṣe èyí tó pọ̀ jù lára iṣẹ́ náà . Iṣẹ́ mímúra àpéjọ yẹn wọ̀ mí lọ́rùn gan - an . Ó pè mí , ó bá mi wí gan - an , ó ní mi ò mọṣẹ́ mi níṣẹ́ . Èmi àti mọ́mì mi nìkan la rí òtítọ́ , dádì mi ò ṣètò . Ó dùn mí gan - an pé Maxine ìyàwó mi ṣaláìsí lọ́dún 2011 . Àmọ́ ọkàn mi balẹ̀ pé màá rí i nígbà àjíǹde . Èyí ò rọrùn fún mi torí pé ọgọ́ta [ 60 ] ọdún gbáko ni mo ti lò lórílẹ̀ - èdè Puerto Rico . Àwọn kan tó máa ń wá sọ́dọ̀ mi máa ń fẹ́ kí n gbà wọ́n níyànjú nípa ọ̀rọ̀ ìdílé àtàwọn ìṣòro tí wọ́n ní . Iṣẹ́ ìsìn mímọ́ ni gbogbo iṣẹ́ tá à ń ṣe ní Bẹ́tẹ́lì . Ibi yòówù ká ti máa sin Jèhófà , gbogbo wa la láǹfààní láti máa yìn ín lógo . Ìtàn ìgbésí ayé Leonard Smith wà nínú Ilé Ìṣọ́ April 15 , 2012 . Kí nìdí tá a fi lè sọ pé ẹ̀bùn Ọlọ́run ni ìgbéyàwó ? Báwo ni ìgbéyàwó ṣe rí látìgbà ayé Ádámù títí dìgbà ayé Jésù ? Kí ló lè ran Kristẹni kan lọ́wọ́ láti pinnu bóyá kóun ṣègbéyàwó tàbí kóun má ṣe ? 1 , 2 . ( a ) Báwo ni ìgbéyàwó ṣe bẹ̀rẹ̀ ? ( b ) Kí ni tọkọtaya àkọ́kọ́ wá mọ̀ nípa ìgbéyàwó ? ( Ka Jẹ́nẹ́sísì 2 : 20 - 24 . ) Ohun pàtàkì kan tí Ọlọ́run tìtorí ẹ̀ dá ìgbéyàwó sílẹ̀ ni pé kí wọ́n lè mú káwọn èèyàn kúnnú ayé . Kí la rí kọ́ látinú èsì tí Ádámù àti Éfà fún Jèhófà ? Ṣàlàyé ohun tó wà nínú Jẹ́nẹ́sísì 3 : 15 . ( a ) Kí ló ń ṣẹlẹ̀ nínú ìdílé látìgbà tí Ádámù àti Éfà ti ṣọ̀tẹ̀ ? ( b ) Kí ni Bíbélì sọ pé kí tọkọtaya máa ṣe ? Báwo ni ìgbéyàwó ṣe rí látìgbà ayé Ádámù sí ìgbà ayé Nóà ? Kí ni Jèhófà ṣe fáwọn èèyàn búburú nígbà ayé Nóà , kí la sì rí kọ́ látinú ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn ? ( a ) Irú ìwà wo ló ti di bárakú láwọn ilẹ̀ kan ? ( b ) Ọ̀nà wo ni Ábúráhámù àti Sárà gbà jẹ́ àpẹẹrẹ rere fáwọn tọkọtaya ? ( Ka 1 Pétérù 3 : 3 - 6 . ) Báwo ni Òfin Mósè ṣe tọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ́nà lórí ọ̀rọ̀ ìgbéyàwó ? ( Ka Diutarónómì 7 : 3 , 4 . ) 12 , 13 . ( a ) Kí làwọn ọkùnrin kan ń ṣe sí ìyàwó wọn nígbà ayé wòlíì Málákì ? ( b ) Tí ẹnì kan tó ti ṣèrìbọmi bá sá lọ pẹ̀lú ọkọ tàbí aya ẹlòmíì , kí ni ìjọ máa ṣe ? ( a ) Òfin wo làwọn Kristẹni ń tẹ̀ lé tó bá dọ̀rọ̀ ìgbéyàwó ? Ó tún sọ pé : “ Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá ní ìkóra - ẹni - níjàánu , kí wọ́n gbéyàwó , nítorí ó sàn láti gbéyàwó ju kí ìfẹ́ onígbòónára máa mú ara ẹni gbiná . ” 18 , 19 . ( a ) Ta ló yẹ kí Kristẹni kan fẹ́ ? ( b ) Kí la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ tó kàn ? Àwọn nǹkan wo ni Ọlọ́run ní kí ọkọ àti ìyàwó máa ṣe ? Kí nìdí tí ìfẹ́ àti ìwà jẹ̀lẹ́ńkẹ́ fi ṣe pàtàkì nínú ilé ? Ọ̀nà wo ni Bíbélì lè gbà ran tọkọtaya lọ́wọ́ tí wọ́n bá ní èdèkòyédè ? Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn tọkọtaya máa ń láyọ̀ lọ́jọ́ ìgbéyàwó wọn , kí ni Bíbélì sọ pé wọ́n máa ní ? Irú ìfẹ́ wo ló yẹ káwọn tọkọtaya máa fi hàn síra wọn ? Báwo ló ṣe yẹ kí ìfẹ́ tó wà láàárín tọkọtaya lágbára tó ? Pọ́ọ̀lù sọ pé : “ Ẹ̀yin ọkọ , ẹ máa bá a lọ ní nínífẹ̀ẹ́ àwọn aya yín , gan - an gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti nífẹ̀ẹ́ ìjọ , tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ lọ́wọ́ fún un . ” ( Ka Jòhánù 13 : 34 , 35 ; 15 : 12 , 13 . ) 4 , 5 . ( a ) Kí ni ojúṣe ọkọ nínú ilé ? ( b ) Báwo ló ṣe yẹ kí ìyàwó máa ṣe sí ọkọ rẹ̀ ? ( d ) Àwọn àyípadà wo ni tọkọtaya kan ṣe ? Nǹkan ti yàtọ̀ báyìí , ó ti di pé kí n máa dúró de ọkọ mi kí n tó ṣèpinnu . Kì í rọrùn nígbà míì , àmọ́ torí pé ohun tí Jèhófà fẹ́ là ń ṣe , a ti túbọ̀ mọ ara wa sí i . ” Ní báyìí tí mo ti gbéyàwó , ó tún ti wá ṣòro sí i torí pé mo gbọ́dọ̀ ro ti ìyàwó mi nígbà tí mo bá ń ṣèpinnu . Àmọ́ , bí mo ṣe ń bẹ Jèhófà pé kó máa tọ́ mi sọ́nà , tí mo sì ń fara balẹ̀ tẹ́tí sí ìyàwó mi , ṣe ló túbọ̀ ń rọrùn fún mi láti ṣèpinnu lójoojúmọ́ . Àwa méjèèjì ti wá mọwọ́ ara wa gan - an báyìí . ” Báwo ni ìfẹ́ ṣe lè jẹ́ kí tọkọtaya yanjú èdèkòyédè tí wọ́n bá ní ? 7 , 8 . ( a ) Ìmọ̀ràn wo ni Bíbélì fún tọkọtaya tó bá dọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀ ? ( b ) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé kí tọkọtaya máa bá ara wọn lò lọ́nà jẹ̀lẹ́ńkẹ́ ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 7 : 3 - 5 . ) Àjọgbà ló yẹ kí ọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀ jẹ́ , kì í ṣe èyí tá à ń fipá múni ṣe tàbí èyí tẹ́nì kan á máa ro tiẹ̀ nìkan ṣáá . Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa fa ojú ẹni tí kì í ṣe ọkọ tàbí aya wa mọ́ra tàbí ká máa bá a tage ? 10 , 11 . ( a ) Báwo ni ìkọ̀sílẹ̀ ṣe gbòde kan tó ? ( b ) Kí ni Bíbélì sọ nípa ìpínyà ? ( d ) Kí ló máa ran tọkọtaya lọ́wọ́ tí wọn ò fi ní pínyà ? Kí ló lè mú kí ẹnì kan máa ronú àtipínyà pẹ̀lú ọkọ tàbí aya rẹ̀ ? Ìmọ̀ràn wo ni Bíbélì fún àwọn tí ọkọ tàbí aya wọn kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 7 : 12 - 14 . ) Tàbí , ọkọ , báwo ni o ṣe mọ̀ bóyá ìwọ yóò gba aya rẹ là ? ” 15 , 16 . ( a ) Ìmọ̀ràn wo ni Bíbélì fáwọn aya tí ọkọ wọn kì í ṣe ìránṣẹ́ Jèhófà ? ( b ) Kí ló yẹ kí Kristẹni kan ṣe tí “ ẹni tí kò gbà gbọ́ náà bá tẹ̀ síwájú láti lọ ” ? Àpọ́sítélì Pétérù gba àwọn aya Kristẹni níyànjú pé kí wọ́n máa tẹrí ba fún àwọn ọkọ wọn , “ kí ó lè jẹ́ pé , bí ẹnikẹ́ni kò bá ṣègbọràn sí ọ̀rọ̀ náà , kí a lè jèrè wọn láìsọ ọ̀rọ̀ kan nípasẹ̀ ìwà àwọn aya wọn , nítorí fífi tí wọ́n fi ojú rí ìwà mímọ́ yín pa pọ̀ pẹ̀lú ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀ . ” Tí ọkọ tàbí aya tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí náà bá pinnu pé òun fẹ́ pínyà ńkọ́ ? Bíbélì sọ pé : “ Bí ẹni tí kò gbà gbọ́ náà bá tẹ̀ síwájú láti lọ , jẹ́ kí ó lọ ; arákùnrin kan tàbí arábìnrin kan kò sí ní ipò ìsìnrú lábẹ́ irúfẹ́ àwọn ipò bẹ́ẹ̀ , ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti pè yín sí àlàáfíà . ” Kí ló yẹ káwọn tọkọtaya Kristẹni máa fi sípò àkọ́kọ́ ? Kí nìdí tó fi dá wa lójú pé ìgbéyàwó àwa Kristẹni lè ládùn kó sì lóyin ? [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 5 ) A ti yí àwọn orúkọ náà pa dà . [ 2 ] ( ìpínrọ̀ 13 ) Wo àkòrí náà “ Ohun Tí Bíbélì Sọ Nípa Ìkọ̀sílẹ̀ àti Ìpínyà ” nínú àfikún tó wà nínú ìwé “ Ẹ Dúró Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run , ” ojú ìwé 219 sí 221 . . ” Inú àwọn ará máa ń dùn tí wọ́n bá ń wàásù fáwọn èèyàn lọ́wọ́ àárọ̀ lágbègbè Odò Danube . Àwọn akéde yìí ń wàásù fún ẹnì kan tó nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ wọn ní gbàgede Vigadó Square nílùú Budapest , orílẹ̀ - èdè Hungary Báwo lo ṣe lè fi kún ohun tó ò ń ṣe nínú ìjọsìn Ọlọ́run ? Báwo lo ṣe lè fi kún ohun tó ò ń ṣe láìjẹ́ kó sú ẹ ? Àwọn ìyípadà wo lo lè ṣe táá mú kó o túbọ̀ jáfáfá lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù ? 1 , 2 . ( a ) Báwo lohun tó wà nínú ìwé Aísáyà 60 : 22 ṣe ń nímùúṣẹ láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí ? ( b ) Àwọn apá wo ló ti yẹ ká fi kún ohun tá à ń ṣe nínú ìjọsìn Ọlọ́run lónìí ? BÍBÉLÌ sọ pé : “ Ẹni tí ó kéré yóò di ẹgbẹ̀rún , ẹni kékeré yóò sì di alágbára ńlá orílẹ̀ - èdè . ” Báwo lo ṣe lè fi kún ohun tó ò ń ṣe nínú ìjọsìn Ọlọ́run ? Báwo làwọn ọ̀dọ́ ṣe lè lo okun wọn lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run ? 6 - 8 . ( a ) Kí ló mú kí arákùnrin kan yí èrò tó ní nípa iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run pa dà , kí ló sì yọrí sí ? ( b ) Báwo la ṣe lè tọ́ Jèhófà wò , ká sì rí i pé ẹni rere ni ? Jèhófà ti bù kún mi gan - an , torí náà mo mọ̀ pé mo gbọ́dọ̀ ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn mi , bí mo sì ti ń ṣe bẹ́ẹ̀ , ṣe ni ìbùkún yẹn túbọ̀ ń pọ̀ sí i . ” ( Ka Sáàmù 34 : 8 - 10 . ) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká ní sùúrù ? Àwọn ànímọ́ àtàtà wo ló yẹ ká sapá láti ní , kí sì nìdí tí wọ́n fi ṣe pàtàkì ? Báwo la ṣe lè fi hàn pé a jẹ́ ẹni tó ṣe é fọkàn tán ? Báwo lo ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jósẹ́fù táwọn míì bá hùwà àìdáa sí ẹ ? Kí ló yẹ kó o ṣe táwọn míì bá hùwà àìdáa sí ẹ ? 14 , 15 . ( a ) Kí nìdí tó fi yẹ ká máa “ fiyè sí ” ọ̀nà tá à ń gbà wàásù ? ( b ) Kí lo lè ṣe tí kò bá rọrùn láti wàásù ládùúgbò rẹ ? ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí àti àpótí náà “ Ǹjẹ́ O Lè Wàásù Láwọn Ọ̀nà Míì ? ” ) Báwo ni ìwàásù níbi térò pọ̀ sí ṣe gbéṣẹ́ tó ? 17 , 18 . ( a ) Kí lo lè ṣe tẹ́rù bá ń bà ẹ́ láti wàásù níbi térò pọ̀ sí ? ( b ) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká ní irú ẹ̀mí tí Dáfídì ní bá a ṣe ń wàásù ? Ó sọ pé : “ Tá a bá ń ṣe ìjọsìn ìdílé , èmi àtìyàwó mi máa ń jíròrò onírúurú nǹkan táwọn èèyàn máa ń sọ , a sì máa ń ṣèwádìí nípa èsì tá a máa fáwọn tó bá ta ko ọ̀rọ̀ wa . A tún máa ń bi àwọn ará wa míì nípa ohun táwọn náà rò . ” ( Ka 1 Tímótì 4 : 15 . ) Wọn yóò máa sọ̀rọ̀ nípa ògo ipò ọba rẹ , wọn yóò sì máa sọ̀rọ̀ nípa agbára ńlá rẹ , láti sọ àwọn ìṣe agbára ńlá rẹ̀ di mímọ̀ fún àwọn ọmọ ènìyàn àti ògo ọlá ńlá ipò ọba rẹ̀ . ” Àǹfààní wo làwọn míì máa rí tó o bá ń lo ara rẹ lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run ? Venecia wá sọ pé : “ Ìjẹ́rìí orí fóònú gbéṣẹ́ lóòótọ́ ! ” Ọdún mẹ́ta sẹ́yìn ni ìyàwó mi kú , ìjàǹbá ọkọ̀ sì tún pa ọmọ mi lọ́dún tó kọjá . ” Bó ti lẹ̀ jẹ́ pé ọdún méjì ti kọjá lẹ́yìn tí mo rí lẹ́tà yín , mo láyọ̀ láti sọ fún yín pé mo ti di Ẹlẹ́rìí Jèhófà . ” Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wa pé kí wọ́n máa dá kẹ́kọ̀ọ́ ? Báwo la ṣe lè kọ́ àwọn ẹni tuntun láti máa wàásù fáwọn èèyàn ? Kí nìdí tó fi yẹ ká dá àwọn arákùnrin lẹ́kọ̀ọ́ kí wọ́n lè di alàgbà ? Kí nìdí tó fi yẹ ká kọ́ àwọn míì kí wọ́n lè fi kún ohun tí wọ́n ń ṣe nínú ìjọsìn Ọlọ́run ? 3 , 4 . ( a ) Kí ni Pọ́ọ̀lù sọ tó jẹ́ ká mọ̀ pé kéèyàn máa dá kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ṣe pàtàkì tá a bá fẹ́ jáfáfá lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn wa ? ( b ) Ká tó lè ran àwọn míì lọ́wọ́ láti máa dá kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì , kí làwa náà gbọ́dọ̀ máa ṣe ? Sọ àwọn nǹkan tá a lè ṣe tá a bá fẹ́ ran ẹni tá à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ lọ́wọ́ kó lè máa dá kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì déédéé . Bi ara rẹ pé , ‘ Kí ni mo lè ṣe tí ẹni tí mò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ á fi máa dá kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì déédéé ? ’ Sọ fún un pé kó máa ka gbogbo ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ àti Jí ! ( a ) Báwo lo ṣe lè ran ẹni tó ò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ lọ́wọ́ kó lè máa wù ú láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ? ( b ) Kí ni akẹ́kọ̀ọ́ kan lè bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe tó bá ti ń gbádùn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ? Báwo ni Jésù ṣe kọ́ àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ ? 8 , 9 . ( a ) Báwo ni Jésù ṣe máa ń ṣe sáwọn èèyàn tó ń wàásù fún ? ( b ) Báwo la ṣe lè mú káwọn akéde tuntun máa bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ bíi ti Jésù ? 10 - 12 . ( a ) Báwo ni Jésù ṣe mú káwọn èèyàn nífẹ̀ẹ́ sí ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run ? ( b ) Báwo la ṣe lè mú káwọn akéde tuntun túbọ̀ mọ bá a ṣe ń kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ? 13 , 14 . ( a ) Kí lo rí kọ́ lára àwọn tí Bíbélì sọ pé wọ́n lo ara wọn fún àwọn míì ? ( b ) Àwọn nǹkan wo lo lè ṣe káwọn ẹni tuntun àtàwọn ọ̀dọ́ lè máa fìfẹ́ hàn sáwọn ará ? Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé káwọn alàgbà rí i pé àwọn arákùnrin tó wà nínú ìjọ mọ̀ọ̀yàn kọ́ ? 16 , 17 . ( a ) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe dá Tímótì lẹ́kọ̀ọ́ ? ( b ) Báwo làwọn alàgbà ṣe lè dá àwọn arákùnrin lẹ́kọ̀ọ́ káwọn náà lè di alàgbà lọ́jọ́ iwájú ? Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa dá àwọn míì lẹ́kọ̀ọ́ nínú ìjọsìn Jèhófà ? Kí ló mú kó dá wa lójú pé gbogbo ìsapá wa láti dá àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ máa yọrí sí rere ? Lásán ni wọ́n ń jọ́sìn mi , nítorí pé wọ́n ń fi àwọn àṣẹ ènìyàn kọ́ni gẹ́gẹ́ bí ẹ̀kọ́ . ’ Ní pípa àṣẹ Ọlọ́run tì , ẹ̀yin di òfin àtọwọ́dọ́wọ́ ti ènìyàn mú ṣinṣin . ” — Máàkù 7 : 6 - 8 . 3 ‘ Má Ṣe Jẹ́ Kí Ọwọ́ Rẹ Rọ Jọwọrọ ’ Báwo ni Jèhófà ṣe fún Mósè , Ásà àti Nehemáyà lókun ? Àwọn ọ̀nà wo làwa náà lè gbà fún àwọn ará wa lókun ? ( b ) Àwọn nǹkan wo ló lè mú kí ọwọ́ ẹnì kan rọ jọwọrọ ? Bí àpẹẹrẹ , ọ̀pọ̀ ìgbà ni Bíbélì mẹ́nu kan ọwọ́ . Kí ló máa fún ẹ lókun táá sì máa fún ẹ láyọ̀ bó o ṣe ń fara dà á ? Àmọ́ , nígbà tí ọwọ́ bẹ̀rẹ̀ sí í ro Mósè , àwọn ọmọ Ámálékì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ́gun . ( b ) Báwo ni Ọlọ́run ṣe dáhùn àdúrà Nehemáyà ? ( Ka Nehemáyà 1 : 10 ; 2 : ​ 17 - 20 ; 6 :⁠ 9 . ) Ṣó dá ẹ lójú pé Jèhófà ṣì ń lo “ agbára ńlá ” àti “ ọwọ́ líle ” rẹ̀ láti fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ òde òní lókun ? 10 , 11 . ( a ) Kí ni Sátánì máa ń ṣe láti mú ká dẹwọ́ ? ( b ) Ọ̀nà wo ni Jèhófà ń gbà fún wa lókun àti agbára ? Ó máa ń lo àwọn alákòóso , àwọn aṣáájú ẹ̀sìn àtàwọn apẹ̀yìndà láti parọ́ mọ́ wa àti láti halẹ̀ mọ́ wa . 13 , 14 . ( a ) Kí ló fún arákùnrin kan lókun lẹ́yìn tí ìyàwó rẹ̀ kú ? Àdúrà àti ìdákẹ́kọ̀ọ́ ni kò jẹ́ kí n bọ́hùn . Lékè gbogbo rẹ̀ , mo ti wá rí bó ti ṣe pàtàkì tó láti ní àjọṣe tó dára pẹ̀lú Jèhófà kí àwọn ipò lílekoko tó dé . ” Báwo ni Jèhófà ṣe ń kọ́ wa ká lè borí àwọn ọ̀tá wa ? Bákan náà ló ń ràn wá lọ́wọ́ nípasẹ̀ àwọn ìtẹ̀jáde wa , ìpàdé ìjọ àtàwọn àpéjọ wa . Kí la lè ṣe tí ibi kò fi ní ṣẹ́gun wa ? ( b ) Àwọn àpẹẹrẹ wo nínú Bíbélì la máa jíròrò ? Kí nìdí tí Jékọ́bù ò fi jáwọ́ jíjà fitafita ? ( Ka Jẹ́nẹ́sísì 32 : ​ 24 - 28 . ) Báwo làwọn kan ṣe borí èròkerò ? Àpilẹ̀kọ míì tó tún ṣe ọ̀dọ́kùnrin yìí láǹfààní ni “ Gbígbé Ìgbésí Ayé Tó Yàtọ̀ Sí Ti Ẹ̀dá ​ — Ǹjẹ́ Ọlọ́run Fọwọ́ Sí I ? ” Ọ̀dọ́kùnrin náà wá sọ pé : “ Ohun tí mo kà yẹn wá fi mí lọ́kàn balẹ̀ , pé bí mo ṣe ń la ọjọ́ kọ̀ọ̀kan já , ó dájú pé màá lè jẹ́ olóòótọ́ . Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà pé ó ń lo ètò rẹ̀ láti ràn wá lọ́wọ́ ká lè la ayé búburú yìí já . ” Àpẹẹrẹ ẹlòmíì ni ti arábìnrin kan lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà . Ó sọ pé : “ Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ yín pé ohun tá a nílò gan - an lẹ máa ń fún wa , ó sì máa ń bọ́ sásìkò . Ọ̀pọ̀ ìgbà ló máa ń ṣe mí bíi pé èmi gan - an lẹ dìídì kọ àwọn àpilẹ̀kọ náà fún . Ọjọ́ pẹ́ tí ọkàn mi ti máa ń fà sóhun tí Jèhófà kórìíra , bó tilẹ̀ jẹ́ pé mò ń sapá gan - an láti borí ẹ̀ . Àwọn ìgbà kan tiẹ̀ wà tí mo rò pé agbára mi ò ní lè gbé e mọ́ . Mo mọ̀ pé aláàánú ni Jèhófà , ó sì máa ń dárí jini , àmọ́ torí pé èròkerò máa ń wá sí mi lọ́kàn ṣáá , ṣe ló dà bíi pé nínú mi lọ́hùn - ún , mi ò kórìíra rẹ̀ . Ìṣòro yìí ti wá mú kí gbogbo nǹkan sú mi . . . . Àmọ́ nígbà tí mo ka àpilẹ̀kọ tó sọ pé ‘ Ǹjẹ́ Ó Wù Ẹ́ Láti Mọ Jèhófà ? ’ nínú Ilé Ìṣọ́ March 15 , 2013 , ọkàn mi balẹ̀ pẹ̀sẹ̀ pé Jèhófà máa ràn mí lọ́wọ́ . ” ( a ) Báwo ni ìjà tí Pọ́ọ̀lù ń jà ṣe rí lára rẹ̀ ? Kí la rí kọ́ nínú Òfin tí Ọlọ́run fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípa ìmúra ? Kí ló lè ran Kristẹni kan lọ́wọ́ láti ṣèpinnu tó dáa tó bá dọ̀rọ̀ ìmúra ? Àwọn ìgbà wo ló ṣe pàtàkì gan - an pé ká múra lọ́nà tó bójú mu ? Òótọ́ kan ni pé aṣọ tó bójú mu níbì kan lè má bójú mu níbòmíì . ( Ka 1 Kọ́ríńtì 10 : ​ 32 , 33 . ) Kí ló lè mú kí arákùnrin kan pinnu bóyá kóun dá irùngbọ̀n sí tàbí kóun má ṣe bẹ́ẹ̀ ? Láyé àtijọ́ , Òfin Mósè fi dandan lé e pé àwọn ọkùnrin gbọ́dọ̀ dá irùngbọ̀n sí . Kódà , àwọn arákùnrin kan tá a yàn sípò nínú ìjọ láwọn ilẹ̀ yẹn ní irùngbọ̀n . Síbẹ̀ , àwọn arákùnrin kan nírú àwọn ilẹ̀ bẹ́ẹ̀ lè pinnu pé àwọn ò ní dá irùngbọ̀n sí . Tá a bá ń múra lọ́nà tó bójú mu , kí ló máa mú káwọn èèyàn ṣe ? Arákùnrin kan lórílẹ̀ - èdè Jámánì sọ pé : “ Àwọn tíṣà mi gbà pé ìtàn àròsọ lásán làwọn àkọ́sílẹ̀ nípa ìṣẹ̀dá tó wà nínú Bíbélì . Wọ́n gbà pé ohun tó yẹ káwa akẹ́kọ̀ọ́ gbà gbọ́ ni ẹ̀kọ́ ẹfolúṣọ̀n . ” Ọ̀dọ́bìnrin kan tó jẹ́ Ẹlẹ́rìí nílẹ̀ Faransé sọ pé : “ Ó máa ń ya àwọn tíṣà iléèwé mi lẹ́nu pé àwa akẹ́kọ̀ọ́ kan ṣì wà tá a gba ohun tó wà nínú Bíbélì gbọ́ . ” àti The Origin of Life ​ —⁠ Five Questions Worth Asking , òmíràn ni ìwé Is There a Creator Who Cares About You ? Àkàtúnkà ni mo fi ṣe , ó ti tó ẹ̀ẹ̀mejìlá tí mo ti kà á . ” Wọ́n jẹ́ kí n mọ̀ pé kò sí bí ẹnjiníà kan ṣe gbóná tó , iwájú láá máa bá Ẹlẹ́dàá . ” Kí nìdí tí Ọlọ́run fi fẹ́ ká máa lo làákàyè wa ? ( Ka Róòmù 12 : 1 , 2 ; 1 Tímótì 2 : 4 . ) Ọ̀pọ̀ wọn ò gbé níbì kan náà , wọn ò sì gbáyé lásìkò kan náà . ” Nígbà tí mo ka àpilẹ̀kọ náà débì kan , mo dúró , mo wá ronú lọ gbári , pé àjọyọ̀ ọjọ́sí ni Jésù wá mú ṣẹ yìí , ó ga o ! ” Ọ̀dọ́kùnrin kan nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì sọ pé : “ Kò sí òótọ́ lẹ́nu àwọn èèyàn ayé . Báwọn tó kọ Bíbélì ṣe sòótọ́ mú kó túbọ̀ dá mi lójú pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì . ” Ọ̀dọ́bìnrin kan lórílẹ̀ - èdè Japan sọ pé : “ Inú wa máa ń dùn bá a ṣe ń fi ìlànà Bíbélì sílò ní ìdílé wa . Àlàáfíà wà láàárín wa , ìfẹ́ àti ìṣọ̀kan sì jọba nílé wa . ” Ìwàkiwà tó kúnnú ìsìn ló mú káwọn míì gbà pé kò sí Ọlọ́run . Ògbógi náà wá sọ pé : “ Àwámáridìí làwọn nǹkan tó yí wa ká , títí kan àwọn nǹkan kéékèèké . ” Ó sọ pé : “ Olúkúlùkù ilé ni a kọ́ láti ọwọ́ ẹnì kan , ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ́ ohun gbogbo ni Ọlọ́run . ” Kí nìdí tó fi yẹ kẹ́yin òbí mọ àwọn ọmọ yín dáadáa ? Báwọn ọmọ ṣe ń dàgbà ni wọ́n ń nígbàgbọ́ . ” Wọ́n á bi mí pé : ‘ Kí ni Bíbélì sọ ? ’ ‘ Ṣó o gbà pé òótọ́ ni Bíbélì sọ ? ’ Wọ́n máa ń fẹ́ kí n ṣàlàyé lọ́rọ̀ ara mi . Bí mo sì ṣe ń dàgbà sí i , wọ́n máa ń fẹ́ kí àlàyé mi túbọ̀ kún rẹ́rẹ́ . ” Síbẹ̀ , gbogbo ìbéèrè mi ni wọ́n fi Bíbélì dáhùn . ” ( Ka Diutarónómì 6 : 5 - 8 ; Lúùkù 6 : 45 . ) Ẹní bá rí wọn á mọ̀ pé nígbà tí wọ́n ṣì wà , wọ́n á dùn wò , àgbàyanu sì ni wọ́n . Mi ò jẹ́ gbàgbé àwọn ohun tí mo rí yẹn , mo sì jẹ́ kí ẹ̀kọ́ yìí ṣe kedere sí ọmọ mi . ” Kọ́rọ̀ náà lè yé wọn , ó ní kí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn po tíì fún òun , ó sì fún wọn ní mílíìkì , ṣúgà àti tíì . Ìyá náà wá sọ pé : “ Àwọn méjèèjì fara balẹ̀ po tíì náà . Mo wá bi wọ́n pé kí nìdí tí wọ́n fi fara balẹ̀ bẹ́ẹ̀ , wọ́n sọ pé àwọn fẹ́ po tíì náà bí mo ṣe máa ń fẹ́ gan - an , kó má ṣàn jù , kó má sì ki jù . Mo wá ṣàlàyé fún wọn pé bí Ọlọ́run ṣe fara balẹ̀ ṣe ojú ọ̀run nìyẹn káyé lè dùn gbé fún wa . ” Ǹjẹ́ a lè sọ pé ariwo ọkọ̀ òfuurufú àti orin aládùn tí ẹyẹ máa ń kọ jọra ? Bàbá kan sọ pé : “ Máa ronú onírúurú ọ̀nà tó o lè gbà ṣàlàyé ohun tó o ti ṣàlàyé fún wọn tẹ́lẹ̀ , má ṣe jẹ́ kó sú ẹ . ” Mo máa ń fi ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún [ 15 ] kọ́ wọn lẹ́kọ̀ọ́ lójoojúmọ́ látìgbà tí wọ́n ti wà ní kékeré , àyàfi ọjọ́ tá a bá ń lọ sípàdé . Àmọ́ bọ́jọ́ ṣe ń gorí ọjọ́ , mo rí ìdáhùn sáwọn ìbéèrè yẹn nípàdé , ìgbà míì sì wà tó jẹ́ pé ìgbà Ìjọsìn Ìdílé tàbí ìgbà tí mò ń dá kẹ́kọ̀ọ́ ni màá rí àwọn ìdáhùn náà . Ẹ ò rí i pé ó ṣe pàtàkì pé kẹ́yin òbí máa kọ́ àwọn ọmọ yín . ” Ohun tí tọkọtaya kan tó ń gbé lórílẹ̀ - èdè Bermuda máa ń ṣe tí wọ́n bá ní ìdààmú ọkàn ni pé , wọ́n á pe àwọn ọmọ wọn , wọ́n á sì jọ gbàdúrà pé kí Jèhófà tọ́ àwọn sọ́nà . Àwọn tọkọtaya náà sọ pé : “ A máa ń sọ fún ọmọbìnrin wa àgbà pé , ‘ Gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà pátápátá , máa lo ara rẹ lẹ́nu iṣẹ́ Ọlọ́run , má sì máa ṣàníyàn ju bó ti yẹ lọ . ’ Nígbà tóun náà bá wá rí bí nǹkan ṣe pa dà rí fún wa , ó máa ń gbà pé Jèhófà ló ràn wá lọ́wọ́ . Èyí ti mú kí ìgbàgbọ́ tó ní nínú Ọlọ́run túbọ̀ lágbára , ó sì túbọ̀ dá a lójú pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì . ” Àpilẹ̀kọ àkọ́kọ́ sọ bá a ṣe lè nígbàgbọ́ , kí ìgbàgbọ́ wa sì lágbára . Ẹ jẹ́ kí n ṣàlàyé ohun tó bí ọ̀rọ̀ yìí . ÌLÚ WICHITA , ní ìpínlẹ̀ Kansas lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà ni wọ́n bí mi sí , ní December 10 , 1936 . Bí dókítà yẹn ṣe rí sójà yẹn , ló bá ké sí sójà náà pé , “ Ẹ wá gbé ọ̀lẹ afàjò yìí ! ” Sójà náà rí i pé ọkùnrin yẹn ti yó , ó wá sọ fún un pé , “ O jẹ́ gbalé lọ kọ́tí lè dá lójú ẹ ! ” Kò sígbà tí mo rántí ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn tí mi kì í dúpẹ́ pé Jèhófà fún dádì mi nígboyà . Èmi àtàwọn òbí mi rèé nígbà tá à ń lọ sípàdé àgbègbè kan nílùú Wichita , lọ́dún 1940 Kí wọ́n lè gbọ́ bùkátà ìdílé , wọ́n ń ṣiṣẹ́ àgbẹ̀ , wọ́n sì ń sin ẹran . Nígbà tó yá , arákùnrin yẹn bá mi ta mọ́tò náà ní dọ́là mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n [ 25 ] . Wọ́n sọ wá di aṣáájú - ọ̀nà àkànṣe , wọ́n sì ní ká lọ máa sìn nílùú Walnut Ridge , ní ìpínlẹ̀ Arkansas . Lọ́dún 1962 , wọ́n pè wá sí kíláàsì kẹtadínlógójì [ 37 ] ti Ìlé Ẹ̀kọ́ Gílíádì . Èmi àtìyàwó mi rèé lóde ẹ̀rí nílùú Nairobi , pẹ̀lú Mary àti Chris Kanaiya Ìlú Colorado , níbi táwọn òbí mi ń gbé la pa dà sí . Lóòótọ́ ọmọdé ni wọ́n , àmọ́ ìbéèrè wọn máa ń ju tọmọdé lọ . A máa ń ṣètò pé káwọn ará tó wà nínú iṣẹ́ alákòókò kíkún dé sílé wa . Ohun tí mo ṣe yẹn yà wọ́n lẹ́nu gan - an , wọn ò mọ̀ pé mo lè sọ bẹ́ẹ̀ , ni wọ́n bá bú sẹ́kún , wọ́n wá ń bẹ̀bẹ̀ pé ká ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ náà . A dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà àti ètò rẹ̀ tó ràn wá lọ́wọ́ láti mú kí wọ́n nífẹ̀ẹ́ òtítọ́ . Ẹ̀ẹ̀kejì tí wọ́n ṣèbẹ̀wò ni Kimberly rí ọ̀rẹ́ Paul kan tóun náà ń sìn ní Bẹ́tẹ́lì , Brian Llewellyn lorúkọ rẹ̀ . Torí náà , àwọn méjèèjì pé ọmọ ọdún mẹ́tàlélógún kí wọ́n tó lọ sílé ọkọ . Ètò Ọlọ́run tún pe Brian àti Kimberly wá sí ẹ̀ka ọ́fíìsì wa tó wà nílùú London , àmọ́ nígbà tó yá , wọ́n ní kí wọ́n lọ máa sìn ní ẹ̀ka ọ́fíìsì wa lórílẹ̀ - èdè Màláwì . Lọ́jọ́ tó tẹ̀ lé ọjọ́ tá a kúrò nílé lọ sí Ibùdó Ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ti Watchtower tó wà ní Patterson , Linda pè wá , ó sì sọ pé màámi ti kú . Lẹ́yìn ìyẹn , wọ́n rán wa lọ sórílẹ̀ - èdè Sìǹbábúwè , nígbà tá a kúrò níbẹ̀ , a lọ sórílẹ̀ - èdè Sáńbíà . Kò pẹ́ sígbà yẹn , lọ́dún 2006 , Brian àti Kimberly kó wá sítòsí wa kí wọ́n lè tọ́ àwọn ọmọbìnrin wọn méjèèjì , ìyẹn Mackenzie àti Elizabeth . Paul àti Stephany ṣì wà ní Màláwì , níbi tí Paul ti ń ṣiṣẹ́ sìn nínú Ìgbìmọ̀ Ẹ̀ka . Tá a bá ní èrò tí kò tọ́ nípa àwọn àjèjì , kí nìdí tó fi yẹ ká yí èrò wa pa dà ? Nígbà tí mo kúrò ní pápákọ̀ òfuurufú , òtútù yẹn wọ̀ mí lára gan - an , mi ò tíì rí irú rẹ̀ rí láyé mi , ṣe ni mo bú sẹ́kún . ” Ohun tó ṣẹlẹ̀ ni pé àwọn Júù tó ń sọ èdè Gíríìkì ń ṣàròyé pé wọn ò bójú tó àwọn opó wọn . Yálà a mọ̀ bẹ́ẹ̀ tàbí a ò mọ̀ , gbogbo wa pátá ni àṣà ìbílẹ̀ wa máa ń mú ká ronú tàbí hùwà lọ́nà kan . ( Ka 1 Pétérù 1 : 22 . ) O lè bi ara rẹ pé : ‘ Ká sọ pé ìlú onílùú lèmi náà wà , báwo ni màá ṣe fẹ́ kí wọ́n ṣe sí mi ? ’ Máa ṣe sùúrù fún wọn torí pé ara wọn ṣẹ̀ṣẹ̀ ń mọlé ni . Àpẹẹrẹ wo làwọn àjèjì lè tẹ̀ lé ? Lákọ̀ọ́kọ́ , Rúùtù ò fojú pa àṣà ilẹ̀ tó wà rẹ́ torí pé ó tọrọ àyè kó tó bẹ̀rẹ̀ sí í pèéṣẹ́ . [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 1 ) A ti yí orúkọ rẹ̀ pa dà . Èyí ti mú káwọn kan lára wa kọ́ èdè tuntun . ( Ka Nehemáyà 13 : 23 , 24 . ) ( b ) Báwo la ṣe lè jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wọ̀ wá lọ́kàn ? Lọ́pọ̀ ìgbà , tá a bá ń múra òde ẹ̀rí , tá à ń múra ìpàdé tàbí tá à ń múra iṣẹ́ tá a ní nípàdé , a kì í sábà ronú bọ́rọ̀ náà ṣe kàn wá . Ìdí nìyẹn tí mo fi máa ń wáyè kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àtàwọn ìtẹ̀jáde míì lédè abínibí mi . ” Muriel sọ pé : “ Inú ọmọ wa máa ń dùn láti wàásù lédè abínibí rẹ̀ tó jẹ́ Faransé níjọ tá a wà tẹ́lẹ̀ , àmọ́ ní báyìí tá a ti wà níjọ tí wọ́n ti ń sọ èdè àjèjì , a kíyè sí i pé inú rẹ̀ kì í dùn láti lọ sóde ẹ̀rí mọ́ . ” Serge wá sọ pé : “ Nígbà tá a rí i pé ìtara ọmọ wa ti ń dín kù , ṣe la pa dà sí ìjọ tá a wà tẹ́lẹ̀ . ” Rí i dájú pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wọ àwọn ọmọ rẹ lọ́kàn ( Wo ìpínrọ̀ 14 àti 15 ) Àmọ́ a jọ máa ń gbá àwọn géèmù tó wà lédè Lingala ká lè fìyẹn kọ́ wọ́n lédè yẹn . ” Ẹ máa sapá láti kọ́ èdè ibi tẹ́ ẹ wà , kẹ́ ẹ sì máa dáhùn nípàdé ( Wo ìpínrọ̀ 16 àti 17 ) A tún máa ń rí i dájú pé a lọ sí ìjọ tó ń sọ èdè Faransé lẹ́ẹ̀kan lóṣù , tá a bá sì tún gba ìsinmi lẹ́nu iṣẹ́ , a máa ń lọ sí àpéjọ àgbègbè lédè ìbílẹ̀ wa . ” ( Ka Róòmù 15 : 1 , 2 . ) Báwo la ṣe lè fi hàn pé a mọyì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ? Àwọn arákùnrin yìí ń wàásù fún mẹ́káníìkì kan níbi tí wọ́n ti ń tún mọ́tò ṣe . ( Ka Ìṣípayá 21 : ​ 3 - 6 . ) Kí ló mú kí Ábúráhámù àti ìdílé rẹ̀ ní ìgbàgbọ́ tó lágbára ? ( Ka 1 Jòhánù 5 : ​ 14 , 15 . ) Àwọn àdánwò wo làwọn wòlíì Ọlọ́run fara dà torí ìgbàgbọ́ wọn ? Àwọn míì bí Èlíjà “ rìn káàkiri nínú àwọn aṣálẹ̀ àti àwọn òkè ńlá àti àwọn hòrò àti àwọn ihò inú ilẹ̀ . ” Báwo ni àpẹẹrẹ Nóà ṣe jẹ́ ká túbọ̀ lóye ohun tí ìgbàgbọ́ jẹ́ ? Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà lo ìgbàgbọ́ ? Orí nǹkan méjì wo ni Hébérù 11 : 1 sọ pé ìgbàgbọ́ dá lé ? Ẹ̀yin rí i pé ìgbàgbọ́ rẹ̀ ṣiṣẹ́ pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àti nípa àwọn iṣẹ́ rẹ̀ a sọ ìgbàgbọ́ rẹ̀ di pípé . ” Bí àpẹẹrẹ , Jòhánù sọ pé : “ Ẹni tí ó bá ń lo ìgbàgbọ́ nínú Ọmọ ní ìyè àìnípẹ̀kun ; ẹni tí ó bá ń ṣàìgbọràn sí Ọmọ kì yóò rí ìyè , ṣùgbọ́n ìrunú Ọlọ́run wà lórí rẹ̀ . ” Kí nìdí tí ìfẹ́ fi ṣe pàtàkì bá a bá tiẹ̀ nígbàgbọ́ ? Jákọ́bù bi àwọn arákùnrin tó jẹ́ ẹni àmì òróró pé : “ Ọlọ́run yan àwọn tí í ṣe òtòṣì ní ti ayé láti jẹ́ ọlọ́rọ̀ nínú ìgbàgbọ́ àti ajogún ìjọba náà , èyí tí ó ṣèlérí fún àwọn tí ó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ , àbí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ? ” Nígbà tí àwọn ènìyàn ń sùn , ọ̀tá rẹ̀ wá , ó sì tún fún àwọn èpò sí àárín àlìkámà náà , ó sì lọ . Nígbà tí ewé ọ̀gbìn náà rú jáde , tí ó sì mú èso jáde , nígbà náà ni àwọn èpò fara hàn pẹ̀lú . ” Ìlérí wo ni Jèhófà ṣe fáwọn èèyàn rẹ̀ , kí sì nìdí tí ìlérí yẹn fi jọni lójú ? Ṣó ṣì máa ṣeé ṣe fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti máa jọ́sìn Ọlọ́run bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ ? Torí náà , kò jọ pé àwọn èèyàn Jèhófà lọ sígbèkùn Bábílónì Ńlá lọ́dún 1918 . ( Ka 1 Pétérù 2 : 9 , 10 . ) ( Ka Mátíù 13 : 24 , 25 , 37 - 39 . ) Ṣó ṣì máa ṣeé ṣe fáwọn Kristẹni tòótọ́ láti máa jọ́sìn Ọlọ́run bí wọ́n ṣe fẹ́ , tí inú Ọlọ́run á sì dùn sí wọn ? Ìgbà wo làwọn ẹni àmì òróró bọ́ pátápátá nígbèkùn Bábílónì ? Arákùnrin Rutherford ní ká ṣètò àwọn àpéjọ àgbègbè láwọn ìlú ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lápá ìlà oòrùn orílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà , a sì rán àwọn olùbánisọ̀rọ̀ síbẹ̀ kí wọ́n lè fún àwọn ará níṣìírí tó bá ti lè ṣeé ṣe tó . ” “ Bí ọ̀rọ̀ ìṣírí èyíkéyìí bá wà tí ẹ ní fún àwọn ènìyàn , ẹ sọ ọ́ . ” ​ — ÌṢE 13 : 15 . Àwọn ọ̀rọ̀ yẹn mú kí n gbà pé mi ò wúlò . Alàgbà náà kíyè sí i pé inú mi ò dùn . Ó wá bi mí pé kí ló ṣẹlẹ̀ , mo sọ tọkàn mi fún un , ó sì fara balẹ̀ tẹ́tí sí mi . Lẹ́yìn náà , ó rán mi létí àwọn nǹkan dáadáa tí mo ti ń ṣe látọjọ́ yìí wá . Kò sígbà tí mo rántí ẹsẹ Bíbélì yìí , tí ọ̀rọ̀ inú rẹ̀ kì í wọ̀ mí lọ́kàn . Kí la lè rí kọ́ lára ọ̀nà tí Jèhófà , Jésù àti Pọ́ọ̀lù gbà fún àwọn míì níṣìírí ? ( Ka Oníwàásù 4 : 9 , 10 . ) Kí la rí kọ́ lára Jésù nípa bó ṣe bá àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ lò ? Lẹ́yìn líla àwọn ibi wọnnì já , tí ó sì ń fún àwọn tí ń bẹ níbẹ̀ ní ìṣírí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ , ó wá sí ilẹ̀ Gíríìkì . ” ( Ka 1 Tẹsalóníkà 5 : 12 , 13 . ) Àwọn lẹ́tà náà máa ń fún wa lókun gan - an . ” Arákùnrin Andreas tó lọ́mọ méjì sọ pé : “ Tá a bá ń gbóríyìn fáwọn ọmọ , ó máa jẹ́ kí wọ́n dàgbà dénú , kí wọ́n sì tẹ̀ síwájú nínú ìjọsìn wọn . Lóòótọ́ , àwọn ọmọ wa lè mọ ohun tó tọ́ , àmọ́ tá a bá fẹ́ kí wọ́n máa ṣe ohun tó tọ́ , ó ṣe pàtàkì ká máa yìn wọ́n . ” ( Ka Lúùkù 21 : 1 - 4 ; 2 Kọ́ríńtì 8 : 12 . ) ( Ka Ìṣípayá 2 : 18 , 19 . ) Mo fẹ́ kẹ́ ẹ mọ̀ pé bẹ́ ẹ ṣe ń sọ̀rọ̀ tútù látorí pèpéle àti bẹ́ ẹ ṣe bá mi sọ̀rọ̀ jẹ́ kí n mọ̀ pé Jèhófà ló rán yín sí mi . ” [ 1 ] ( ìpínrọ̀ 1 ) A ti yí àwọn orúkọ kan pa dà . ( b ) Kí la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Àǹfààní wo ni ìjọ rí nígbà tí wọ́n tẹ̀ lé àwọn ìtọ́ni tí wọ́n ń gbà látọ̀dọ̀ ìgbìmọ̀ olùdarí ? ( Ka 3 Jòhánù 9 , 10 . ) ( Ka Mátíù 5 : 23 , 24 ; 18 : 15 - 17 . ) Bíbélì sọ pé a gbọ́dọ̀ máa pé jọ sípàdé déédéé . Ṣé ìwọ náà ń lo Ìkànnì jw.org lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù àti nígbà ìjọsìn ìdílé yín ? àti ìwé Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní ? Sọ díẹ̀ lára àwọn ìdí tó fi yẹ ká máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà . Tá a bá ní ká máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà fún gbogbo ohun tó ti ṣe fún wa , ó tó bẹ́ẹ̀ ó jù bẹ́ẹ̀ lọ . Ó tún sọ bí ìrètí tá a ní pé Jèhófà máa san wá lẹ́san ṣe ń ṣe wá láǹfààní . Mi ò ju ọmọ ọdún mẹ́jọ lọ nígbà yẹn . Bàbá mi kì í fẹ́ kí màmá mi sọ ohun tí wọ́n ń kọ́ fún mi . Àmọ́ , ó máa ń wù mí láti mọ ohun tí wọ́n ń kọ́ , torí náà mo máa ń da ìbéèrè bò wọ́n . Ohun tí wọ́n kọ́ mi wọ̀ mí lọ́kàn gan - an , èmi náà bá pinnu pé màá ya ara mi sí mímọ́ fún Jèhófà . Wọ́n wá ní kí n kọ́kọ́ sọ fún ìránṣẹ́ àwọn ará ( tá à ń pè ní alábòójútó àyíká báyìí ) . Ó ní “ Kí lo tún ń dúró ṣe ? ” Lẹ́yìn oṣù mẹ́rin , mo sọ fún arákùnrin kan pé kó jẹ́ ká jọ máa ṣe iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà . Màmá mi àti arábìnrin kan sì ń bá iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà wọn lọ ní ìjọ míì . Lọ́dún 1951 , mo gba fọ́ọ̀mù Ilé Ẹ̀kọ́ Gílíádì . Ibẹ̀ ni mo wà nígbà tí mo gba ìwé pé kí n máa bọ̀ ní kíláàsì kejìlélógún [ 22 ] ti Ilé Ẹ̀kọ́ Gílíádì . Lẹ́yìn náà ni mo wá wọkọ̀ ojú irin lọ síbi tí ilé ẹ̀kọ́ náà wà , nílùú South Lansing , ìpínlẹ̀ New York . Èmi àti Janet rèé ní ọ̀kan lára àwọn erékùṣù Philippines A ṣì ń sìn ní ẹ̀ka ọ́fíìsì wa tó wà nílùú Quezon City Kí láá jẹ́ kó o ní “ àlàáfíà Ọlọ́run ” ? Báwo làwọn tẹ́ ẹ jọ wà nínú ìjọ ṣe lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti dín àníyàn kù ? ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí . ) ( b ) Kí la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Ìbéèrè náà ni pé , báwo la ṣe lè ṣe bẹ́ẹ̀ ? Dáfídì bẹ Jèhófà pé : “ Fi etí sí àdúrà mi , Ọlọ́run . ” Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa gbàdúrà nígbà tá a bá ń ṣàníyàn ? ( Ka Mátíù 11 : ​ 28 - 30 . ) Kí ni Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé : “ Ẹ má ṣàníyàn láé ” ? Nínú ipò tí Dáfídì wà yìí , ó ṣe ohun kan tó mọ́gbọ́n dání . Ó ṣe tán , òun náà ló ní ká ju ìṣòro wa sọ́dọ̀ òun . Kí nìdí tó o fi lè gbà pé tó o bá ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà , wàá lè fara da ìṣòro rẹ ? ( a ) Báwo la ṣe ń ju àníyàn wa sọ́dọ̀ Jèhófà ? Kí ló jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà máa ń sẹ̀san fáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ? Báwo ni Jèhófà ṣe bù kún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láyé àtijọ́ ? 1 , 2 . ( a ) Báwo ni ìfẹ́ àti ìgbàgbọ́ ṣe tan mọ́ra ? Àmọ́ , àǹfààní wo nìyẹn máa ṣe wá ? Jésù mú kó dá àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ lójú pé Ọlọ́run máa san wọ́n lẹ́san gbogbo ohun tí wọ́n yááfì ( Wo ìpínrọ̀ 5 ) Ìgbà kan wà tí àpọ́sítélì Pétérù bi Jésù pé : “ Àwa ti fi ohun gbogbo sílẹ̀ , a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ; kí ni yóò wà fún wa ní ti gidi ? ” Yàtọ̀ sáwọn tó máa gba èrè wọn lọ́run , àwọn tó nírètí àtigbé nínú Párádísè lórí ilẹ̀ ayé náà máa ‘ yọ̀ , wọ́n á sì fò sókè fún ìdùnnú . ’ Mósè sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé : “ Jèhófà yóò bù kún ọ ní ilẹ̀ tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún láti gbà , kìkì bí ìwọ kì yóò bá kùnà láti fetí sí ohùn Jèhófà Ọlọ́run rẹ kí o lè kíyè sára láti pa gbogbo àṣẹ yìí tí mo ń pa fún ọ lónìí mọ́ . Nítorí tí Jèhófà Ọlọ́run rẹ yóò bù kún ọ , ní tòótọ́ , gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún ọ gan - an . ” Ó sì sọ èkejì ní Éfúráímù . Ó wá ní : “ Ọlọ́run ti mú kí n so èso ní ilẹ̀ ipò ìráre mi . ” Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé : “ Nítorí ìdùnnú tí a gbé ka iwájú rẹ̀ , ó fara da òpó igi oró , ó tẹ́ńbẹ́lú ìtìjú . ” Kò sí àní - àní pé inú Jésù dùn gan - an pé òun sọ orúkọ Jèhófà di mímọ́ . Báwo làwọn ohun tá a bá ṣe fún Jèhófà ṣe máa ń rí lára rẹ̀ ? Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé : “ Ẹni tí ń fi ojú rere hàn sí ẹni rírẹlẹ̀ , Jèhófà ni ó ń wín , Òun yóò sì san ìlòsíni rẹ̀ padà fún un . ” Báwo lọ̀rọ̀ tó wà nínú 1 Jòhánù 3 : 19 , 20 ṣe tù wá nínú ? ( Ka 1 Jòhánù 3 : 19 , 20 . ) Sọ díẹ̀ lára àwọn nǹkan tá à ń gbádùn báyìí . Báwo ni ìbùkún tí Jèhófà ń fún wa ṣe ń rí lára wa ? Àpẹẹrẹ kan ni ti Arábìnrin Bianca tó wà lórílẹ̀ - èdè Jámánì , ó sọ pé : “ Mo dúpẹ́ mo tọ́pẹ́ dá lọ́wọ́ Jèhófà torí pé ó ń bá mi gbé ìṣòro mi , kò sì fi mí sílẹ̀ lọ́jọ́ kan . Ayé yìí ò lójú mọ́ , gbogbo nǹkan sì ti dojú dé . Àmọ́ bí mo ṣe túbọ̀ ń sún mọ́ Jèhófà , ṣe ló dà bíi pé ó dì mí mú , tọ́kàn mi sì balẹ̀ pẹ̀sẹ̀ . Àpẹẹrẹ míì ni ti Arábìnrin Paula tó ń gbé lórílẹ̀ - èdè Kánádà . Kí n má bàa rẹ̀wẹ̀sì , mo ní ìwé kan tí mo kọ àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ àtàwọn kókó látinú ìtẹ̀jáde wa sí , mo sì máa ń yẹ̀ ẹ́ wò látìgbàdégbà . Mo pe ìwé náà ní ‘ Ìwé Tó Ń Gbé Mi Ró . ’ Téèyàn bá ń ronú nípa àwọn ìlérí Jèhófà , èèyàn á tètè borí ìrẹ̀wẹ̀sì . Ìṣòro yòówù ká ní , Jèhófà máa dúró tì wá , á sì ràn wá lọ́wọ́ . ” Síbẹ̀ , máa ronú nípa bí Jèhófà ṣe ń bù kún ìwọ àtàwọn míì . Èrò kan wà tí Pọ́ọ̀lù sọ pé a ò gbọ́dọ̀ gbà láyè rárá . ( Ka Róòmù 6 : 1 , 2 . ) Ìpinnu wo ni ẹnì kọ̀ọ̀kan wa gbọ́dọ̀ ṣe ? ( Ka Òwe 14 : 5 ; Éfésù 4 : 25 . ) ( Ka Róòmù 4 : 20 - 22 . ) ( Ka Ìṣe 18 : 2 - 4 ; 20 : 20 , 21 , 34 , 35 . ) Ọ̀pọ̀ àwọn tó ń rìnrìn - àjò afẹ́ ló máa ń wá sí ìlú Aveiro ní àríwá orílẹ̀ - èdè Potogí kí wọ́n lè wá rí ibi tí wọ́n ti ń ṣe iyọ̀ . Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń wàásù fáwọn tó ń ta iyọ̀ níbẹ̀ Kí làwọn nǹkan míì tí Bíbélì sọ ? Nínú àpilẹ̀kọ yìí , àá rí bá a ṣe lè mọyì òmìnira tí Ọlọ́run fún wa àti bá a ṣe lè lò ó lọ́nà táá fògo fún Jèhófà tó fún wa lẹ́bùn náà . Àpilẹ̀kọ àkọ́kọ́ á jẹ́ ká mọ ohun tó túmọ̀ sí láti mọ̀wọ̀n ara ẹni àti ohun tí kò túmọ̀ sí . Báwo ni Jèhófà ṣe fẹ́ ká máa lo àwọn nǹkan tó fi jíǹkí wa ? Ó ṣe kedere nígbà náà pé Jèhófà fẹ́ ká ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti múnú ara wa àtàwọn míì dùn . Nígbà ayé Nóà , àwọn èèyàn máa ń hùwà ipá gan - an , wọ́n sì máa ń ṣe ìṣekúṣe . Táwọn èèyàn ò bá gbọ́ ìwàásù wa ( Wo ìpínrọ̀ 6 sí 9 ) 6 , 7 . ( a ) Kí làwọn nǹkan tí Nóà ò lè ṣe ? ( b ) Báwo ni ọ̀rọ̀ wa ṣe jọ ti Nóà ? Àwọn èèyàn burúkú ló kúnnú ayé lónìí , a sì mọ̀ pé Jèhófà ti ṣèlérí pé òun máa pa wọ́n run . Ohun kan ni pé a ò lè fipá mú àwọn èèyàn pé kí wọ́n yí pa dà lẹ́yìn tí wọ́n gbọ́ ‘ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run . ’ Ohun tí Nóà lè ṣe : Kàkà kí Nóà káwọ́ gbera torí àwọn nǹkan tí kò lè ṣe , ńṣe ló tẹra mọ́ àwọn nǹkan tó lè ṣe . Kí wá ni Dáfídì ṣe nígbà tí àṣírí tú ? Àwọn ẹ̀ṣẹ̀ téèyàn ti dá sẹ́yìn ( Wo ìpínrọ̀ 11 sí 14 ) 11 , 12 . ( a ) Kí ni Dáfídì ò lè ṣe lẹ́yìn tó dẹ́ṣẹ̀ ? Ohun tí Dáfídì ò lè ṣe : Dáfídì ò lè dáwọ́ aago pa dà sẹ́yìn . Ó ní láti gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà pé tóun bá ronú pìwà dà tọkàntọkàn , Jèhófà máa dárí ji òun , á sì ran òun lọ́wọ́ láti fara da ìyà ẹ̀ṣẹ̀ òun . Ńṣe ló fi ọ̀rọ̀ lé Jèhófà lọ́wọ́ . Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ Arákùnrin Malcolm tó jẹ́ olóòótọ́ títí tó fi kú lọ́dún 2015 . Kéèyàn máa pọkàn pọ̀ sórí ohun tó lè ṣe , kì í ṣe ohun tí kò lè ṣe . ” ( b ) Báwo lo ṣe máa fi ẹsẹ Ìwé Mímọ́ ọdún 2017 sílò nígbèésí ayé rẹ ? Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wa ti ọdún 2017 : “ Gbẹ́kẹ̀ Lé Jèhófà , Kí O sì Máa Ṣe Rere ” — Sm . 37 : 3 Báwo la ṣe lè fọ̀wọ̀ wọ àwọn míì nígbà tí wọ́n bá ṣèpinnu ? Èmi yóò nífẹ̀ẹ́ wọn láti inú ìfẹ́ àtinúwá tèmi . ” 4 , 5 . ( a ) Ta lẹni tí Ọlọ́run kọ́kọ́ fún lẹ́bùn òmìnira , báwo ló sì ṣe lò ó ? ( b ) Ìbéèrè wo ló yẹ ká bi ara wa ? Ó ṣe pàtàkì ká wá ìdáhùn sí ìbéèrè yìí torí pé bá a bá ṣe lo òmìnira wa ló máa pinnu bóyá a máa ní ìyè àìnípẹ̀kun . Bíbélì sọ pé , Ọlọ́run “ bẹ̀rẹ̀ sí mú wọn wá sọ́dọ̀ ọkùnrin náà láti wo ohun tí yóò pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn . ” Kí ni kò yẹ ká ṣe sí òmìnira tí Jèhófà fún wa ? Ká sọ pé o fún ọ̀rẹ́ rẹ lẹ́bùn kan , ó wá ju ẹ̀bùn náà sí ààtàn tàbí ó ń fi ẹ̀bùn náà pa àwọn míì lára . Kí ló yẹ ká pinnu tá ò bá fẹ́ ṣi òmìnira wa lò ? ( Ka 1 Pétérù 2 : 16 . ) Báwo la ṣe lè fi ìlànà tó wà nínú Gálátíà 6 : 5 sílò ? Ẹ jẹ́ ká rántí ìlànà tó wà nínú Gálátíà 6 : 5 . Báwo lo ṣe lè fi hàn pé o mọyì òmìnira tó o ní ? ( a ) Èrò wo lọ̀pọ̀ èèyàn ní tó bá dọ̀rọ̀ ká mọ̀wọ̀n ara ẹni ? Kí ló túmọ̀ sí pé kéèyàn mọ̀wọ̀n ara ẹni , kí ni kò sì túmọ̀ sí ? Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa dá àwọn èèyàn lẹ́jọ́ ? Báwo ni àpẹẹrẹ Jésù ṣe lè ràn wá lọ́wọ́ bí iṣẹ́ tá à ń ṣe nínú ètò Ọlọ́run bá yí pa dà ? ( Ka Gálátíà 6 : 4 , 5 . ) ( Ka Oníwàásù 11 : ​ 4 - 6 . ) Kí ló máa mú ká jẹ́ amẹ̀tọ́mọ̀wà títí láé ? Kí nìdí tí kò fi rọrùn fáwọn kan láti gbé lára iṣẹ́ wọn fáwọn míì ? Jèhófà ní kí Nátánì sọ fún Dáfídì pé : ‘ Ìwọ kọ́ ni wàá kọ́ ilé tí màá gbé . ’ ( Ka Númérì 11 : 24 - 29 . ) Rárá , ì bá wù mí kí gbogbo àwọn ènìyàn Jèhófà jẹ́ wòlíì , nítorí pé Jèhófà yóò fi ẹ̀mí rẹ̀ sára wọn ! ” ( Ka Fílípì 2 : 20 - 22 . ) Ìwé ìròyìn ọgọ́rùn - ún mẹ́jọ ni ẹ̀ka ọ́fíìsì fi ránṣẹ́ sí wa ká lè rí nǹkan fi ṣiṣẹ́ . Lára àwọn ìlú tí mo ti dá àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ ni Manaus , Belém , Fortaleza , Recife , àti Salvador . A dé ìlú Lisbon , Pọ́túgà ní August 1964 . Ètò yìí nìkan ló ń ṣe iṣẹ́ tí Jésù pa láṣẹ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ , ìyẹn iṣẹ́ wíwàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run . ” Arákùnrin Douglas Guest kú nígbà tá à ń ṣàkójọ ìrírí yìí , ó jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà títí dójú ikú ní October 25 , 2015 . Bákan náà , ‘ ẹ̀mí Jèhófà bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ lára Dáfídì . ’ Kí nìdí tí Ọlọ́run fi rọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n ṣègbọràn sáwọn tó ń darí wọn ? ( Ka Hébérù 1 : ​ 7 , 14 . ) Bíbélì pe Òfin tí Jèhófà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní “ Òfin Mósè . ” 11 , 12 . ( a ) Kí ni Jèhófà sọ pé kí Jóṣúà àtàwọn ọba tó jẹ nílẹ̀ Ísírẹ́lì máa ṣe ? Bíbélì sọ pé : “ Gbàrà tí ọba gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ìwé òfin náà , lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ , ó gbọn ẹ̀wù ara rẹ̀ ya . ” Kí nìdí tí Jèhófà fi bá àwọn kan lára àwọn aṣáájú àwọn èèyàn rẹ̀ wí ? Jèhófà bá àwọn kan lára wọn wí , ó rọ àwọn kan lóye , ó sì fàwọn míì rọ́pò wọn . Kí ló fi hàn pé ẹ̀mí mímọ́ fún Jésù lágbára ? Kò pẹ́ sígbà tí Jésù ṣèrìbọmi , “ àwọn áńgẹ́lì wá , wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìránṣẹ́ fún un . ” Wákàtí mélòó kan kí wọ́n tó pa á , “ áńgẹ́lì kan láti ọ̀run fara hàn án , ó sì fún un lókun . ” Báwo ni Jésù ṣe jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ́ òun sọ́nà nínú ohun tó ń ṣe àti ẹ̀kọ́ tó fi ń kọ́ni ? Lásán ni wọ́n ń jọ́sìn mi , nítorí pé wọ́n ń fi àwọn àṣẹ ènìyàn kọ́ni bí ẹ̀kọ́ . ” Kò sí ẹni rere , àyàfi ẹnì kan , Ọlọ́run . ” “ Ní ìṣẹ́jú akàn , áńgẹ́lì Jèhófà kọlù ú , nítorí pé kò fi ògo fún Ọlọ́run ; àwọn kòkòrò mùkúlú sì jẹ ẹ́ , ó sì gbẹ́mìí mì . ” A máa dáhùn àwọn ìbéèrè yìí nínú àpilẹ̀kọ tó kàn . Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìwé tí Mósè fọwọ́ ara rẹ̀ kọ nìyẹn . Kí nìdí tó fi pọn dandan pé kí wọ́n yan àpọ́sítélì kejìlá ? Àwọn yìí ṣiṣẹ́ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbìmọ̀ olùdarí , wọ́n sì ń darí bí nǹkan ṣe ń lọ ní gbogbo ìjọ . ​ — Ìṣe 15 : 2 . 5 , 6 . ( a ) Báwo ni ẹ̀mí mímọ́ ṣe ran ìgbìmọ̀ olùdarí lọ́wọ́ ? ( d ) Báwo ni Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣe tọ́ ìgbìmọ̀ olùdarí sọ́nà ? Lákọ̀ọ́kọ́ , ẹ̀mí mímọ́ ran ìgbìmọ̀ olùdarí lọ́wọ́ . Ohun kẹta ni pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ́ ìgbìmọ̀ olùdarí sọ́nà . Kí nìdí tá a fi lè sọ pé Jésù ló darí àwọn Kristẹni àkọ́kọ́bẹ̀rẹ̀ ? ( a ) Ìgbà wo ni Jésù yan “ ẹrú olóòótọ́ àti olóye ” ? Ọdún mẹ́ta lẹ́yìn tí Arákùnrin Russell kú , ìyẹn lọ́dún 1919 , Jésù yan “ ẹrú olóòótọ́ àti olóye . ” Ilé Ìṣọ́ July 15 , 2013 jẹ́ ká mọ̀ pé “ ẹrú olóòótọ́ àti olóye ” ni ìwọ̀nba díẹ̀ lára àwọn arákùnrin tó jẹ́ ẹni àmì òróró , àwọn ló sì para pọ̀ jẹ́ Ìgbìmọ̀ Olùdarí . Tọ́rọ̀ bá rí bẹ́ẹ̀ , báwo la ṣe máa dáhùn ìbéèrè Jésù pé : “ Ní ti tòótọ́ , ta ni ẹrú olóòótọ́ àti olóye ? ” Báwo ni ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ṣe ń ran Ìgbìmọ̀ Olùdarí lọ́wọ́ ? Sọ ọ̀nà kan tá a lè gbà máa rántí Ìgbìmọ̀ Olùdarí . Ṣé wàá máa tẹ̀ lé Jésù tó jẹ́ Aṣáájú wa láìbojú wẹ̀yìn ? Kí nìdí ? Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Jésù ti pa dà sọ́run , síbẹ̀ kò gbàgbé àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ . Láìpẹ́ , Jésù máa ṣamọ̀nà wa wọnú ayé tuntun níbi tá a ti máa gbádùn ìyè àìnípẹ̀kun . Lọ́dún 1955 , wọ́n yí orúkọ àjọ náà sí Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania . Jèhófà máa “ ń tù wá nínú nínú gbogbo ìpọ́njú wa ” “ Àní mo ti sọ ọ́ ; èmi yóò mú un wá pẹ̀lú . 1 , 2 . ( a ) Kí ni Jèhófà jẹ́ ká mọ̀ ? ÀWỌN ọ̀rọ̀ tó wà nínú ẹsẹ àkọ́kọ́ nínú Bíbélì sọ pé : “ Ní ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ , Ọlọ́run dá ọ̀run àti ilẹ̀ ayé . ” ( d ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò ? Kí nìdí tó fi jẹ́ pé ìràpadà tí Jésù san ló máa mú kí ìfẹ́ Ọlọ́run ṣẹ ? Sọ díẹ̀ lára àwọn ẹ̀bùn tí Ọlọ́run fún Ádámù àti Éfà . Ohun tó ń dọ́gbọ́n sọ ni pé : ‘ A jẹ́ pé ẹ ò lè ṣe ohun tó wù yín nìyẹn . ’ Àmọ́ ìgbà gbogbo ni Jèhófà máa ń tẹ̀ lé àwọn ìlànà tó fi lélẹ̀ , kò sì ní yí i pa dà . ( Ka Diutarónómì 32 : ​ 4 , 5 . ) Kí nìdí tí ìràpadà fi jẹ́ ẹ̀bùn tó ṣeyebíye ? Kì í ṣe ohun kékeré ló ná Jèhófà láti pèsè ìràpadà náà . Ìgbà wo ni Jèhófà máa di “ ohun gbogbo fún olúkúlùkù ” ? Báwo la ṣe lè fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ orúkọ Jèhófà ? ( Ka 1 Pétérù 1 : 15 , 16 . ) Kí ló mú kí Jèhófà kà wá sí olódodo bó tilẹ̀ jẹ́ pé aláìpé ni wá ? Ó ka àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró sí olódodo , ó sì gbà wọ́n ṣọmọ . Kí ni Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé : “ Kí ìfẹ́ rẹ ṣẹ ” ? Àǹfààní wo ni ìràpadà máa ṣe àwọn tó ti kú ? Kí ni ohun tí Ọlọ́run fẹ́ fún àwọn “ ogunlọ́gọ̀ ńlá ” ? ( a ) Àwọn nǹkan wo ni Jèhófà ń ṣe fún wa báyìí ? ( Ka Ìṣe 3 : 19 - 21 . ) Ẹ̀bùn tí Jèhófà fún wa kọjá ìwàláàyè . Bíbélì sọ pé : “ Àwa fúnra wa sì ti wá mọ̀ , a sì ti gba ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní nínú ọ̀ràn tiwa gbọ́ . Ǹjẹ́ a lè yí ìpinnu kan tá a ti ṣe pa dà ? A máa rí ìdáhùn sáwọn ìbéèrè náà nínú àpilẹ̀kọ yìí . Láìfìyẹn pè , Jèhófà ṣì gbà pé wọ́n fi ọkàn tó pé pérépéré sin òun . Ṣé Ọlọ́run máa gbà pé àwa náà ń fi ọkàn tó pé pérépéré sin òun , bó tilẹ̀ jẹ́ pé à ń ṣàṣìṣe ? Ilé kékeré kan là ń gbé nínú oko kan lápá ìlà oòrùn ìlú South Dakota . Iṣẹ́ àgbẹ̀ ni ìdílé wa ń ṣe , a sì nífẹ̀ẹ́ iṣẹ́ wa gan - an , àmọ́ ìyẹn kọ́ ló ṣe pàtàkì jù sí wa . Lẹ́yìn táwọn òbí mi ya ara wọn sí mímọ́ fún Jèhófà Baba wa ọ̀run , wọ́n ṣèrìbọmi lọ́dún 1934 , wọ́n sì di Ẹlẹ́rìí Jèhófà . Ìránṣẹ́ ìjọ là ń pè ní Olùṣekòkáárí ìgbìmọ̀ àwọn alàgbà báyìí . Ẹ̀gbọ́n mi obìnrin tó ń jẹ́ Dorothy di akéde Ìjọba Ọlọ́run nígbà tó pé ọmọ ọdún mẹ́fà , èmi náà sì ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí mo pé ọmọ ọdún mẹ́fà . Àkókò alárinrin ni ìgbà àpéjọ àyíká àti àgbègbè máa ń jẹ́ fún wa . Mo fi ohun tí Bíbélì sọ sọ́kàn pé : “ Ẹni tí ó bá ń bá àwọn ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n , ” mo sì ní ọ̀pọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n nínú ìdílé wa tí wọ́n tì mí lẹ́yìn láti di aṣáájú - ọ̀nà . Tí wọ́n bá ń bẹ àwọn ìjọ tó wà nítòsí wò , wọ́n máa ń pè mí pé kí n wá bá àwọn jáde lọ wàásù . Èmí rèé nígbà tí mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé Bẹ́tẹ́lì , mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ mọ́tò kan tá a máa ń lò nínú oko Ilé iṣẹ́ rédíò àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tá à ń pè ní WBBR náà wà nínú oko yẹn . Àwa mẹ́ẹ̀ẹ́dógún sí ogún lára ìdílé Bẹ́tẹ́lì ni wọ́n ní kó máa ṣiṣẹ́ nínú oko yẹn . Ọ̀dọ́ ló pọ̀ jù lára àwa tá a wà níbẹ̀ , a ò sì fi bẹ́ẹ̀ nírìírí . Òṣìṣẹ́ kára ni Arákùnrin Peterson ní Bẹ́tẹ́lì , síbẹ̀ wọn ò fi ọwọ́ yẹpẹrẹ mú iṣẹ́ ìwàásù . Èmi àti Angela rèé lọ́dún 1975 , wọ́n fẹ́ fi ọ̀rọ̀ wá wa lẹ́nu wò lórí tẹlifíṣọ̀n Ọdún mẹ́ta lẹ́yìn náà , wọ́n ní ká máa bọ̀ ní Bẹ́tẹ́lì . Kí nìdí tó fi yẹ ká bọlá fún Jèhófà àti Jésù ? Ọlọ́run dá àwa èèyàn ní àwòrán ara rẹ̀ . 8 , 9 . ( a ) Báwo làwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe máa ń ṣe sáwọn aláṣẹ ? ( Ka 1 Tímótì 5 : 17 . ) Bẹ́ẹ̀ ni kí a má pè yín ní ‘ aṣáájú , ’ nítorí ọ̀kan ni Aṣáájú yín , Kristi . Ẹnì yòówù tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ , ẹnì yòówù tí ó bá sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ ni a óò gbé ga . ” Kí nìdí tí kò fi yẹ káwọn míì máa ṣèpinnu fún wa ? ( a ) Kí lá jẹ́ ká máa ṣèpinnu tó mọ́gbọ́n dání ? Kí lá jẹ́ ká máa ṣèpinnu tó mọ́gbọ́n dání ? ( Ka 2 Kọ́ríńtì 1 : 24 . ) Àwọn alàgbà tó nífẹ̀ẹ́ máa ń ran àwọn míì lọ́wọ́ kí wọ́n lè fúnra wọn ṣèpinnu ( Wo ìpínrọ̀ 11 ) Ó tún yẹ káwọn alàgbà máa fara balẹ̀ ṣèwádìí kí wọ́n tó ṣèpinnu . Ṣé á múnú àwọn ará ilé mi dùn , táá sì jẹ́ ká wà ní àlàáfíà ? Ṣé á fi hàn pé mo ní sùúrù , mo sì jẹ́ onínúure ? ’ Kí nìdí tí Jèhófà fi retí pé ká fúnra wa ṣèpinnu ? Kí ló túmọ̀ sí pé kéèyàn fi ọkàn tó pé pérépéré sin Jèhófà ? Èwo lára àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà ni wàá fẹ́ fara wé , kí sì nìdí ? ( Ka 2 Kíróníkà 14 : 11 . ) Kí lọkàn rẹ máa sọ pé kó o ṣe ? Bíbélì sọ pé Jèhóṣáfátì ọmọ Ásà “ ń bá a nìṣó ní rírìn ní ọ̀nà Ásà baba rẹ̀ . ” ( Ka 2 Kíróníkà 20 : 2 - 4 . ) ( Ka Aísáyà 37 : ​ 15 - 20 . ) ( Ka 2 Àwọn Ọba 20 : ​ 1 - 3 . ) ( Ka 2 Kíróníkà 34 : 18 , 19 . ) Kí nìdí tá a fi máa sọ̀rọ̀ nípa àwọn ọba mẹ́rin Júdà ? ( Ka 2 Kíróníkà 16 : 7 - 9 . ) ( Ka 2 Kíróníkà 32 : 31 . ) ( Ka 2 Kíróníkà 35 : 20 - 22 . ) Bíbélì sọ pé ọ̀rọ̀ “ láti ẹnu Ọlọ́run ” ni Nékò sọ fún Jòsáyà . Torí náà , ẹ jẹ́ ká máa ṣàṣàrò lórí àwọn àpẹẹrẹ tó wà nínú Bíbélì , ká sì máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà pé ó fún wa láwọn àpẹẹrẹ bẹ́ẹ̀ ! Ẹ̀jẹ́ mélòó lo ti jẹ́ fún Jèhófà ? Ẹ̀jẹ́ ìyàsímímọ́ rẹ àti ẹ̀jẹ́ ìgbéyàwó rẹ ńkọ́ ? Tó bá ń ṣe wá bíi pé wọ́n hùwà àìdáa sí wa , ohun tá a bá ṣe máa fi hàn bóyá a nígbàgbọ́ , a lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ , a sì tún jẹ́ adúróṣinṣin . “ Ayé ń kọjá lọ , bẹ́ẹ̀ sì ni ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ , ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò dúró títí láé . ” ​ — 1 JÒH . 2 : 17 . Kí ni Jèhófà máa ṣe sáwọn èèyàn burúkú àtàwọn ètò búburú ayé yìí ? Bíbélì sọ pé : “ Ayé ń kọjá lọ . ” Kò sí òkùnkùn tàbí ibú òjìji èyíkéyìí fún àwọn aṣenilọ́ṣẹ́ láti fi ara wọn pa mọ́ níbẹ̀ . ” Ní ẹsẹ míì nínú sáàmù kan náà , ó sọ pé : “ Àwọn olódodo ni yóò ni ilẹ̀ ayé , wọn yóò sì máa gbé títí láé lórí rẹ̀ . ” Àwọn wo ni “ ọlọ́kàn tútù ” àti “ olódodo ” ? Kí ló jẹ́ kó dá wa lójú pé ayé tuntun máa wà létòlétò ? Ṣé ètò míì máa wà láyé yìí lẹ́yìn ogun Amágẹ́dọ́nì ? Torí náà , àwọn nǹkan máa wà létòlétò nínú “ ayé tuntun . ” Ìwàkiwà wo ló wọ́pọ̀ lágbègbè tó ò ń gbé , báwo làwọn ìwà náà sì ṣe kan ìwọ àti ìdílé rẹ ? Kí la rí kọ́ nínú bí Jèhófà ṣe pa àwọn èèyàn Sódómù àti Gòmórà run ? ( Ka 2 Pétérù 2 : ​ 6 - 8 . ) ( Ka Sáàmù 46 : ​ 8 , 9 . ) Àwọn nǹkan wo ni kò ní sí mọ́ títí láé lẹ́yìn Amágẹ́dọ́nì ? Ṣàpèjúwe . ( b ) Kí ló yẹ ká ṣe ká lè wà títí láé nígbà tí ayé búburú yìí kò bá sí mọ́ ? Ó DÁ Ábúráhámù lójú pé Jèhófà máa ṣèdájọ́ tó tọ́ fáwọn èèyàn Sódómù àti Gòmórà . Ìdí ni pé tó bá di pé ká ṣe ìdájọ́ òdodo , kò sẹ́ni tá a lè fi wé Jèhófà . Àwa Kristẹni mọ̀ pé kò sí káwọn èèyàn inú ayé má hùwà àìṣòdodo sí wa . Nígbà tó di ọdún 1946 , ó lọ sí kíláàsì kẹjọ ti Ilé Ẹ̀kọ́ Gílíádì nílùú New York lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà . Lẹ́yìn tó kẹ́kọ̀ọ́ yege , wọ́n ní kó máa ṣe iṣẹ́ alábòójútó àyíká lórílẹ̀ - èdè Switzerland . Àwọn àpẹẹrẹ wo la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí àtèyí tó tẹ̀ lé e ? Nínú àpilẹ̀kọ yìí , a máa jíròrò nípa Jósẹ́fù tó jẹ́ àtọmọdọ́mọ Ábúráhámù àtohun táwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ṣe fún un . 10 , 11 . ( a ) Ìwà àìdáa wo làwọn èèyàn hù sí Jósẹ́fù ? ( Ka Mátíù 5 : ​ 23 , 24 ; 18 : 15 . ) Tá a bá jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà , tá a sì nífẹ̀ẹ́ àwọn arákùnrin wa , a ò ní ṣe irú àṣìṣe bẹ́ẹ̀ . Ní pàtàkì jù , kò jẹ́ kí àìpé àti àṣìṣe àwọn míì mú kó fi Jèhófà sílẹ̀ . Kí nìdí tó fi yẹ ká túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà tí wọ́n bá ṣàìdáa sí wa nínú ìjọ ? Báwo la ṣe lè fi hàn pé a gbẹ́kẹ̀ lé “ Onídàájọ́ gbogbo ilẹ̀ ayé ” ? Wo ìtàn ìgbésí ayé Willi Diehl nínú Ilé - Ìṣọ́nà ti November 1 , 1991 , a pe àkòrí rẹ̀ ní , “ Jehofa ni Ọlọrun Mi , Ninu Ẹni Ti Emi Yoo Nigbẹkẹle . ” ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí . ) ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa dáhùn nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Àpẹẹrẹ àtàtà ni wọ́n jẹ́ fún àwa ìránṣẹ́ Jèhófà tá a yàn láti jẹ́jẹ̀ẹ́ fún un . Báwo ni ẹ̀jẹ́ téèyàn jẹ́ fún Ọlọ́run ṣe lágbára tó ? Kí la rí kọ́ lára Jẹ́fútà àti Hánà ? 2 , 3 . ( a ) Kí ló túmọ̀ sí tá a bá léèyàn jẹ́jẹ̀ẹ́ ? ( b ) Kí ni Ìwé Mímọ́ sọ nípa ẹ̀jẹ́ téèyàn jẹ́ fún Ọlọ́run ? Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó jáde ní ẹnu rẹ̀ ni kí ó ṣe . ” ( a ) Kí nìdí tá a fi sọ pé kéèyàn jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Ọlọ́run kì í ṣe ọ̀rọ̀ ṣeréṣeré ? ( b ) Kí la máa kọ́ nípa Jẹ́fútà àti Hánà ? ( a ) Báwo ló ṣe rọrùn tó fún Jẹ́fútà àti ọmọbìnrin rẹ̀ láti san ẹ̀jẹ́ tí Jẹ́fútà jẹ́ ? Bí àpẹẹrẹ , Jẹ́fútà sọ pé : ‘ Mo ti la ẹnu mi sí Jèhófà , èmi kò sì lè yí i pa dà . ’ ( b ) Kí ni ẹ̀jẹ́ tí Hánà jẹ́ máa gba pé kí Sámúẹ́lì ṣe ? Ó mú Sámúẹ́lì lọ bá Élì Àlùfáà Àgbà tó wà níbi àgọ́ ìjọsìn ní Ṣílò , ó wá sọ pé : “ Ọmọdékùnrin yìí ni mo gbàdúrà nípa rẹ̀ pé kí Jèhófà yọ̀ǹda ìtọrọ tí mo ṣe lọ́dọ̀ rẹ̀ . Ẹ̀jẹ́ míì tó tún ṣe pàtàkì gan - an téèyàn lè jẹ́ ni ẹ̀jẹ́ ìgbéyàwó . Kí ni Bíbélì sọ nípa ìkọ̀sílẹ̀ àti ìpínyà ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 7 : ​ 10 , 11 . ) Tọkọtaya kan sọ pé : “ Àtìgbà tá a ti ń kẹ́kọ̀ọ́ ìwé yìí la ti túbọ̀ ń láyọ̀ . ” Látìgbà tá a ti ń fi ìmọ̀ràn inú rẹ̀ sílò la ti ń gbádùn ara wa . ” 18 , 19 . ( a ) Kí ni ọ̀pọ̀ òbí Kristẹni ti ṣe ? ( b ) Kí la lè sọ nípa àwọn tó wà nínú àkànṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún ? Ẹ̀jẹ́ àkànṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún ( Wo ìpínrọ̀ 19 ) Iṣẹ́ ìsìn tí wọ́n ń ṣe ló jẹ́ àkànṣe , kì í ṣe àwọn fúnra wọn . Wo ìwé ‘ Ẹ Dúró Nínú Ìfẹ́ Ọlọ́run , ’ Àfikún “ Ohun Tí Bíbélì Sọ Nípa Ìkọ̀sílẹ̀ àti Ìpínyà . ” Olódùmarè ha ní inú dídùn rárá sí jíjẹ́ tí o jẹ́ olódodo , tàbí èrè èyíkéyìí nínú ṣíṣe tí o ṣe ọ̀nà rẹ ní aláìlẹ́bi ? ” ( b ) Báwo làwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe ṣẹ́gun àwọn ọmọ ogun Jábínì ? ( Ka Àwọn Onídàájọ́ 4 : ​ 14 - 16 . ) Ọ̀gbàrá Kíṣónì gbá wọn lọ . ” Wo àpilẹ̀kọ tá a pè ní “ “ Àníyàn Nípa Owó ” ” nínú Ilé Ìṣọ́ July 1 , 2015 . 1 , 2 . ( a ) Kí ló ṣẹlẹ̀ sí Nábótì àtàwọn ọmọ rẹ̀ ? ( b ) Ànímọ́ méjì wo la máa gbé yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Irú èèyàn wo ni Nábótì , kí sì nìdí tó fi kọ̀ láti ta ọgbà àjàrà rẹ̀ fún Ọba Áhábù ? Nábótì jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà bó tilẹ̀ jẹ́ pé àpẹẹrẹ búburú Ọba Áhábù àti Jésíbẹ́lì ìyàwó rẹ̀ ni ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń tẹ̀ lé . Ka 1 Àwọn Ọba 21 : ​ 1 - 3 . Nábótì fìrẹ̀lẹ̀ sọ fún Ọba pé : “ Kò ṣeé ronú kàn níhà ọ̀dọ̀ mi , ní ojú ìwòye Jèhófà , pé kí n fi ohun ìní àjogúnbá àwọn baba ńlá mi fún ọ . ” Kí nìdí tí Nábótì fi kọ̀ ? Báwo ni ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ ò ṣe ní jẹ́ káwọn ẹbí àti ọ̀rẹ́ Nábótì ṣinú rò ? ( Ka Diutarónómì 32 : ​ 3 , 4 . ) ( b ) Àwọn ọ̀nà wo ni ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ máa gbà ràn wá lọ́wọ́ ? Kí lo máa ṣe táwọn alàgbà bá ṣèpinnu kan tí kò bá ẹ lára mu ? Ìṣẹ̀lẹ̀ wo la fẹ́ gbé yẹ̀ wò , kí sì nìdí ? Báwo ni wọ́n ṣe tún èrò Pétérù ṣe , àwọn ìbéèrè wo ló sì jẹyọ ? Kódà nígbà tó yá , Ọlọ́run mí sí i láti kọ lẹ́tà méjì tó wá di apá kan Bíbélì . 3 Bá A Ṣe Lè Ran Àwọn Àjèjì Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Máa ‘ Fayọ̀ Sin Jèhófà ’ Àpilẹ̀kọ kejì sọ báwọn òbí tó ń wá ibi ìsádi ṣe lè fàwọn ìlànà Bíbélì sílò kí wọ́n sì ṣèpinnu tó máa ṣe àwọn ọmọ wọn láǹfààní . Ṣe là ń gbúròó ìbọn , a sì ń rí báwọn èèyàn ṣe ń sá kiri . Àwọn òbí mi kó gbogbo àwa ọmọ mọ́kànlá , ó di lẹ - lẹ - lẹ pẹ̀lú ìwọ̀nba aṣọ tá a kó dání . Kí ló mú kí Jésù àti ọ̀pọ̀ lára àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ di ẹni tó ń wá ibi ìsádi ? Ìdí nìyẹn tó fi sọ pé : “ Nígbà tí wọ́n bá ṣe inúnibíni sí yín ní ìlú ńlá kan , ẹ sá lọ sí òmíràn . ” ( b ) tí wọ́n bá wà ní ibùdó ? Mo wá sọ fáwọn tó kù pé kí wọ́n máa lọ . Àmọ́ bàbá mi ò fẹ́ káwọn apààyàn yẹn bá mi níbẹ̀ , ni wọ́n bá gbé mi . Ohun tí wọ́n ń ṣe ò ju pé kí wọ́n máa ṣòfófó , kí wọ́n mutí , kí wọ́n ta tẹ́tẹ́ , kí wọ́n jalè , kí wọ́n sì máa ṣèṣekúṣe . ” ( Ka 1 Jòhánù 3 : 17 , 18 . ) ( b ) Kí nìdí tó fi yẹ ká fi sùúrù ràn wọ́n lọ́wọ́ ? Torí náà , ó ṣe pàtàkì pé ká tètè kàn sáwọn ará tó ń wá ibi ìsádi ní gbàrà tí wọ́n bá dé . ( b ) Báwo làwọn tó ń wá ibi ìsádi ṣe lè fi hàn pé àwọn lẹ́mìí ìmoore ? Báwo la ṣe lè ran àwọn ará tó ń wá ibi ìsádi lọ́wọ́ ? ( a ) Kí làwọn tó ń wá ibi ìsádi gbọ́dọ̀ ṣọ́ra fún ? Nígbà tó yá , ó fi àpò òfìfo tá a kó àwọn nǹkan náà sí hàn wá , ó rẹ́rìn - ín , ó wá sọ pé : ‘ Ṣẹ́ ẹ rí i , ẹ ò nílò gbogbo nǹkan yẹn ! ’ ” ​ — Ka 1 Tímótì 6 : 8 . Torí náà , a gbọ́dọ̀ jẹ́ kí wọ́n rí i pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ wọn àti pé àwa náà nífẹ̀ẹ́ wọn . Ọ̀pọ̀ lára àwọn tó ń wá ibi ìsádi ló wá láti àwọn orílẹ̀ - èdè tí wọ́n ti fòfin de iṣẹ́ ìwàásù wa . Arábìnrin náà sọ pé : “ Ṣe làwọn ará gbà wá tọwọ́tẹsẹ̀ àfi bí ọmọ ìyá , wọ́n fún wa lóúnjẹ àti aṣọ , kódà wọ́n pèsè ibi tá a máa gbé , wọ́n sì máa ń fún wa lówó tá a lè fi wọkọ̀ . ” Ó wá fi kún un pé : “ Àwọn wo ló lè gba ẹni tí wọn ò mọ̀ rí sílé torí pé wọ́n jọ ń ṣe ẹ̀sìn kan náà ? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà nìkan ni ! ” ​ — Ka Jòhánù 13 : 35 . Gbàrà tí àwọn tó ń wá ibi ìsádi bá ti dé , kí àwọn alàgbà tẹ̀ lé ìtọ́ni tó wà nínú A Ṣètò Wa Láti Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà , orí 8 , ìpínrọ̀ 30 . Àmọ́ bí wọ́n ṣe ń ṣe ìwádìí yẹn lọ , wọ́n lè fọgbọ́n béèrè lọ́wọ́ ẹni náà nípa ìjọ rẹ̀ àtàwọn nǹkan míì tó jẹ mọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ , kí wọ́n lè mọ bó ṣe ń ṣe sí nínú ìjọ . “ Èmi kò ní ìdí kankan tí ó tóbi ju nǹkan wọ̀nyí lọ fún ṣíṣọpẹ́ , pé kí n máa gbọ́ pé àwọn ọmọ mi ń bá a lọ ní rírìn nínú òtítọ́ . ” ​ — 3 JÒH . Báwo làwọn òbí ṣe lè fi àpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀ fáwọn ọmọ wọn ? Báwo làwọn olórí ìdílé ṣe lè pinnu ìjọ tó yẹ kí ìdílé wọn máa lọ ? Báwo làwọn míì ṣe lè ṣèrànwọ́ fáwọn òbí àtàwọn ọmọ tó ṣí wá sórílẹ̀ - èdè wọn ? 1 , 2 . ( a ) Ìṣòro wo ni ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ tí òbí wọn jẹ́ àjèjì máa ń ní ? ( b ) Àwọn ìbéèrè wo la máa jíròrò nínú àpilẹ̀kọ yìí ? Àmọ́ lẹ́yìn tí mo bẹ̀rẹ̀ iléèwé , èdè tí wọ́n ń sọ ládùúgbò ibi tá a kó lọ ni mo bẹ̀rẹ̀ sí í sọ . Lẹ́yìn ọdún díẹ̀ , èdè yẹn nìkan ni mò ń sọ . Bó ṣe di pé mi ò lóye nǹkan tí wọ́n ń sọ nípàdé mọ́ nìyẹn , àṣà ìbílẹ̀ àwọn òbí mi ò sì bá mi lára mu mọ́ . ” 3 , 4 . ( a ) Báwo làwọn òbí ṣe lè fi àpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀ fáwọn ọmọ wọn ? ( b ) Kí ni kò yẹ káwọn òbí máa retí látọ̀dọ̀ àwọn ọmọ wọn ? Táwọn ọmọ yín bá rí i pé ẹ̀ ń ‘ wá ìjọba náà lákọ̀ọ́kọ́ , ’ èyí á mú káwọn náà gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà pé á pèsè ohun tí wọ́n nílò lójoojúmọ́ . Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọwọ́ yín dí débi tẹ́ ò fi ní ráyè tàwọn ọmọ yín . Àǹfààní wo làwọn ọmọ rẹ máa rí tí wọ́n bá gbọ́ èdè ìbílẹ̀ rẹ ? Ẹ̀yin òbí , tó bá jẹ́ pé ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sáwọn ọmọ yín nìyẹn , ṣé ẹ̀yin náà lè sapá láti kọ́ èdè tí wọ́n ń sọ nílùú tẹ́ ẹ wà ? Bákan náà , tó bá jẹ́ èdè míì lọmọ yín gbọ́ dáadáa , ṣé kò yẹ kẹ́ ẹ sapá láti kọ́ èdè náà kẹ́ ẹ lè jọ máa sọ̀rọ̀ dáadáa ? Tọ́rọ̀ bá rí bẹ́ẹ̀ , o ṣì lè kọ́ àwọn ọmọ rẹ láti mọ Jèhófà kí wọ́n sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ . Àmọ́ a máa ń rí bí wọ́n ṣe ń dá kẹ́kọ̀ọ́ , tí wọ́n ń gbàdúrà tí wọ́n sì ń sapá ká lè máa ṣe ìjọsìn ìdílé wa lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ . Tó bá gba pé kí ọmọ kan fi èdè méjì kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ , báwo làwọn òbí ṣe lè ran irú ọmọ bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ ? ( a ) Ta ló máa pinnu ìjọ tí ìdílé kan máa lọ ? Àmọ́ , tó bá jẹ́ pé èdè táwọn ọmọ wọn gbọ́ dáadáa ni wọ́n ń sọ nípàdé , wọ́n á lóye ohun tí wọ́n ń sọ ju báwọn òbí wọn ṣe rò lọ . ( Ka 1 Kọ́ríńtì 14 : 9 , 11 . ) Ohun tó wá ṣe kedere sí wa pé ká ṣe kò fi bẹ́ẹ̀ bá wa lára mu . Àmọ́ , nígbà tá a rí i pé àwọn ọmọ wa ò fi bẹ́ẹ̀ lóye ohun tí wọ́n ń sọ níjọ tó ń sọ èdè ìbílẹ̀ wa , a pinnu pé a máa lọ sí ìjọ tó ń sọ èdè àdúgbò ibi tá à ń gbé . A jọ máa ń lọ sípàdé àti òde ẹ̀rí déédéé . A tún máa ń pe àwọn ará pé kí wọ́n wá jẹun nílé wa , ká sì jọ gbafẹ́ jáde . Ohun tó jẹ́ káwọn ọmọ wa mọ àwọn ará dáadáa nìyẹn , ó tún mú kí wọ́n sún mọ́ Jèhófà , kí wọ́n sì rí i bíi Bàbá àti Ọ̀rẹ́ wọn . Ohun tó ṣe pàtàkì jù sí wa nìyẹn , kì í ṣe pé kí wọ́n ṣáà ti gbọ́ èdè wa . ” Samuel tún sọ pé : “ Èmi àtìyàwó mi máa ń lọ síjọ tó ń sọ èdè ìbílẹ̀ wa kí ẹ̀kọ́ òtítọ́ lè túbọ̀ yé wa sí i . Ọwọ́ wa máa ń dí gan - an , ó sì máa ń rẹ̀ wá . Àmọ́ , a dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà pé ó bù kún gbogbo ìsapá wa àtàwọn ohun tá a yááfì . Ní báyìí , àwọn ọmọ wa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ló ń ṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún . ” Ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Kristina sọ pé : “ Mo lóye díẹ̀ nínú èdè àwọn òbí mi , àmọ́ èyí tí wọ́n ń sọ nípàdé kò yé mi rárá . Nígbà tí mo wà lọ́mọ ọdún méjìlá , mo lọ sí àpéjọ àgbègbè kan tí wọ́n ṣe ní èdè tá a fi ń kẹ́kọ̀ọ́ níléèwé . Fúngbà àkọ́kọ́ , òtítọ́ yé mi kedere ! Ẹ̀yin ọ̀dọ́ , ṣé ẹ máa fẹ́ lọ síjọ tó ń sọ èdè tí wọ́n ń sọ ládùúgbò yín ? Arábìnrin Nadia tó ń sìn ní Bẹ́tẹ́lì báyìí sọ pé : “ Nígbà táwa ọmọ dàgbà , a fẹ́ máa lọ síjọ tó ń sọ èdè tí wọ́n ń sọ ládùúgbò wa . ” Nadia wá sọ pé : “ Inú wa dùn pé àwọn òbí wa sapá gan - an láti kọ́ wa lédè ìbílẹ̀ wa àti pé wọn ò jẹ́ ká lọ síjọ míì . Ohun tí wọ́n ṣe yìí mú kí ìgbésí ayé wa nítumọ̀ , ó sì ti jẹ́ ká láǹfààní láti ran àwọn míì lọ́wọ́ kí wọ́n lè mọ Jèhófà . ” ( b ) Báwo làwọn míì ṣe lè ran àwọn òbí lọ́wọ́ kí òtítọ́ lè jinlẹ̀ lọ́kàn àwọn ọmọ wọn ? ( Ka Òwe 1 : 8 ; 31 : 10 , 27 , 28 . ) Síbẹ̀ , táwọn òbí kan ò bá gbọ́ èdè tí wọ́n ń sọ ládùúgbò tí wọ́n ṣí lọ , ó lè gba pé káwọn míì ràn wọ́n lọ́wọ́ kí ẹ̀kọ́ òtítọ́ lè dọ́kàn àwọn ọmọ náà . Àwọn òbí àtàwọn ọmọ ló máa jàǹfààní tí wọ́n bá ń bá àwọn Kristẹni kẹ́gbẹ́ ( Wo ìpínrọ̀ 18 àti 19 ) ( b ) Kí làwọn òbí gbọ́dọ̀ máa ṣe ? Ọ̀pọ̀ nǹkan ni mo máa ń kọ́ tá a bá jọ ń múra iṣẹ́ tí mo ní nípàdé sílẹ̀ . Mo sì máa ń gbádùn àwọn àkókò tá a máa ń lò pa pọ̀ . ” Ẹ̀yin òbí , ẹ bẹ Jèhófà pé kó ràn yín lọ́wọ́ , kẹ́ ẹ sì ṣe gbogbo ohun tẹ́ ẹ lè ṣe . ( Ka 2 Kíróníkà 15 : 7 . ) Kì í ṣe ohun tó wù yín ló yẹ kẹ́ ẹ kà sí pàtàkì jù bí kò ṣe báwọn ọmọ yín ṣe máa sún mọ́ Jèhófà . Àmọ́ lẹ́yìn - ọ̀ - rẹyìn , mo kọ́ èdè àwọn adití , mo sì ń gbádùn kí n máa bá àwọn ọmọ tó kù ṣeré . Ó tún fẹ́ kí n bá ọkọ rẹ̀ tó ń jẹ́ Gary sọ̀rọ̀ . Èyí mú kí márùn - ún lára àwọn ọmọ kíláàsì wọn di Ẹlẹ́rìí Jèhófà . Ó fún mi ní súìtì kan , ó sì bi mí bóyá a lè jọ jọ́rẹ̀ẹ́ . Nígbà tó fẹ́ ṣèrìbọmi , àwọn òbí rẹ̀ sọ fún un pé , “ Tó o bá mọ̀ pé Ẹlẹ́rìí Jèhófà lo fẹ́ ṣe , wàá kó jáde nílé yìí ! ” Ó ń bá ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ lọ , ó sì ṣèrìbọmi . Nígbà témi àti ẹ̀ ṣègbéyàwó lọ́dún 1960 , àwọn òbí rẹ̀ kò wá síbi ìgbéyàwó wa . Nicholas ọmọ mi àti Deborah ìyàwó rẹ̀ ń ṣiṣẹ́ ní ẹ̀ka ọ́fíìsì wa ní London Faye àti James , Jerry àti Evelyn , Shannan àti Steven Mo wá ń dara pọ̀ mọ́ ìjọ tó ń sọ èdè àwọn adití nílùú Calgary , mo sì jẹ́ alàgbà níbẹ̀ . Kí la lè ṣe tí ìfẹ́ tá a ní fún Jèhófà ò fi ní di tútù ? Kí la lè ṣe kí ìfẹ́ tá a ní fún ẹ̀kọ́ òtítọ́ lè túbọ̀ jinlẹ̀ ? Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká nífẹ̀ẹ́ àwọn ará wa ? Kí ló ṣeé ṣe kó fà á tí ìfẹ́ àwọn Kristẹni kan fi di tútù ? Lóde òní , ṣe ni ìfẹ́ táwọn èèyàn ní fún Ọlọ́run túbọ̀ ń dín kù sí i . Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà ( Wo ìpínrọ̀ 10 ) ( Ka Sáàmù 119 : 97 - 100 . ) Nífẹ̀ẹ́ ẹ̀kọ́ òtítọ́ ( Wo ìpínrọ̀ 14 ) Ní alẹ́ ọjọ́ tí Jésù lò kẹ́yìn láyé , ó sọ fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé : “ Èmi ń fún yín ní àṣẹ tuntun kan , pé kí ẹ nífẹ̀ẹ́ ara yín lẹ́nì kìíní - kejì ; gan - an gẹ́gẹ́ bí mo ti nífẹ̀ẹ́ yín , pé kí ẹ̀yin pẹ̀lú nífẹ̀ẹ́ ara yín lẹ́nì kìíní - kejì . Nípa èyí ni gbogbo ènìyàn yóò fi mọ̀ pé ọmọ ẹ̀yìn mi ni yín , bí ẹ bá ní ìfẹ́ láàárín ara yín . ” ​ — Jòh . 13 : 34 , 35 . Àpọ́sítélì Jòhánù sọ pé : “ Ẹni tí kò nífẹ̀ẹ́ arákùnrin rẹ̀ , tí òun rí , kò lè máa nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run , tí kò rí . ” Nífẹ̀ẹ́ àwọn ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin ( Wo ìpínrọ̀ 17 ) Àwọn nǹkan wo la lè ṣe táá fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ àwọn ará wa ? Ka 1 Tẹsalóníkà 4 : 9 , 10 . 21 : 15 . Ó wá sọ fún wọn pé “ ‘ Ẹ ju àwọ̀n sí ìhà ọ̀tún ọkọ̀ ojú omi , ẹ ó sì rí díẹ̀ . ’ Nígbà náà ni wọ́n jù ú , ṣùgbọ́n wọn kò lè fà á wọlé mọ́ nítorí ògìdìgbó ẹja . ” ​ — Jòh . 21 : 1 - 6 . ( b ) Ẹ̀kọ́ pàtàkì wo ni arákùnrin kan lórílẹ̀ - èdè Thailand kọ́ nípa iṣẹ́ rẹ̀ ? Nígbà tó yá , mo wá rí i pé tí mo bá máa fọ̀rọ̀ Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́ , àfi kí n wáṣẹ́ míì ṣe . ” Arákùnrin náà sọ pé : “ Lẹ́yìn ọdún kan tí mo fi tuwó jọ , mo bẹ̀rẹ̀ sí í ta áásìkiriìmù . Níbẹ̀rẹ̀ , ọjà náà ò tà , ọ̀rọ̀ náà wá tojú sú mi . Yàtọ̀ síyẹn , bí mo bá pàdé àwọn tá a jọ ń ṣiṣẹ́ tẹ́lẹ̀ , ṣe ni wọ́n máa ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́ , wọ́n máa ń bi mí pé kí ló sún mi dédìí iṣẹ́ tí mò ń ṣe , èmi tí mò ń ṣiṣẹ́ nínú ọ́fíìsì tí ọyẹ́ ti ń fẹ́ ni mo wá ń jókòó sídìí ọjà . Mo máa ń gbàdúrà sí Jèhófà , mo máa ń bẹ̀ ẹ́ pé kó jẹ́ kí n lè fara dà á , kí n sì lè túbọ̀ máa ráyè fún àwọn nǹkan tẹ̀mí . Mo wá mọ irú áásìkiriìmù táwọn oníbàárà mi fẹ́ . Lẹ́yìn yẹn , wàràwàrà ni mò ń tà , kódà ọjà mi kì í ṣẹ́ kù . Kí n sòótọ́ , mo wá lówó lọ́wọ́ ju ìgbà tí mò ń ṣiṣẹ́ ní ọ́fíìsì . Ní báyìí , kò sóhun tó ń kó mi lọ́kàn sókè mọ́ bíi ti àtijọ́ , èyí sì ń fún mi láyọ̀ . Àmọ́ , ohun tó fún mi láyọ̀ jù ni pé mo túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà . ” ​ — Ka Mátíù 5 : 3 , 6 . Lẹ́yìn tó ṣèrìbọmi , ó sọ pé : “ Ohun kan ṣoṣo tí mo kábàámọ̀ ni pé mo ti fọ̀pọ̀ àkókò ṣòfò kí n tó mọ̀ pé ìjọsìn Jèhófà ló máa ń fúnni láyọ̀ kì í ṣe eré ìnàjú táyé ń gbé lárugẹ . ” Jésù sọ pé “ kò sí ẹnì kan tí ó lè sìnrú fún ọ̀gá méjì . ” Ó tún sọ pé : “ Ẹ kò lè sìnrú fún Ọlọ́run àti fún Ọrọ̀ . ” ( Ka 1 Kọ́ríńtì 2 : 14 . ) Wo àpilẹ̀kọ náà “ Ṣé Eré Ìtura Tó O Yàn Máa Ṣe Ẹ́ Láǹfààní ? ” A tún máa ń lọ sóde ẹ̀rí déédéé . ” Ó dùn wá gan - an pé a máa fi àwọn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wa sílẹ̀ . ” Àmọ́ ohun kan ṣẹlẹ̀ lóṣù kan lẹ́yìn náà . Miriam sọ pé : “ Ètò Ọlọ́run sọ wá di aṣáájú - ọ̀nà àkànṣe . Inú wa dùn pé àá ṣì máa bá iṣẹ́ ìsìn wa lọ ! ” Wọ́n gbà pé ìlérí Jèhófà tó wà nínú Sáàmù 37 : 5 máa ṣẹ sáwọn lára , pé : “ Yí ọ̀nà rẹ lọ sọ́dọ̀ Jèhófà , kí o sì gbójú lé e , òun yóò sì gbé ìgbésẹ̀ . ” Ní báyìí , ohun tá à ń ṣe gan - an nìyẹn , a ò sì ṣaláìní àwọn nǹkan tó pọn dandan . ” Kí nìdí tá a fi lè retí pé àwọn tó ṣègbéyàwó àtàwọn tó ní ìdílé máa níṣòro ? Ó dá wa lójú pé ire wa ni Jèhófà ń fẹ́ bó ṣe fẹ́ ire fáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nígbà àtijọ́ . ​ — Ka Jeremáyà 29 : ​ 11 , 12 . ( Ka 1 Sámúẹ́lì 1 : ​ 4 - 7 . ) Paula wá sọ pé : “ Bó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi àti Ann kò bára wa tan , síbẹ̀ bó ṣe fà mí mọ́ra tù mí nínú gan - an . Ohun tó jẹ́ kí n máa sin Jèhófà nìṣó nìyẹn . ” ( Ka Sáàmù 145 : ​ 18 , 19 . ) “ Ibi tí ìṣúra yín bá wà , ibẹ̀ ni ọkàn - àyà yín yóò wà pẹ̀lú . ” ​ — LÚÙKÙ 12 : 34 . Bá a ṣe ń ṣe bẹ́ẹ̀ , máa ronú lórí ohun tó o lè ṣe táá jẹ́ kó o túbọ̀ nífẹ̀ẹ́ àwọn ìṣúra tẹ̀mí yìí . Ṣé ìwọ náà rí bí péálì tí ọkùnrin yẹn rí ti ṣeyebíye sí i tó ? ( Ka Máàkù 10 : ​ 28 - 30 . ) ( a ) Kí nìdí tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi sọ pé iṣẹ́ ìwàásù dà bí ‘ ìṣúra nínú àwọn ohun èlò tí a fi amọ̀ ṣe ’ ? ( Ka Róòmù 1 : ​ 14 , 15 ; 2 Tímótì 4 : 2 . ) Àwọn kan nínú wọn ń sìn ní Bẹ́tẹ́lì , aṣáájú - ọ̀nà làwọn kan , àwọn míì sì jẹ́ alàgbà . Irene wá sọ pé : “ Ọ̀pọ̀ nǹkan míì ni mo lè fayé mi ṣe , àmọ́ kò séyìí tó lè fún mi láyọ̀ bí èyí tí mò ń ṣe yìí . ” Kí ni “ ibi ìtọ́jú ìṣúra ” tí Jésù sọ nínú Mátíù 13 : ​ 52 , báwo la sì ṣe máa kó nǹkan sínú rẹ̀ ? ( Ka Òwe 2 : ​ 4 - 7 . ) Ẹ jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ arákùnrin kan tó ń jẹ́ Peter . Àmọ́ kó lè dán Peter wò , ó bi í pé : “ Ọmọ dáadáa , èdè wo lo rò pé wọ́n fi kọ ìwé Dáníẹ́lì ? ” Nígbà tí mo délé , mo lọ wo àwọn ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ àti Jí ! tí mo ti kà láwọn oṣù mélòó kan sẹ́yìn , mo sì rí àpilẹ̀kọ kan tó sọ pé èdè Árámáíkì ni wọ́n fi kọ ìwé Dáníẹ́lì . ” Bó o ṣe ń ṣe bẹ́ẹ̀ , wàá máa to ìṣúra jọ sí ọ̀run ‘ níbi tí olè kò lè dé tàbí kí òólá jẹ run . Nítorí ibi tí ìṣúra rẹ bá wà , ibẹ̀ ni ọkàn - àyà rẹ yóò wà pẹ̀lú . ’ ​ — Lúùkù 12 : ​ 33 , 34 . “ Èmi àti arákùnrin kan tá a jọ ń ṣiṣẹ́ kì í gbọ́ ara wa yé . Lọ́jọ́ kan , ṣe la bẹ̀rẹ̀ sí í pariwo mọ́ ara wa , bí àwọn méjì kan ṣe wọlé nìyẹn . ” ​ — CHRIS . “ Ìyàlẹ́nu ló jẹ́ fún mi nígbà tí arábìnrin kan tá a jọ máa ń lọ sóde ẹ̀rí ṣàdédé lóun ò bá mi jáde mọ́ . Mi ò sì mọ ohun tó fà á . ” ​ — JANET . “ Àwa mẹ́ta la jọ ń sọ̀rọ̀ lórí fóònù . Nígbà tó yá , ọ̀kan lára wa dágbére fún wa , mo sì rò pé ó ti kúrò . Ni mo bá bẹ̀rẹ̀ sí í sọ̀rọ̀ ẹ̀ láìdáa fún ẹnì kejì , láìmọ̀ pé onítọ̀hún kò tíì gbé fóònù sílẹ̀ . ” ​ — MICHAEL . “ Nínú ìjọ wa , aáwọ̀ kan ṣẹlẹ̀ láàárín àwọn aṣáájú - ọ̀nà méjì . Ohun tó ṣẹlẹ̀ láàárín wọn yẹn kò dùn mọ́ àwọn ará nínú rárá . ” ​ — GARY . “ Ẹ má ṣe dá ara yín lágara [ tàbí bínú ] síra yín lójú ọ̀nà . ” “ Àwọn ìwéwèé máa ń já sí pàbó níbi tí kò bá ti sí ọ̀rọ̀ ìfinúkonú . ” Michael sọ pé : “ Ó dárí jì mí , ọ̀rọ̀ náà sì tán nínú rẹ̀ . ” “ Ẹ máa bá a lọ ní fífaradà á fún ara yín lẹ́nì kìíní - kejì , kí ẹ sì máa dárí ji ara yín fàlàlà lẹ́nì kìíní - kejì bí ẹnikẹ́ni bá ní ìdí fún ẹjọ́ lòdì sí ẹlòmíràn . ” Ní báyìí , àárín wọn ti gún , wọ́n sì ń bára wọn ṣiṣẹ́ lóde ẹ̀rí . Ìyàtọ̀ tó wà láàárín àwọn méjèèjì lè má fi bẹ́ẹ̀ jọni lójú , síbẹ̀ ó lè fa wàhálà . ” Torí bọ́rọ̀ náà ṣe rí lára mi , tó bá bá mi sọ̀rọ̀ , ṣe ni mo máa ń dá a lóhùn gán - ín . Mo ronú pé , ‘ Torí kì í fọ̀wọ̀ mi wọ̀ mí , èmi náà ò ní máa bọ̀wọ̀ fún un . ’ Ó sọ pé : “ Mo rí i pé ìwà tí mò ń hù kù díẹ̀ káàtó , inú mi ò sì dùn . Mo wá pinnu pé á dáa kí n yíwà mi pa dà . Mo gbàdúrà sí Jèhófà pé kó ràn mí lọ́wọ́ . Lẹ́yìn ìyẹn , mo ra ẹ̀bùn kan lọ fún arábìnrin náà , mo sì fi káàdì ìkíni kan kún un . Nínú káàdì yẹn , mo bẹ̀ ẹ́ pé kó dárí jì mí . Lẹ́yìn náà , a dì mọ́ra wa , a sì parí ọ̀rọ̀ náà . OWÓ lọ̀pọ̀ èèyàn kà sí pàtàkì jù lóde òní . Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì kí Jèhófà yanjú ẹ̀sùn tí Sátánì fi kàn án ? Báwo lọ̀rọ̀ bí Jèhófà ṣe máa fi hàn pé òun lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣàkóso ti ṣe pàtàkì tó ? Họ́wù , láti ọjọ́ tí àwọn baba ńlá wa ti sùn nínú ikú , ohun gbogbo ń bá a lọ gẹ́gẹ́ bí ó ti rí láti ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ìṣẹ̀dá . ” ( Ka Aísáyà 55 : ​ 10 , 11 . ) ( Ka Jóòbù 1 : ​ 7 - 12 . ) ( Ka Jóòbù 38 : ​ 18 - 21 . ) ( Ka Róòmù 5 : ​ 3 - 5 . ) Ìdí kan ni pé ìfẹ́ ló fi ń ṣàkóso . Ó ń bójú tó wa ju bá a ṣe lè bójú tó ara wa lọ . Báwo làwọn olórí ìdílé àtàwọn alàgbà ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jèhófà ? Sáàmù 147 rọ àwa èèyàn Ọlọ́run léraléra pé ká yin Jèhófà . Kí ló wú onísáàmù náà lórí tó fi ní ká máa yin Jèhófà ? “ Ẹ yan àwọn ọ̀rẹ́ fún ara yín nípasẹ̀ ọrọ̀ àìṣòdodo . ” ​ — LÚÙKÙ 16 : 9 . Kí la lè ṣe tá ò fi ní tara bọ ètò ìṣòwò ayé yìí ? Kí nìdí tó fi jẹ́ pé kò sígbà tá ò ní láwọn tálákà nínú ayé yìí ? Kí la rí kọ́ nínú ìmọ̀ràn tí Jésù gbà wá yìí ? Báwo la ṣe mọ̀ pé ọ̀rọ̀ káràkátà kò sí nínú ohun tí Ọlọ́run ní lọ́kàn fún aráyé ? Sọ àpẹẹrẹ báwọn kan ṣe fi hàn pé àwọn jẹ́ olóòótọ́ nínú bí wọ́n ṣe ń lo ọrọ̀ àìṣòdodo tí wọ́n ní . Mo túbọ̀ ń dárí jini , mo túbọ̀ ń ní sùúrù , mo túbọ̀ mọ béèyàn ṣe ń mú nǹkan mọ́ra , mo sì máa ń gbàmọ̀ràn . ” Báwo ni Ábúráhámù ṣe fi hàn pé òun nígbàgbọ́ nínú Ọlọ́run ? ( b ) Báwo la ṣe lè fi ìmọ̀ràn Pọ́ọ̀lù sílò lónìí ? Lónìí , gbogbo àwa ọmọ ẹ̀yìn Jésù ló ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti fi ìmọ̀ràn Pọ́ọ̀lù yìí sílò , títí kan àwọn tó lé ní mílíọ̀nù kan tó ń ṣe iṣẹ́ ìsìn alákòókò kíkún . Àwọn tó jẹ́ “ ọlọ́rọ̀ nínú àwọn iṣẹ́ àtàtà ” ni Jèhófà máa ń bù kún . Igi , òkúta àtàwọn ohun ìkọ́lé míì tó jẹ́ ojúlówó máa wà lárọ̀ọ́wọ́tó láti kọ́ àwọn ilé tó rẹwà . Tó o bá fẹ́ ṣètọrẹ , lọ sí ìkànnì jw.org / yo kó o sì tẹ ìlujá “ Ṣe Ọrẹ Láti Ti Iṣẹ́ Tá À Ń Ṣe Kárí Ayé Lẹ́yìn ” tó wà nísàlẹ̀ ìkànnì náà . ARÁBÌNRIN kan tó ń jẹ́ Susi sọ pé : “ Ọkàn wa ṣì máa ń gbọgbẹ́ kódà lẹ́yìn nǹkan bí ọdún kan tí ọmọkùnrin wa kú . ” Ní gbogbo ìgbà tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀ , ṣe ni àlàáfíà Ọlọ́run máa ń mú kí ọkàn wa balẹ̀ pẹ̀sẹ̀ . ” ​ — Ka Fílípì 4 : ​ 6 , 7 . Kí ni Jésù ṣe tó fi hàn pé ó bá àwọn ẹbí Lásárù kẹ́dùn ? Bí àpẹẹrẹ , àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí lè tù ẹ́ nínú nígbàkígbà tó o bá ń ṣọ̀fọ̀ : ( Ka 1 Tẹsalóníkà 5 : 11 . ) Kí ló yẹ ká fi sọ́kàn nípa bí ẹ̀dùn ọkàn ṣe máa ń rí lára ẹnì kọ̀ọ̀kan ? Kódà , tí ẹni náà bá tiẹ̀ gbìyànjú láti ṣàlàyé bí nǹkan ṣe rí lára rẹ̀ , kì í fi bẹ́ẹ̀ rọrùn fáwọn èèyàn láti lóye ohun tó ń sọ . Bí wọ́n ṣe ń sunkún yẹn máa ń mú kí n gbà pé mi ò dá nìkan ṣọ̀fọ̀ . ” Junia tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sọ pé : “ Ó máa ń tù mí lára gan - an tí mo bá gba káàdì tàbí lẹ́tà tí ọ̀rọ̀ ìtùnú wà nínú rẹ̀ tàbí táwọn ará bá ní kí n wá sílé àwọn . Àwọn nǹkan yìí máa ń jẹ́ kí n mọ̀ pé àwọn ará nífẹ̀ẹ́ mi , ọ̀rọ̀ mi sì jẹ wọ́n lọ́kàn . ” Arábìnrin Dalene sọ pé : “ Lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan táwọn arábìnrin bá wá kí mi , mo máa ń sọ pé kí wọ́n gbàdúrà fún mi . Níbẹ̀rẹ̀ , wọn kì í mọ ohun tí wọ́n máa sọ , àmọ́ bí wọ́n ṣe ń bá àdúrà náà lọ , ọ̀rọ̀ wọn máa ń sọjú abẹ níkòó , ó sì máa ń jẹ́ àtọkànwá . Ìgbàgbọ́ tí wọ́n ní àti bí wọ́n ṣe fìfẹ́ hàn sí mi máa ń mára tù mí , ó sì máa ń fún mi lókun . ” Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé : “ Alábàákẹ́gbẹ́ tòótọ́ a máa nífẹ̀ẹ́ ẹni ní gbogbo ìgbà , ó sì jẹ́ arákùnrin tí a bí fún ìgbà tí wàhálà bá wà . ” Bí àpẹẹrẹ , arákùnrin kan sọ pé : “ Mo mọ̀ pé tó bá máa di déètì ọjọ́ tá a ṣègbéyàwó , kò sí bí mi ò ṣe ní rántí ìyàwó mi tó kú , ó sì dájú pé ọkàn mi máa gbọgbẹ́ gan - an . Kò rọrùn fún mi lọ́jọ́ yẹn , àmọ́ àwọn ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin ṣètò àpèjẹ ráńpẹ́ kan , wọ́n sì pe àwọn ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́ kí n má bàa dá nìkan wà . ” Arábìnrin Junia sọ pé : “ Ó máa ń ṣèrànwọ́ gan - an táwọn èèyàn bá wà pẹ̀lú wa láwọn àsìkò míì , yàtọ̀ sí àwọn ọjọ́ pàtàkì nìkan . Ká sòótọ́ , kò sóhun tá a ṣe tó lè mú káwọn tó ń ṣọ̀fọ̀ gbàgbé ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wọn pátápátá , bẹ́ẹ̀ sì ni ojú olójú kò lè dà bí ojú ẹni . Ó jẹ́ kí n rí i pé lóòótọ́ ni Jèhófà nífẹ̀ẹ́ mi . ” Kí nìdí tí àwọn ìlérí Jèhófà fi tù wá nínú ? Àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ míì tó ti tu ọ̀pọ̀ nínú ni Sáàmù 20 : ​ 1 , 2 ; 31 : 7 ; 38 : ​ 8 , 9 , 15 ; 55 : 22 ; 121 : ​ 1 , 2 ; Aísáyà 57 : 15 ; 66 : 13 ; Fílípì 4 : 13 ; àti 1 Pétérù 5 : 7 . Tún wo àpilẹ̀kọ náà “ Máa Tu Àwọn Tó Ń Ṣọ̀fọ̀ Nínú bí Jésù Ti Ṣe ” nínú Ilé Ìṣọ́ November 1 , 2010 . “ A ò mọ nǹkan míì tá a lè sọ ju pé a nífẹ̀ẹ́ rẹ . A lè má lóye bí ọ̀rọ̀ náà ṣe rí lára rẹ gan - an , àmọ́ jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà lóye rẹ , kò sì ní fi ẹ́ sílẹ̀ . A fẹ́ kó o mọ̀ pé à ń rántí rẹ nínú àdúrà wa . ” “ Àdúrà wa ni pé kí Jèhófà fún ẹ lókun kó o lè fara dà á . ” “ Ó dájú pé ohun tí Bíbélì sọ máa tù ẹ́ nínú pé Jèhófà ò gbàgbé èèyàn rẹ tó kú , á sì jí i dìde lọ́jọ́ iwájú . ” “ Ọjọ́ ńbọ̀ tá ò ní ṣọ̀fọ̀ mọ́ láé torí pé kò sí èèyàn wa kan tó máa kú mọ́ . Ní báyìí ná , bó tilẹ̀ jẹ́ pé èèyàn rẹ ti kú , gbogbo wa là ń rántí iṣẹ́ rere tó ṣe , a sì ń retí ìgbà tó máa jíǹde nínú Párádísè . ” “ Ó lè ṣòro fún ẹ láti ṣàlàyé , torí pé ọgbẹ́ tí ikú èèyàn ẹni máa ń dá síni lọ́kàn kọjá àfẹnusọ . Nígbà ìpọ́njú ńlá , Jèhófà ni àwọn Kristẹni máa gbẹ́kẹ̀ lé wọn ò ní gbèjà ara wọn Arákùnrin kan ń wàásù fún ọ̀kan lára àwọn òṣìṣẹ́ inú oko ápù tó wà nílùú Grójec ( b ) Àwọn nǹkan wo la máa kọ́ bá a ṣe ń jíròrò Sáàmù 147 ? Tá a bá sì ní ká máa ka iye ìṣùpọ̀ ìràwọ̀ tó wà , wọn ò lóǹkà ! Mi ò fẹ́ kó o banú jẹ́ , ohun tí mo fẹ́ ni pé kó o máa láyọ̀ pé Ẹlẹ́rìí mi ni ọ́ ! ” ( Ka Sáàmù 147 : ​ 8 , 9 . ) Arákùnrin Mutsuo sọ pé : “ Ṣe ló dà bíi pé Jèhófà dúró ti ọ̀kọ̀ọ̀kan wa , tó sì ń tọ́jú wa . 12 , 13 . ( a ) Àwọn nǹkan wo ló yẹ ká yẹra fún tá a bá fẹ́ kí Jèhófà ràn wá lọ́wọ́ ? Bákan náà , Ọlọ́run máa ń “ rẹ àwọn ẹni burúkú wá sí ilẹ̀ . ” Bíbélì sọ pé : “ Jèhófà ní ìdùnnú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ , sí àwọn tí ń dúró de inú rere rẹ̀ onífẹ̀ẹ́ . ” 15 - 17 . ( a ) Báwo ni ìṣòro wa ṣe máa ń rí lára wa nígbà míì , àmọ́ báwo ni Jèhófà ṣe máa ń fi Ọ̀rọ̀ rẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ ? Lónìí , Jèhófà ń tọ́ wa sọ́nà nípasẹ̀ Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ . ( Ka Sáàmù 147 : ​ 19 , 20 . ) Àwọn ìpinnu wo láá jẹ́ kó o láyọ̀ nígbèésí ayé ? Àwọn iṣẹ́ ìsìn míì wo ni ọwọ́ rẹ lè tẹ̀ tó o bá ṣe iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà ? Ó DÁJÚ pé ẹ̀yin ọ̀dọ́ mọ̀ pé kéèyàn tó bẹ̀rẹ̀ ìrìn - àjò kan , ó gbọ́dọ̀ pinnu ibi tó ń lọ . Ìgbésí ayé dà bí ìgbà téèyàn ń rìnrìn - àjò , ìgbà tó o sì wà lọ́dọ̀ọ́ ló yẹ kó o pinnu ibi tó o fẹ́ forí lé . Kí ló mú kó dá ẹ lójú pé Jèhófà fẹ́ kó o ṣèpinnu táá jẹ́ kó o láyọ̀ ? Jèhófà Ẹlẹ́dàá wa jẹ́ “ Ọlọ́run ìfẹ́ ” àti “ Ọlọ́run aláyọ̀ , ” ìdí nìyẹn tó fi dá àwa èèyàn “ ní àwòrán rẹ̀ . ” Wàá láyọ̀ tó o bá fara wé Ọlọ́run wa onífẹ̀ẹ́ . Jésù Kristi fi àpẹẹrẹ pípé lẹ́lẹ̀ fún ẹ̀yin ọ̀dọ́ . Jésù tún máa ń kẹ́kọ̀ọ́ Ìwé Mímọ́ , ó sì tipa bẹ́ẹ̀ sún mọ́ Jèhófà . Bíbélì sọ pé : “ Àwọn ìwéwèé máa ń já sí pàbó níbi tí kò bá ti sí ọ̀rọ̀ ìfinúkonú , ṣùgbọ́n àṣeparí ń bẹ nínú ògìdìgbó àwọn agbani - nímọ̀ràn . ” Àmọ́ o , bíi tàwọn iṣẹ́ míì , wàá nílò ìdálẹ́kọ̀ọ́ kó o tó lè di ọ̀jáfáfá . Nígbà tí mo kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ , mi ò ní ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kankan , àmọ́ láàárín oṣù kan péré tí mo lọ sí ìpínlẹ̀ ìwàásù míì , mo ti ń darí ọ̀pọ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì . Kódà ọ̀kan lára àwọn ìkẹ́kọ̀ọ́ mi ti ń wá sípàdé . Bí àpẹẹrẹ , Jacob tó wá láti Amẹ́ríkà sọ pé : “ Nígbà tí mo wà lọ́mọ ọdún méje , ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ kíláàsì mi ló jẹ́ ọmọ orílẹ̀ - èdè Vietnam . Ó wù mí gan - an pé kí n wàásù fún wọn , torí náà mo pinnu pé màá kọ́ èdè wọn . Nígbà tí mo bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ èdè náà , mo sábà máa ń fi Ilé Ìṣọ́ èdè òyìnbó wé ti èdè Vietnamese . Mo tún láwọn ọ̀rẹ́ ní ìjọ kan tí kò jìnnà sí wa tí wọ́n ń fi èdè Vietnamese ṣèpàdé . Nígbà tí mo pé ọmọ ọdún méjìdínlógún [ 18 ] , mo bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà . Nígbà tó yá , mo lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Bíbélì fún Àwọn Àpọ́n . Ìdálẹ́kọ̀ọ́ yẹn ràn mí lọ́wọ́ gan - an torí pé èmi nìkan ni alàgbà nínú àwùjọ tó ń sọ èdè Vietnamese tí mo wà báyìí . Ẹnu máa ń ya àwọn ọmọ ìbílẹ̀ Vietnam gan - an pé mo gbọ́ èdè wọn . Wọ́n máa ń gbà mí tọwọ́tẹsẹ̀ , ọ̀pọ̀ wọn ló sì gbà kí n máa kọ́ àwọn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì . Kódà , àwọn kan ti ṣèrìbọmi lára wọn . ” ​ — Fi wé Ìṣe 2 : ​ 7 , 8 . Mo máa ń fún àwọn ọ̀dọ́ tó wà níjọ wa níṣìírí , inú mi sì máa ń dùn bí wọ́n ṣe ń tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí . Lẹ́yìn tí mo lọ sí Ilé Ẹ̀kọ́ Bíbélì fún Àwọn Àpọ́n , wọ́n rán mi lọ sí ìpínlẹ̀ ìwàásù míì . Lóòótọ́ kò tíì sí èyíkéyìí lára àwọn tí mò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ tó ṣèrìbọmi , àmọ́ ìkẹ́kọ̀ọ́ àwọn míì ti ṣèrìbọmi . Báwo ni iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà ṣe lè mú kọ́wọ́ rẹ tẹ àwọn iṣẹ́ ìsìn míì ? Arákùnrin kan tó ń jẹ́ Kevin sọ pé : “ Àtikékeré ló ti máa ń wù mí pé kí n fayé mi ṣe iṣẹ́ ìsìn Jèhófà . Nígbà ti mo pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún [ 19 ] , mo bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà . Kí n lè gbọ́ bùkátà ara mi , mo máa ń bá arákùnrin kan tó jẹ́ kọ́lékọ́lé ṣiṣẹ́ fún ọjọ́ mélòó kan lọ́sẹ̀ . Mo kọ́ béèyàn ṣe ń kan òrùlé , wíńdò àti ilẹ̀kùn . Nígbà tó yá , mo dara pọ̀ mọ́ àwọn tó ń ṣèrànwọ́ fáwọn tí àjálù bá , odindi ọdún méjì ni mo sì lò pẹ̀lú wọn , tá à ń tún àwọn Gbọ̀ngàn Ìjọba àti ilé àwọn ará ṣe . Nígbà tí mo gbọ́ nípa iṣẹ́ ìkọ́lé tó ń lọ lórílẹ̀ - èdè South Africa , mo sọ fún ètò Ọlọ́run pé mo fẹ́ dara pọ̀ , wọ́n sì gbà pé kí n lọ . Tá a bá ti parí Gbọ̀ngàn Ìjọba kan láàárín ọ̀sẹ̀ mélòó kan , àá tún kọjá sí òmíì . A jọ ń jẹ , a jọ ń mu , a jọ ń ṣiṣẹ́ , a sì jọ ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì pọ̀ . Mo tún gbádùn kí n máa bá àwọn ará ṣiṣẹ́ lóde ẹ̀rí lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ . Ohun tí mo yàn látìgbà ọmọdé mi ti mú kí n láyọ̀ gan - an , kódà ayọ̀ náà kọjá sísọ . ” Iṣẹ́ aláyọ̀ ni iṣẹ́ ìsìn Bẹ́tẹ́lì torí pé iṣẹ́ yòówù kó o máa ṣe níbẹ̀ , Jèhófà lò ń ṣe é fún . Lẹ́yìn ọdún kan àtààbọ̀ , wọ́n pè mí sí Bẹ́tẹ́lì . Wọ́n kọ́ mi béèyàn ṣe ń lo ẹ̀rọ ìtẹ̀wé , lẹ́yìn náà ni mo tún ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń ṣe ètò orí kọ̀ǹpútà . Mo láyọ̀ gan - an pé mo wà ní Bẹ́tẹ́lì torí pé ohun tá à ń ṣe níbí ń mú káwọn èèyàn sún mọ́ Jèhófà . ” Jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà fẹ́ kí ayé rẹ ládùn kó lóyin . ( Ka 1 Tímótì 6 : ​ 18 , 19 . ) Lẹ́yìn náà , pinnu pé wàá ṣe ohun táá múnú rẹ̀ dùn . Àtìgbà tí Ọlọ́run ti dá àwa èèyàn ni Sátánì ti ń kíyè sí ìwà wa . Ìwọ fúnra rẹ lo máa kẹ́kọ̀ọ́ kó o lè ní ìmọ̀ . ” Wọ́n sì lè sọ pé : “ Wọ́n kàn fẹ́ tì yín sẹ́nu ikú ni ! ” Jésù sọ pé : “ Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn tí ń pa ara àti lẹ́yìn èyí tí wọn kò lè ṣe nǹkan kan jù bẹ́ẹ̀ lọ . ” Má gbọ̀n rìrì tàbí kí o jáyà , nítorí Jèhófà Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí o bá lọ . ” Tẹ́tí sí Jèhófà , kó o sì gbẹ́kẹ̀ lé e nínú gbogbo ohun tó ò ń ṣe . Àpilẹ̀kọ kejì sọ bí Jèhófà ṣe máa ń gbọ̀nà àrà ṣe àwọn nǹkan . Bíi tàwọn àgbẹ̀ , àwa náà ní láti ṣe sùúrù . Kí la rí kọ́ lára wòlíì Míkà ? ( Ka Míkà 7 : ​ 1 - 3 . ) Tá a bá nígbàgbọ́ bíi ti Míkà , ṣe lá máa wù wá láti dúró de Jèhófà . Ìdí nìyẹn tá a fi ń ‘ fara dà á ní kíkún , pẹ̀lú ìpamọ́ra àti ìdùnnú . ’ Ọ̀pọ̀ ọdún ni Ábúráhámù fi dúró kó tó ní àwọn ọmọ - ọmọ , ìyẹn Ísọ̀ àti Jékọ́bù ( Wo ìpínrọ̀ 9 àti 10 ) ( Ka Hébérù 11 : 8 - 12 . ) Ẹ wo bí inú Ábúráhámù ṣe máa dùn tó nígbà tó bá jíǹde sínú Párádísè lórí ilẹ̀ ayé ! Ọlọ́run ní in lọ́kàn fún rere , fún ète ṣíṣe gẹ́gẹ́ bí ti òní yìí , láti pa àwọn ènìyàn púpọ̀ mọ́ láàyè . ” ( b ) Kí ló mú kí Dáfídì lè dúró de Jèhófà ? Ṣe ni èmi yóò máa kọrin sí Jèhófà , nítorí ó ti bá mi lò lọ́nà tí ń mú èrè wá . ” ( Ka 2 Pétérù 3 : 9 . ) Kí láá jẹ́ ká lè ní sùúrù ? Kí la rí kọ́ látinú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù nílùú Fílípì ? ( Ka Ìṣe 16 : 8 - 10 . ) Ó ṣeé ṣe kí èyí mú kí Pọ́ọ̀lù máa ronú pé , kí nìdí tí Jèhófà fi jẹ́ kí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ṣẹlẹ̀ sí mi ? Ṣe lòun àti Sílà bẹ̀rẹ̀ sí í “ gbàdúrà , wọ́n sì ń fi orin yin Ọlọ́run . ” 4 , 5 . ( a ) Ọ̀nà wo ni ọ̀rọ̀ wa lè gbà dà bíi ti Pọ́ọ̀lù ? ( b ) Báwo ni nǹkan ṣe yí pa dà bìrí fún Pọ́ọ̀lù ? Àwọn nǹkan wo la máa jíròrò ? ( Ka 1 Pétérù 5 : ​ 6 , 7 . ) Nígbà míì , Jèhófà lè dáhùn àdúrà wa lọ́nà tó máa yà wá lẹ́nu gan - an . Jèhófà rán áńgẹ́lì kan láti pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn - án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n [ 185,000 ] àwọn ọmọ ogun Senakéríbù ní òru ọjọ́ kan ṣoṣo . ( a ) Kí la rí kọ́ nínú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Jósẹ́fù ? Ó dájú pé ohun tí Jèhófà ṣe kọjá gbogbo ohun tí Jósẹ́fù lérò . Tún ronú nípa Sárà tó jẹ́ ìyá àgbà fún Jósẹ́fù . ( Ka Aísáyà 43 : ​ 10 - 13 . ) A mọ̀ pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ wa , ó sì fẹ́ káyé wa dùn kó sì lóyin . Báwo la ṣe lè bọ́ àwọn ìwà àtijọ́ wa sílẹ̀ ká má sì gbé wọn wọ̀ mọ́ ? Nígbà tó fi máa dọdún 1939 , ẹgbẹ̀rún mẹ́fà [ 6,000 ] àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ló wà ní àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ . ” Ẹ tún mú kí pápá ìṣeré yìí mọ́ tónítóní nígbà tẹ́ ẹ ṣe tán . Àmọ́ ohun tó wú mi lórí jù ni pé ẹ wà níṣọ̀kan bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọ̀ yín yàtọ̀ síra . ” Àmọ́ nígbà tó yá , ó ń ṣe mí bíi pé mi ò já mọ́ nǹkan kan . ” Bí Sakura ṣe ń gbé ìgbésí ayé rẹ̀ nìyẹn títí tó fi pé ọmọ ọdún mẹ́tàlélógún [ 23 ] . Ó le débi pé ṣe ló máa ń ṣe mí bíi pé kí obìnrin tá a jọ ń gbé pọ̀ bíi tọkọtaya tètè kúrò nílé kí n lè wo fíìmù ìṣekúṣe . ” Kí ló mú kí Stephen kápá ìbínú rẹ̀ , tí kì í sì í bú èébú mọ́ ? Ó sọ pé : “ Nǹkan ti yàtọ̀ gan - an nínú ìdílé wa . Ní báyìí , Stephen ti di ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ nínú ìjọ , ìyàwó rẹ̀ sì ti ń ṣe iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà déédéé fún ọ̀pọ̀ ọdún . Lára àwọn ẹsẹ Bíbélì tó ràn mí lọ́wọ́ ni Aísáyà 55 : 7 tó sọ pé : ‘ Kí ènìyàn burúkú fi ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ , ’ àti 1 Kọ́ríńtì 6 : 11 tó sọ nípa àwọn tó fi ìwà àtijọ́ wọn sílẹ̀ pé : ‘ Ohun tí àwọn kan lára yín ti jẹ́ rí nìyẹn . ’ Ọ̀pọ̀ ọdún ni Jèhófà fi mú sùúrù fún mi , tó sì ń fi ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ ràn mí lọ́wọ́ kí n lè gbé àkópọ̀ ìwà tuntun wọ̀ . ” Tá a bá fẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti ẹ̀mí mímọ́ ràn wá lọ́wọ́ , a gbọ́dọ̀ máa múra ìpàdé sílẹ̀ , ká sì máa pésẹ̀ síbẹ̀ déédéé . A ti yí àwọn orúkọ kan nínú àpilẹ̀kọ yìí pa dà . Wo orí 25 nínú ìwé Awọn Ìbéèrè Tí Awọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè ​ — Awọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́ , Apá Kìíní . ( Ka Kólósè 3 : 10 - 14 . ) Pọ́ọ̀lù sọ pé : ‘ Kò sí Gíríìkì tàbí Júù , ìdádọ̀dọ́ tàbí àìdádọ̀dọ́ , ọmọ ilẹ̀ òkèèrè , Síkítíánì , ẹrú tàbí òmìnira . ’ ( a ) Báwo ló ṣe yẹ káwa ìránṣẹ́ Jèhófà máa ṣe sáwọn míì ? ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí . ) ( b ) Kí ló yọrí sí ? Àmọ́ lọ́jọ́ kan , ó lọ sípàdé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà . Á túbọ̀ ṣe kedere sí ẹ pé ìṣọ̀kan wà láàárín wa , wàá sì rí i pé lóòótọ́ ni ìfẹ́ so wá pọ̀ . ” Tá a bá wá ka àwọn ẹsẹ Bíbélì kan fún wọn nínú Bíbélì èdè Potogí , irú bí Ìṣípayá 21 : 3 , 4 tàbí Sáàmù 37 : 10 , 11 , 29 , wọ́n máa ń fara balẹ̀ tẹ́tí sílẹ̀ , kódà wọ́n tiẹ̀ máa ń da omi lójú nígbà míì . ” A dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà tó mú kí àwọn nǹkan yìí ṣeé ṣe . ” ​ — Ka Ìṣe 10 : 34 , 35 . Báwo ni Jésù ṣe fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ tó bá di pé ká níwà tútù , ká sì ní sùúrù ? Ó wá fi kún un pé à ń dẹ́ṣẹ̀ bí a bá ń ṣe ojúsàájú . Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká fìfẹ́ wọ ara wa láṣọ ? Bákan náà , ìfẹ́ máa ń ní ‘ ìpamọ́ra àti inú rere , kì í sì í wú fùkẹ̀ . ’ Pọ́ọ̀lù sọ pé tí òun ò bá ní ìfẹ́ , òun “ kò jámọ́ nǹkan kan . ” Ìfẹ́ náà jẹ́ lọ́nà yìí , kì í ṣe pé àwa ti nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run , bí kò ṣe pé òun nífẹ̀ẹ́ wa , ó sì rán Ọmọ rẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìpẹ̀tù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa . ” Kò séèyàn tó lè fìfẹ́ tó tóyẹn hàn torí Jésù fúnra rẹ̀ sọ pé : “ Kò sí ẹni tí ó ní ìfẹ́ tí ó tóbi ju èyí lọ , pé kí ẹnì kan fi ọkàn rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ . ” Ẹ jẹ́ ká jíròrò bá a ṣe lè ṣe é . Jòhánù sọ pé : “ Ẹ̀yin ọmọ kéékèèké , ẹ jẹ́ kí a nífẹ̀ẹ́ , kì í ṣe ní ọ̀rọ̀ tàbí pẹ̀lú ahọ́n , bí kò ṣe ní ìṣe àti òtítọ́ . ” Àmọ́ , mo bi ara mi pé , ‘ Báwo ni mo ṣe lè fara wé Jésù nínú ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí ? ’ Lẹ́yìn tí mo ronú nípa ohun tí Jésù máa ṣe tó bá jẹ́ òun ni irú ẹ̀ ṣẹlẹ̀ sí , mo pinnu pé màá gbàgbé ọ̀rọ̀ náà , mi ò sì ní jẹ́ kó di wàhálà . Ìgbà tó yá ni mo wá mọ̀ pé ẹni tá a jọ ń ṣiṣẹ́ yìí ń ṣàìsàn , nǹkan ò sì dẹrùn fún un . Mo wá gbà pé kì í ṣe ohun tó ní lọ́kàn ló kọ nípa mi . Bí mo ṣe ń ronú nípa ohun tí Jésù ṣe nígbà tí wọ́n hùwà àìdáa sí i ló jẹ́ kí èmi náà fìfẹ́ hàn sẹ́ni yẹn . ” Bó ṣe kúrò ní ọ̀run , ṣe ló “ sọ ara rẹ̀ di òfìfo , ” ó sì gbà kí wọ́n pa òun . ÀLÀÁFÍÀ : Bá a ṣe ń ‘ fara dà á fún ara wa lẹ́nì kìíní - kejì nínú ìfẹ́ , ’ à ń gbádùn “ ìdè asonipọ̀ṣọ̀kan ti àlàáfíà . ” Ẹ ò rí i pé ohun àrà ọ̀tọ̀ gbáà ló jẹ́ pé àwa èèyàn Jèhófà wà níṣọ̀kan nínú ayé tó ti pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ yìí ! Pọ́ọ̀lù sọ pé : “ Ìfẹ́ a máa gbéni ró . ” Lọ́jọ́ kejì , èrò pọ̀ débi pé gbọ̀ngàn tí wọ́n lò kò gba àwọn tó wá . ’ Ìjọ kan kọ̀wé pé , “ Nǹkan gidi kan ṣoṣo tó wà lágbègbè yìí ni wáyà ìbánisọ̀rọ̀ kan . ” Lọ́dún 2016 àwọn 2,262,646 ló wá sí Ìrántí Ikú Kristi ní Mẹ́síkò . Ó sọ nípa ohun tí Jósẹ́fù pinnu láti ṣe nígbà tó gbọ́ pé Màríà lóyún . 1 , 2 . ( a ) Kí ló ń ṣẹlẹ̀ torí pé àwọn èèyàn ò ní ìkóra - ẹni - níjàánu ? Kí lo lè ṣe tó ò fi ní kó sínú ìdẹwò ? Kí ló ṣẹlẹ̀ sí arákùnrin kan , kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé káwa náà máa fara balẹ̀ nírú àwọn ipò bẹ́ẹ̀ ? Báwo làwọn òbí ṣe lè mú káwọn ọmọ wọn ní ìkóra - ẹni - níjàánu ? Báwo lo ṣe lè ran àwọn ọmọ rẹ lọ́wọ́ káwọn náà lè ní ìkóra - ẹni - níjàánu ? ( Ka Ẹ́kísódù 34 : 5 - 7 . ) ( a ) Kí nìdí tí Jèhófà fi rán àwọn áńgẹ́lì lọ sílùú Sódómù ? ( Ka Ẹ́kísódù 22 : 26 , 27 . ) Bíbélì sọ pé : “ Jèhófà Ọlọ́run àwọn baba ńlá wọ́n sì ń ránṣẹ́ lòdì sí wọn ṣáá nípasẹ̀ àwọn ońṣẹ́ rẹ̀ , ó ń ránṣẹ́ léraléra , nítorí pé ó ní ìyọ́nú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ àti sí ibùgbé rẹ̀ . ” Bíbélì sọ pé : ‘ Ó bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn ní ohun púpọ̀ . ’ Iṣẹ́ tiwa ni pé ká ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ nísinsìnyí láti mọ Jèhófà . Ọ̀nà kan tá a lè gbà fàánú hàn ni pé ká máa bá àwọn èèyàn kẹ́dùn . “ Jẹ́ onígboyà àti alágbára kí o sì gbé ìgbésẹ̀ . Báwo làwọn òbí àtàwọn ọmọ ṣe lè lo ìgboyà ? 1 , 2 . ( a ) Iṣẹ́ ńlá wo ni Jèhófà gbé fún Sólómọ́nì ? Ohun kan ni pé , bí Sólómọ́nì bá máa ṣe iṣẹ́ náà yanjú , ó ṣe pàtàkì pé kó nígboyà , kó sì gbé ìgbésẹ̀ . Kí ló mú kí Sólómọ́nì dẹni tó nígboyà ? ( Ka 1 Kíróníkà 28 : 20 . ) Báwo ni ìgboyà tí Jésù ní ṣe ran àwọn àpọ́sítélì lọ́wọ́ ? Ní báyìí , ẹ jẹ́ ká jíròrò méjì lára àwọn ibi tá a ti nílò ìgboyà : ( 1 ) nínú ìdílé àti ( 2 ) nínú ìjọ . ( b ) Báwo làwọn ọ̀dọ́ ṣe lè fara wé Mósè ? Jèhófà máa ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè pèsè ohun tí ìdílé wọn nílò . Ó sọ pé : “ Mo máa ń tijú gan - an nígbà tí mo wà ní kékeré . Mi ò kì í lè bá àwọn tá a jọ ń ṣèpàdé ní Gbọ̀ngàn Ìjọba sọ̀rọ̀ , ká má tíì sọ pé kí n bá ẹni tí mi ò mọ̀ rí sọ̀rọ̀ lóde ẹ̀rí . ” Àmọ́ àwọn ará nínú ìjọ àtàwọn òbí rẹ̀ ràn án lọ́wọ́ débi pé ọwọ́ rẹ̀ tẹ ohun tó pinnu láti ṣe , ìyẹn láti di aṣáájú - ọ̀nà déédéé . Báwo ni Sáàmù 37 : 25 àti Hébérù 13 : 5 ṣe lè ran àwọn òbí lọ́wọ́ ? ( Ka Sáàmù 37 : 25 ; Hébérù 13 : 5 . ) Arákùnrin kan tó ní ọmọ méjì sọ pé : “ Àwọn òbí kan máa ń náwó nára káwọn ọmọ wọn lè mókè lẹ́nu ẹ̀kọ́ wọn , nínú eré ìnàjú àti nínú eré ìdárayá . Ohun tó bọ́gbọ́n mu jù ni pé kí àwọn òbí náwó nára kí àwọn ọmọ wọn lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà . Gbogbo ìgbà tá a bá ń rí àwọn ọmọ wa ni inú wa máa ń dùn , torí pé ìjọsìn Jèhófà ló gbawájú láyé wọn , a sì máa ń fún wọn níṣìírí nígbà gbogbo . ” Sọ bí àwọn tó wà nínú ìjọ ṣe lè lo ìgboyà . ( a ) Báwo làwọn arákùnrin tó ti ṣèrìbọmi ṣe lè lo ìgboyà ? ( Ka Fílípì 2 : 13 ; 4 : 13 . ) A rọ gbogbo ẹ̀yin arákùnrin tó ti ṣèrìbọmi pé kẹ́ ẹ jẹ́ onígboyà , kẹ́ ẹ sì múra tán láti ṣiṣẹ́ nínú ìjọ ! Torí náà , “ jẹ́ onígboyà . . . kí o sì gbé ìgbésẹ̀ . ” 1 , 2 . ( a ) Báwo ni ìgbésí ayé ì bá ṣe rí ká ní kò sí Bíbélì ? Nígbà tó yá , àpọ́sítélì Pétérù fa ọ̀rọ̀ inú Aísáyà 40 : 8 yọ . ( Ka 1 Pétérù 1 : 24 , 25 . ) ( Ka Ìṣípayá 14 : 6 . ) Nínú àwọn ẹ̀dà tí wọ́n ṣe jáde lẹ́yìn náà , wọ́n lo “ OLUWA ” láwọn ibi tí orúkọ Ọlọ́run ti fara hàn nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì . Kí nìdí tó fi yẹ ká máa dúpẹ́ pé a ní Bíbélì Ìtumọ̀ Ayé Tuntun ? ( b ) Bíbélì wo ni Bíbélì Septuagint ? ( Ka Sáàmù 119 : 162 - 165 . ) Wo àpilẹ̀kọ náà , “ Ṣó Pọn Dandan Kó O Kọ́ Èdè Hébérù àti Gíríìkì ? ” tó wà nínú Ilé Ìṣọ́ November 1 , 2009 . Ní April 3 , 2017 , a ṣí ibì kan tá a kó onírúurú Bíbélì sí ní oríléeṣẹ́ wa tó wà nílùú Warwick , lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà . Ibi tá a pàtẹ àwọn Bíbélì yìí sí la pè ní “ The Bible and the Divine Name . ” A rọ̀ ẹ́ pé kó o ṣèbẹ̀wò síbi àtẹ yìí àtàwọn àtẹ míì ní oríléeṣẹ́ wa . Jọ̀ọ́ lọ sórí ìkànnì www.jw.org /⁠ yo , kó o lè forúkọ sílẹ̀ pé o fẹ́ wá ṣèbẹ̀wò . Wo abala NÍPA WA > Ọ́FÍÌSÌ ÀTI RÍRÌN YÍ KÁ ỌGBÀ . Ẹsẹ Bíbélì yẹn kà pé : “ Baba àánú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ àti Ọlọ́run ìtùnú gbogbo . . . ń tù wá nínú nínú gbogbo ìpọ́njú wa . ” Ojúṣe wo làwọn arákùnrin tó ń kọ́ni látorí pèpéle ní ? Ǹjẹ́ kò yẹ ká máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà pé ó fún wa ní Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ ? Wo àpótí náà , “ Nǹkan Yí Pa Dà . ” Fara balẹ̀ ṣàlàyé àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó o bá kà , ṣàkàwé wọn , kó o sì sọ ẹ̀kọ́ inú wọn “ Nǹkan yí pa dà lẹ́yìn ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún [ 15 ] tí mo ti ṣe ìrìbọmi . Lọ́jọ́ kan tí ẹnì kan ń sọ àsọyé nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba . . . , ẹni yìí tọ́ka sí ìwé Jákọ́bù 1 : ​ 23 , 24 . “ Lọ́jọ́ mélòó kan lẹ́yìn náà , mo ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tó yí ìgbésí ayé mi pa dà . Ìyẹn ìwé Aísáyà 1 : ​ 18 , níbi tí Jèhófà ti sọ pé : ‘ Ẹ wá , nísinsìnyí , ẹ sì jẹ́ kí a mú àwọn ọ̀ràn tọ́ láàárín wa . . . . Bí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín tilẹ̀ rí bí aṣọ rírẹ̀dòdò , a ó sọ wọ́n di funfun gẹ́gẹ́ bí ìrì dídì . ’ Ńṣe ló dà bíi pé Jèhófà ń bá mi sọ̀rọ̀ , pé : ‘ Vicky , ó yá , jẹ́ ká yanjú ọ̀ràn yìí láàárín ara wa . Mo mọ̀ ẹ́ , mo mọ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí o ti dá , mo mọ ohun tó wà lọ́kàn rẹ , mo sì nífẹ̀ẹ́ rẹ . ’ “ Mi ò lè sùn lálẹ́ ọjọ́ yẹn . Síbẹ̀ , ohun tí mò ń sọ fún Ọlọ́run ni pé : ‘ Ìfẹ́ tí o fi hàn kò tó láti ṣàǹfààní fún mi . Ikú ìrúbọ tí Ọmọ rẹ kú kò tó láti bo ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ . ’ Àmọ́ nígbà tí mo ronú lórí ẹ̀bùn ìràpadà yìí , mo wá gbà pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ mi . ” Àwọn àpilẹ̀kọ yìí ṣàlàyé ìran kẹfà , ìkeje àti ìkẹjọ tí Sekaráyà rí . Ẹ jẹ́ kí n kọ́kọ́ sọ ìtàn ara mi fún yín . ÌLÚ Hemsworth lórílẹ̀ - èdè England ni wọ́n bí mi sí lọ́dún 1923 . Inú wa dùn pé àwọn ará ti pọ̀ gan - an lágbègbè yẹn báyìí . Ká tó dé Northern Ireland ni ẹ̀gbọ́n mi àti ìyàwó rẹ̀ tó ń jẹ́ Lottie ti ń ṣiṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà àkànṣe níbẹ̀ . Nígbà tó dọdún 1952 , àwa mẹ́rẹ̀ẹ̀rin lọ sí ìpàdé àgbègbè kan nílùú Belfast . Àmọ́ a wá ilé títí , a ò rílé , torí náà lálẹ́ ọjọ́ yẹn , inú mọ́tò làwa mẹ́rẹ̀ẹ̀rin sùn mọ́jú . Tá a bá lọ wàásù , a máa lọ sáwọn ibi tó jìn tó máìlì mẹ́wàá sí mẹ́ẹ̀ẹ́dógún sí ibi tá a páàkì sí . A gbádùn iṣẹ́ alábòójútó àyíká gan - an . Ọdún 1965 la ṣe àpéjọ àgbáyé àkọ́kọ́ lórílẹ̀ - èdè Ireland , ìlú Dublin la sì ti ṣe é . Àwọn tó pé jọ fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ẹgbẹ̀rún mẹ́rin [ 3,948 ] , àwọn márùndínláàádọ́rin [ 65 ] ló sì ṣèrìbọmi . Arthur ń kí Arákùnrin Nathan Knorr bó ṣe ń dé sí àpéjọ tá a ṣe lọ́dún 1965 Arthur mú Ìwé Ìtàn Bíbélì jáde lédè Gaelic lọ́dún 1983 Nǹkan tún yí pa dà fún wa lọ́dún 2011 nígbà tí ètò Ọlọ́run so ẹ̀ka ọ́fíìsì tó wà nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì àti ti Ireland pa pọ̀ , wọ́n sì ní ká lọ máa ṣiṣẹ́ ní Bẹ́tẹ́lì tó wà nílùú London . Láti bí ọdún mélòó kan sẹ́yìn ni mo ti máa ń ní ìsoríkọ́ àti ẹ̀dùn ọkàn , mo sì máa ń ro àròkàn . Kò sí bí mo ṣe lè gbàgbé ọkọ mi torí pé bí ìgbín bá fà , ìkarahun á tẹ̀ lé e la jọ máa ń ṣe . Àmọ́ nírú àwọn àsìkò yìí , ṣe ni mo túbọ̀ máa ń sún mọ́ Jèhófà . “ Ẹ jẹ́ kí a nífẹ̀ẹ́ , kì í ṣe ní ọ̀rọ̀ tàbí pẹ̀lú ahọ́n , bí kò ṣe ní ìṣe àti òtítọ́ . ” ​ — 1 JÒH . 3 : 18 . Irú ìfẹ́ wo ni “ ìfẹ́ tí kò ní àgàbàgebè ” ? Àwọn ọ̀nà wo ni Jèhófà gbà fìfẹ́ hàn sí wa ? Kí Jèhófà tó dá àwa èèyàn ló ti nífẹ̀ẹ́ wa . Àwọn nǹkan wo la lè ṣe táá fi hàn pé lóòótọ́ la nífẹ̀ẹ́ ? 6 , 7 . ( a ) Irú ìfẹ́ wo ni “ ìfẹ́ tí kò ní àgàbàgebè ” ? ( Ka Mátíù 6 : ​ 1 - 4 . ) Báwo la ṣe lè máa gba àwọn ará lálejò tìfẹ́tìfẹ́ ? ( Ka 1 Jòhánù 3 : 17 . ) ( Ka Róòmù 12 : ​ 17 , 18 . ) Báwo la ṣe lè fi hàn pé lóòótọ́ la ti dárí ji àwọn tó ṣẹ̀ wá ? Kí ni Jésù ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé òun mú idà wá ? Kí láá jẹ́ kó o lè fara dà á táwọn mọ̀lẹ́bí rẹ bá ta kò ẹ́ torí pé ò ń jọ́sìn Jèhófà ? 3 , 4 . ( a ) Kí ni ẹ̀kọ́ Jésù máa ń fà láàárín àwọn èèyàn ? Jésù sọ pé : “ Ẹ má rò pé mo wá láti fi àlàáfíà lélẹ̀ lórí ilẹ̀ ayé ; èmi kò wá láti fi àlàáfíà lélẹ̀ , bí kò ṣe idà . Nítorí mo wá láti fa ìpínyà , láti pín ọkùnrin níyà sí baba rẹ̀ , àti ọmọbìnrin sí ìyá rẹ̀ , àti ọ̀dọ́ aya sí ìyá ọkọ rẹ̀ . Báwo ni òbí tó jẹ́ Ẹlẹ́rìí ṣe lè kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa bọlá fún òbí wọn tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí ? Kàkà bẹ́ẹ̀ , jẹ́ kó yé wọn pé ẹnì kọ̀ọ̀kan ló máa pinnu bóyá òun máa sin Jèhófà tàbí òun ò ní ṣe bẹ́ẹ̀ . Bíbélì gbà wá níyànjú pé kí “ àsọjáde [ wa ] máa fìgbà gbogbo jẹ́ pẹ̀lú oore ọ̀fẹ́ . ” ( Ka 1 Pétérù 3 : ​ 1 , 2 , 16 . ) Kí lo lè ṣe tó bá ń ṣe ẹ́ bíi pé ìwọ lo fà á táwọn mọ̀lẹ́bí rẹ fi ń gbọ̀rọ̀ rẹ sódì ? Ọ̀kan lára àwọn ibi tá a ti ń wàásù níbi tí èrò pọ̀ sí rèé nílùú Èkó . Báwo ni nǹkan ṣe rí fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì lásìkò yẹn ? ( Ka Sekaráyà 1 : ​ 3 , 4 . ) Ìran kan tó ṣàjèjì ló bẹ̀rẹ̀ orí 5 ìwé Sekaráyà . ( Ka Sekaráyà 5 : ​ 1 , 2 . ) 8 - 10 . ( a ) Kí ló túmọ̀ sí pé kéèyàn búra ? Àwọn nǹkan wo la rí kọ́ nínú ìran kẹfà tí Sekaráyà rí ? ( Ka Sekaráyà 5 : ​ 5 - 8 . ) ( Ka Sekaráyà 5 : ​ 9 - 11 . ) Báwo ni iṣẹ́ ìkọ́lé ńlá tá à ń ṣe lónìí ṣe rí lára rẹ ? ( Ka Sekaráyà 6 : ​ 1 - 3 . ) Jèhófà ṣì ń lo àwọn áńgẹ́lì láti fún àwa èèyàn rẹ̀ lókun kí wọ́n sì dáàbò bò wá 7 , 8 . ( a ) Kí làwọn òkè méjèèjì náà ṣàpẹẹrẹ ? ( b ) Kí nìdí táwọn òkè náà fi jẹ́ bàbà ? Àwọn wo ló ń gun àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin náà , iṣẹ́ wo sì ni Jèhófà fún wọn ? ( Ka Sekaráyà 6 : ​ 5 - 8 . ) ( Ka Sekaráyà 6 : ​ 9 - 12 . ) Nígbẹ̀yìn - gbẹ́yín , ìjọsìn tòótọ́ á wá gbilẹ̀ ! Jèhófà kò ní gbàgbé ìfẹ́ tá a ní fún un láé ! ÌLÚ kékeré kan ní Gujarat , lórílẹ̀ - èdè Íńdíà ni John , àwọn òbí rẹ̀ , ẹ̀gbọ́n rẹ̀ àtàwọn àbúrò rẹ̀ mẹ́rin ń gbé . Nígbà tó gba lẹ́tà náà lọ́wọ́ John , ó kíyè sí i pé John ṣèṣe lọ́wọ́ , ó wá sọ fún un pé òun máa bá a tọ́jú egbò náà . Ló bá gba ọ̀dọ̀ àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì wọn lọ , ó sì bi í láwọn ìbéèrè méjì kan náà . Ó yá , sọ fún mi , ibo ni Bíbélì ti sọ pé Jésù kì í ṣe Ọlọ́run . Ibo ni Bíbélì ti sọ pé kò yẹ ká jọ́sìn Màríà ? A lè rí ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ kọ́ nínú ètò tí Jèhófà ṣe pé káwọn tó ṣèèṣì pààyàn nílẹ̀ Ísírẹ́lì àtijọ́ sá lọ sí ìlú ààbò . Báwo ni orin ti ṣe pàtàkì tó nínú ìjọsìn tòótọ́ ? ( b ) Báwo ló ṣe yẹ ká máa kọrin nípàdé , àwọn wo ló sì yẹ kó múpò iwájú ? Ka ọ̀rọ̀ orin náà jáde sókè , má ṣe jẹ́ kí ohùn rẹ gbọ̀n , kó o sì jẹ́ kó rinlẹ̀ . ( a ) Báwo ni líla ẹnu dáadáa ṣe máa jẹ́ ká lè kọrin ? ( a ) Ìfilọ̀ wo ni wọ́n ṣe níbi ìpàdé ọdọọdún tó wáyé lọ́dún 2016 ? Ẹ máa kọ àwọn orin wa nígbà Ìjọsìn Ìdílé yín ( Wo ìpínrọ̀ 18 ) ( Ka Númérì 35 : ​ 24 , 25 . ) Lẹ́yìn tí wọ́n ràn án lọ́wọ́ , ó sọ pé : “ Kí n sòótọ́ , ẹ̀rù kọ́kọ́ bà mí láti sọ fáwọn alàgbà . Tí Jèhófà bá ti dárí jini , ó ti tán nìyẹn . Bí Jèhófà ṣe sọ , ṣe ló máa ń mú ẹ̀dùn ọkàn wa jìnnà réré sí wa . A ò sì ní rí wọn mọ́ láé . ” Ṣé wàá sá di Jèhófà , kí nìdí ? Báwo la ṣe lè fàánú hàn bíi ti Jèhófà táwọn èèyàn bá ṣẹ̀ wá ? 1 , 2 . ( a ) Ọwọ́ wo ni Jésù fi mú Òfin Ọlọ́run ? ( b ) Kí nìyẹn kọ́ wa nípa Jèhófà ? ( Ka Ìṣe 20 : ​ 26 , 27 . ) ( Ka Númérì 35 : ​ 20 - 24 . ) Ẹ lọ , nígbà náà , kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ ohun tí èyí túmọ̀ sí , ‘ Àánú ni èmi fẹ́ , kì í sì í ṣe ẹbọ . ’ Nítorí èmi kò wá láti pe àwọn olódodo , bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ . ” Kí lo rí kọ́ nínú ìjíròrò wa nípa àwọn ìlú ààbò ? Two Christian sisters share the Bible’s message with a merchant in the town of Tipitapa Díẹ̀ lára àwọn ọ̀nà tó o lè gbà ṣètọrẹ rèé . Owó Ìbánigbófò àti Owó Ìfẹ̀yìntì : O lè kọ orúkọ àjọ kan tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń lò gẹ́gẹ́ bí ẹni tí yóò gba owó ìbánigbófò ẹ̀mí tàbí owó ìfẹ̀yìntì rẹ lẹ́nu iṣẹ́ àti irú owó míì bẹ́ẹ̀ . Ìmọ̀ràn wo ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fún wa nípa èrò ayé ? Èrò wo làwọn èèyàn ní , kí la lè ṣe tá ò fi ní ronú bíi tiwọn ? Ẹ máa ṣọ́ra : bóyá ẹnì kan lè wà tí yóò gbé yín lọ gẹ́gẹ́ bí ẹran ọdẹ rẹ̀ nípasẹ̀ ìmọ̀ ọgbọ́n orí àti ẹ̀tàn òfìfo ní ìbámu pẹ̀lú òfin àtọwọ́dọ́wọ́ ènìyàn , ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ohun àkọ́bẹ̀rẹ̀ ayé , tí kò sì sí ní ìbámu pẹ̀lú Kristi . ” “ Kò pọn dandan kí n gba Ọlọ́run gbọ́ kí n tó lè jẹ́ èèyàn dáadáa . ” “ Èèyàn lè láyọ̀ láìṣe ẹ̀sìn kankan . ” Torí pé Jèhófà ló dá wa , ó lẹ́tọ̀ọ́ láti fún wa lófin . Jésù sọ pé : “ Kò sí ẹnì kan tí ó lè sìnrú fún ọ̀gá méjì ; nítorí yálà òun yóò kórìíra ọ̀kan , kí ó sì nífẹ̀ẹ́ èkejì , tàbí òun yóò fà mọ́ ọ̀kan , kí ó sì tẹ́ńbẹ́lú èkejì . ( Ka 1 Tẹsalóníkà 2 : ​ 13 , 19 , 20 . ) “ Àwa èèyàn lè dá yanjú ìṣòro ayé . ” Kí ló yẹ kí ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú ìdílé ṣe kí wọ́n lè rí èrè ọjọ́ iwájú gbà ? ( b ) Kí láá mú ká pọkàn pọ̀ sórí èrè ọjọ́ iwájú ? Kí ló yẹ ká ṣe tá a bá bára wa láwọn ipò tó léwu ? ( Ka Oníwàásù 7 : ​ 21 , 22 . ) 10 , 11 . ( a ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká maá jowú ? Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé : “ Ìfẹ́ a máa ní ìpamọ́ra àti inú rere . Ṣé àwa náà lè máa fìfẹ́ àti inú rere hàn bíi ti Jónátánì ? Ẹ̀yin ọkọ , ẹ máa bá a nìṣó ní nínífẹ̀ẹ́ àwọn aya yín , ẹ má sì bínú sí wọn lọ́nà kíkorò . Ẹ̀yin ọmọ , ẹ jẹ́ onígbọràn sí àwọn òbí yín nínú ohun gbogbo , nítorí èyí dára gidigidi nínú Olúwa . Kí ló yẹ kí ọkọ kan ṣe tí ìyàwó rẹ̀ tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí kò bá bọ̀wọ̀ fún un ? Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé : “ Ẹnikẹ́ni tí ó bá fawọ́ àwọn àsọjáde rẹ̀ sẹ́yìn kún fún ìmọ̀ , ènìyàn tí ó ní ìfòyemọ̀ sì tutù ní ẹ̀mí . ” Àwọn àpilẹ̀kọ yìí máa jẹ́ kó túbọ̀ dá ẹ lójú pé àjíǹde máa wáyé lóòótọ́ . 11 : 11 . Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ inú Bíbélì wo ló mú kó dá Màtá lójú pé àwọn òkú máa jíǹde ? Bíi ti Màtá , ìṣẹ̀lẹ̀ tó ń mọ́kàn ẹni yọ̀ wo lò ń fojú sọ́nà fún ? Kàkà bẹ́ẹ̀ , ohun tó sọ ni pé : “ Mo mọ̀ pé yóò dìde . ” Nígbà tó yá , ọmọ obìnrin náà ṣàìsàn , ó sì kú . Ọlọ́run gbọ́ àdúrà Èlíjà , ẹ̀mí ọmọ náà sì pa dà sínú rẹ̀ . ( Ka 1 Àwọn Ọba 17 : ​ 17 - 24 . ) ( Ka 2 Àwọn Ọba 4 : ​ 32 - 37 . ) Kí ni Pétérù ṣe fún Dọ́káàsì nígbà tó kú ? Ìgbà kan wà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ń ṣèpàdé pẹ̀lú àwọn ará nínú yàrá òkè kan nílùú Tíróásì , tó jẹ́ apá kan orílẹ̀ - èdè Tọ́kì báyìí . Ọmọkùnrin kan tó ń jẹ́ Yútíkọ́sì jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ wíńdò , ó ń gbọ́ ohun tí Pọ́ọ̀lù ń sọ . Ìyẹn nìkan kọ́ o , Jèhófà tún sọ pé irú - ọmọ náà máa wá “ nípasẹ̀ Ísákì . ” Àmọ́ , ìyẹn ò túmọ̀ sí pé Ọlọ́run ò lè jí ẹni tó kú dìde o . ( Ka Jóòbù 14 : ​ 13 - 15 . ) ( b ) Kí nìdí tí àjíǹde fi ṣe pàtàkì ? Àmọ́ , ṣé wàá mẹ́nu kan ìrètí àjíǹde gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára ohun tó o gbà gbọ́ , tó o sì ń fojú sọ́nà fún ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 15 : ​ 12 - 19 . ) Àmọ́ , ó dá wa lójú pé Jésù ti jíǹde . Báwo ni ọ̀rọ̀ inú Sáàmù 118 ṣe kan Jésù ? “ Àwọn akọ́lé ” kọ Mèsáyà tì ( Wo ìpínrọ̀ 7 ) Ọ̀nà wo ni Jésù gbà di “ olórí igun ilé ” ? Báwo ni Jésù ṣe lè di “ olórí igun ilé ” lẹ́yìn tí wọ́n kọ̀ ọ́ , tí wọ́n sì pa á ? ( a ) Àsọtẹ́lẹ̀ wo ló wà nínú Sáàmù 16 : 10 ? ( Ka Ìṣe 2 : ​ 29 - 32 . ) ( Ka Ìṣe 2 : ​ 33 - 36 . ) ( Ka Ìṣe 13 : ​ 32 - 37 , 42 . ) Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ kan wà nípa “ àwọn ìgbà tàbí àsìkò tí Baba ti fi sí abẹ́ àṣẹ òun fúnra rẹ̀ . ” Pọ́ọ̀lù sọ pé : “ A ti gbé Kristi dìde kúrò nínú òkú , àkọ́so nínú àwọn tí ó ti sùn nínú ikú . ” Kí ló máa ṣẹlẹ̀ sáwọn ẹni àmì òróró nígbà ìpọ́njú ńlá ? Nítorí bí ó bá jẹ́ pé ìgbàgbọ́ wa ni pé Jésù kú , ó sì tún dìde , bẹ́ẹ̀ , pẹ̀lú , àwọn tí ó ti sùn nínú ikú nípasẹ̀ Jésù . . . Àwa alààyè tí a kù nílẹ̀ di ìgbà wíwàníhìn - ín Olúwa kì yóò ṣáájú àwọn tí ó ti sùn nínú ikú lọ́nàkọnà ; nítorí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò sọ̀ kalẹ̀ láti ọ̀run wá pẹ̀lú ìpè àṣẹ , . . . àwọn tí ó kú ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Kristi ni yóò sì kọ́kọ́ dìde . Àwọn ẹni àmì òróró tó wà láàyè nígbà ìpọ́njú ńlá ni “ a ó gbà lọ dájúdájú nínú àwọsánmà . ” Abúlé kan nílùú Bulacan , lórílẹ̀ - èdè Philippines ni wọ́n bí mi sí ní July 29 , 1929 , ibẹ̀ náà sì ni mo dàgbà sí . Mo gbádùn kí n máa ka Bíbélì , pàápàá àwọn ìwé Ìhìn Rere mẹ́rẹ̀ẹ̀rin . Bó ṣe di pé èmi náà fẹ́ máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù nìyẹn . ​ — Jòh . 10 : 27 . Àsìkò yẹn sì làwọn òbí mi ní kí n máa pa dà bọ̀ nílé . Arákùnrin àgbàlagbà kan ló wá wàásù nílé wa , ó sì ṣàlàyé ohun tí Bíbélì sọ nípa “ àwọn ọjọ́ ìkẹyìn . ” Arákùnrin náà ní ká wá síbi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kan tí wọ́n fẹ́ ṣe lábúlé kan tí ò jìnnà sí wa . Lẹ́yìn ìgbà bíi mélòó kan tí mo lọ sípàdé , wọ́n ní kí n sùn sọ́dọ̀ àwọn , ọ̀rọ̀ Bíbélì la sì jọ sọ mọ́jú . Mo dáhùn pé , “ Bẹ́ẹ̀ ni , mo fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀ . ” Ó dá mi lójú pé mo ti ṣe tán láti “ sìnrú fún Ọ̀gá náà , Kristi . ” Torí náà ní February 15 , 1946 , méjì lára wa ṣèrìbọmi nínú odò kan tó wà nítòsí . Ìdílé Cruz sọ pé kí n wá máa gbé lọ́dọ̀ àwọn nílùú Angat . Èdè Gẹ̀ẹ́sì ló fi sọ àsọyé náà , mo wá ṣe àkópọ̀ rẹ̀ lédè Tagalog . Àwọn arákùnrin méjìlá tí kò tíì gbéyàwó ló ń sìn níbẹ̀ . Lẹ́yìn tí mo kẹ́kọ̀ọ́ yege níbẹ̀ , wọ́n ní kí n lọ ṣiṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà àkànṣe fúngbà díẹ̀ ní Bronx , nílùú New York City . Lẹ́yìn tá a ṣègbéyàwó , ìjọ kan tó wà ní erékùṣù Rapu Rapu Island la kọ́kọ́ bẹ̀ wò . Kódà , ọkùnrin tó ní “ Àwa èèyàn Ṣáínà kì í ta ilé wa ” náà ta ilé rẹ̀ fún wa . Bí ìyẹn bá sì ti ṣẹlẹ̀ , ó ṣeé ṣe kí ọlẹ̀ náà bẹ̀rẹ̀ sí í dàgbà nínú okùn ilé ọmọ , táwọn olóyìnbó ń pè ní Fallopian tube . Ká sòótọ́ , irú nǹkan bẹ́ẹ̀ kì í sábà ṣẹlẹ̀ , àmọ́ ó lè ṣẹlẹ̀ . Ìwé kan tí àjọ National Health Service lórílẹ̀ - èdè England gbé jáde sọ pé : “ IUD oníkọ́pà gbẹ́ṣẹ́ gan - an , tipátipá la fi ń rí àwọn tí kò ṣiṣẹ́ fún . Ohun tí èyí túmọ̀ sí ni pé nínú ọgọ́rùn - ún [ 100 ] obìnrin tó ń lo IUD , tipátipá ni wọ́n fi máa ń rí obìnrin kan tó lóyún láàárín ọdún kan . Bí kọ́pà inú IUD náà bá ṣe pọ̀ tó , bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe máa gbéṣẹ́ tó . ” ( a ) Kí ló túmọ̀ sí pé a yí ẹnì kan lérò pa dà “ láti gbà gbọ́ ” ? ( b ) Báwo la ṣe mọ̀ pé wọ́n yí Tímótì lérò pa dà láti gba ìhìn rere nípa Jésù gbọ́ ? Kí n sòótọ́ , ọkàn mi kì í balẹ̀ tó bá sọ pé òun ò ní ìbéèrè kankan nípa ohun tá a kọ́ ọ . ” Ǹjẹ́ àlàyé tí Bíbélì ṣe dá àwọn ọmọ rẹ lójú ? Àwọn nǹkan wo ló yẹ kó o jẹ́ káwọn ọmọ rẹ mọ̀ ? Arábìnrin Stephanie , tó ní ọmọbìnrin mẹ́ta sọ pé : “ Àtìgbà táwọn ọmọ mi ti wà ní kékeré ni mo ti máa ń bi ara mi pé , ‘ Ṣé mo máa ń jẹ́ káwọn ọmọ mi mọ ìdí tí mo fi gbà pé Jèhófà wà lóòótọ́ , pé ó nífẹ̀ẹ́ wa àti pé àwọn ìlànà rẹ̀ bọ́gbọ́n mu ? Ṣé mò ń jẹ́ kó ṣe kedere sáwọn ọmọ mi pé mo nífẹ̀ẹ́ Jèhófà lóòótọ́ ? ’ Mi ò lè retí pé kí ẹ̀kọ́ òtítọ́ jinlẹ̀ lọ́kàn wọn tí kò bá jinlẹ̀ lọ́kàn tèmi alára . ” Bíbélì sọ pé : “ Ọkàn - àyà ọmọdékùnrin ni ìwà òmùgọ̀ dì sí . ” Irú ọgbọ́n bẹ́ẹ̀ ṣe pàtàkì tí wọ́n bá máa rí ìgbàlà . Báwo lẹ̀yin òbí ṣe lè mú káwọn ọmọ yín “ di ọlọ́gbọ́n fún ìgbàlà ” ? Wàá rí i lórí Ìkànnì jw.org , lábẹ́ abala BIBLE TEACHINGS > BIBLE STUDY TOOLS . Báwo lo ṣe lè ṣiṣẹ́ ìgbàlà rẹ yọrí ? Inú òtítọ́ ni wọ́n ti tọ́ àwọn kan lára wọn dàgbà . Àmọ́ bó ṣe ń dàgbà sí i , tí ìmọ̀lára rẹ̀ láti ní ìbálòpọ̀ sì ń lágbára sí i , ó gbọ́dọ̀ jẹ́ kó dá òun lójú pé pípa òfin Jèhófà mọ́ lohun tó bọ́gbọ́n mu jù . ” ( b ) Kí lo rí kọ́ nínú Fílípì 4 : ​ 11 - 13 ? Kí ló túmọ̀ sí pé kó o ṣiṣẹ́ ìgbàlà rẹ yọrí “ pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì ” ? Àwọn nǹkan wo ló ti mú kí ìdákẹ́kọ̀ọ́ rẹ túbọ̀ nítumọ̀ ? Nígbà míì mo lè sọ pé , ‘ Lọ́jọ́ kan tí mò ń kọ́ ẹnì kan ní Bíbélì , ó ṣẹlẹ̀ pé . . . ’ Lẹ́yìn tí mo bá ti sọ̀yẹn , màá wá máa bá ọ̀rọ̀ mi lọ . Àwa náà la lè jẹ́ kí wọ́n mọ ẹni táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà jẹ́ gan - an . Torí náà , ohun tá a bá ṣe ló máa pinnu bóyá wọ́n á gbọ́ tàbí wọn ò ní gbọ́ . Tá a bá ń tijú àtisọ ohun tá a gbà gbọ́ fún wọn , tí ẹ̀rù ń bà wá tàbí tí ohùn wa ń gbọ̀n nígbà tá à ń bá wọn sọ̀rọ̀ , ojú wo ni wọ́n fi máa wò wá ? Ṣé wọn ò ní sọ pé ohun tá à ń sọ kò dá wa lójú ? Wọ́n tiẹ̀ lè má fẹ́ gbọ́ wa . Àmọ́ , tá a bá fìgboyà sọ̀rọ̀ , tí ara wa sì balẹ̀ nígbà tá à ń ṣàlàyé ohun tá a gbà gbọ́ , ó ṣeé ṣe kí wọ́n máa fara balẹ̀ tẹ́tí sáwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà . ” Jésù sọ pé : “ Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ tọ̀ mí lẹ́yìn , kí ó sẹ́ níní ara rẹ̀ , kí ó sì gbé òpó igi oró rẹ̀ , kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn nígbà gbogbo . ” Kí la rí kọ́ nínú Aísáyà 40 : 26 ? Kò sẹ́ni tó tíì lè ka gbogbo ìràwọ̀ tó wà lójú ọ̀run . Kí ló mú kó dá wa lójú pé Jèhófà lè fún wa lókun tá a nílò ? Ó tún fi kún un pé : “ Ẹ ó sì rí ìtura fún ọkàn yín . Àmọ́ nígbà tá a bá pa dà dé , báwo lara wa ṣe máa ń rí ? Ọ̀rọ̀ náà wọ̀ mí lọ́kàn gan - an , kódà mi ò mọ ìgbà tí mo bẹ̀rẹ̀ sí í da omi lójú . Àsọyé yẹn tún jẹ́ kí n rí i pé ó ṣe pàtàkì kí n máa wá sípàdé tí mo bá máa rókun gbà . ” Kí ni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ní lọ́kàn nígbà tó sọ pé : “ Nígbà tí èmi bá jẹ́ aláìlera , nígbà náà ni mo di alágbára ” ? Ó kọ ọ́ lórin pé : “ Nítorí nípasẹ̀ rẹ , mo lè sáré ní ìgbéjàko ẹgbẹ́ onísùnmọ̀mí ; àti pé nípasẹ̀ Ọlọ́run mi , mo lè gun ògiri . ” Ǹjẹ́ kò ní dáa ká tẹ̀lé ìmọ̀ràn Bíbélì pé ká tètè yanjú ọ̀rọ̀ náà ? O lè bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ báyìí , “ Ó jọ pé mo jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yẹn ká mi lára ju bó ṣe yẹ lọ , àmọ́ ọ̀rọ̀ tó o sọ lánàá mú kí n . . . Nítorí pé tọ̀sán - tòru ni ọwọ́ rẹ wúwo lára mi . ” Ó sọ pé : “ Ẹ̀ṣẹ̀ mi ni mo jẹ́wọ́ fún ọ nígbẹ̀yìn - gbẹ́yín , . . . ìwọ fúnra rẹ sì dárí ìṣìnà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi jì . ” ( 4 ) Ṣé ọjọ́ kan ń bọ̀ tá a máa ṣe Ìrántí Ikú Kristi tó kẹ́yìn ? ( Ka Jòhánù 3 : 16 ; 17 : 3 . ) ( a ) Lálẹ́ ọjọ́ tí Jésù fi Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa lọ́lẹ̀ , kí ló gbàdúrà fún ? ( b ) Báwo la ṣe mọ̀ pé Jèhófà dáhùn àdúrà yẹn ? ( Ka Jòhánù 17 : ​ 20 , 21 . ) ( Ka Ìsíkíẹ́lì 37 : ​ 15 - 17 . ) Báwo la ṣe lè pa kún ìṣọ̀kan tó wà láàárín àwa èèyàn Ọlọ́run ? Báwo la ṣe lè máa ‘ fara dà á fún ara wa lẹ́nì kìíní - kejì nínú ìfẹ́ ’ ? Báwo la ṣe mọ̀ pé ọjọ́ kan ń bọ̀ tá a máa ṣe Ìrántí Ikú Kristi tó kẹ́yìn ? Nílùú Riberalta ní ìpínlẹ̀ Beni , àwọn tọkọtaya aṣáájú - ọ̀nà méjì ń kó àwọn ìtẹ̀jáde wa sínú ọkọ̀ òfuurufú . Kí nìdí tí Jèhófà fi fẹ́ ká fi àwọn ohun ìní wa ta òun lọ́rẹ ? Báwo ni ètò Ọlọ́run ṣe ń lo owó tá a fi ń ṣètọrẹ lónìí ? Kí nìdí tá a fi ń fún Jèhófà ní nǹkan ? ( Ka 2 Kọ́ríńtì 8 : ​ 18 - 21 . ) Àwọn ọrẹ tá à ń ṣe la fi ń ṣe àwọn iṣẹ́ tá à ń ṣe kárí ayé ( Wo ìpínrọ̀ 14 sí 16 ) Àmọ́ , tá a bá ti wo Ètò Tẹlifíṣọ̀n JW , a máa ń rántí pé ara ẹgbẹ́ ará kárí ayé ni wá . Inú àwọn ará tó wà níbí máa ń dùn gan - an láti wo Ètò Tẹlifíṣọ̀n JW . Tí wọ́n bá ti wò ó tán , wọ́n sábà máa ń sọ pé ṣe làwọn túbọ̀ ń sún mọ́ Ìgbìmọ̀ Olùdarí . Inú wọn máa ń dùn gan - an pé àwọn wà nínú ètò tí Ọlọ́run ń darí . ” ( Ka Òwe 11 : ​ 24 , 25 . ) Ẹni tí ó bá nífẹ̀ẹ́ aya rẹ̀ nífẹ̀ẹ́ ara rẹ̀ , nítorí pé kò sí ènìyàn kankan tí ó jẹ́ kórìíra ara òun fúnra rẹ̀ ; ṣùgbọ́n a máa bọ́ ọ , a sì máa ṣìkẹ́ rẹ̀ . ” Kí la lè ṣe tá ò fi ní jẹ́ olùfẹ́ ara wa nìkan ? Pọ́ọ̀lù sọ pé àwọn èèyàn máa jẹ́ “ olùfẹ́ owó . ” Ní ọdún mélòó kan sẹ́yìn , aṣáájú - ọ̀nà kan bá ọkùnrin kan sọ̀rọ̀ Ọlọ́run . Kí ni Ágúrì sọ nípa ipò òṣì àti ọrọ̀ ? Ó ní : “ Kí n má bàa yó tán kí n sì sẹ́ ọ ní ti tòótọ́ , kí n sì wí pé : ‘ Ta ni Jèhófà ? ’ Ó máa ń sọ fún mi pé , ‘ Ọ̀gá tó dáa jù lọ ni mò ń bá ṣiṣẹ́ ! ’ Ní báyìí témi náà ti di aṣáájú - ọ̀nà , a ti jọ wà lábẹ́ Ọ̀gá kan náà , ìyẹn Jèhófà . ” Kí la lè ṣe tá ò fi ní jẹ́ olùfẹ́ owó ? Ohun tó ń sọ ni pé wọn ò nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run rárá àti rárá . ” Kí la lè ṣe tá ò fi ní jẹ́ olùfẹ́ adùn ? A tún mọ̀ pé ìfẹ́ “ kì í fọ́nnu , kì í wú fùkẹ̀ . ” Ó la ojú afọ́jú , ó mú àwọn arọ , adẹ́tẹ̀ àti adití lára dá . ( Ka Aísáyà 11 : ​ 6 , 7 . ) O lè ka ìrírí àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ nínú ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ tá a pè ní “ Bíbélì Máa Ń Yí Ìgbésí Ayé Àwọn Èèyàn Pa Dà ” tó wà ní abala Ẹ̀KỌ́ BÍBÉLÌ > ÀLÀÁFÍÀ ÀTI AYỌ̀ lórí ìkànnì jw.org / yo . Ó yẹ ká jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni wá . 3 Jẹ́ Onígbọràn Kó O sì Nígbàgbọ́ Bíi Ti Nóà , Dáníẹ́lì àti Jóòbù 28 Ìdùnnú ​ — Ànímọ́ Rere Tí Ọlọ́run Ń Fúnni 9 , 10 . ( a ) Báwo la ṣe lè jẹ́ onígbọràn ká sì tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ Nóà ? ( Ka Málákì 3 : ​ 17 , 18 . ) ( b ) Irú ẹni wo ni Jèhófà ka Dáníẹ́lì sí ? ( b ) Ẹ̀kọ́ wo lẹ̀yin òbí lè rí kọ́ lára àwọn òbí Dáníẹ́lì ? ( Ka Jóòbù 1 : ​ 9 , 10 . ) 19 , 20 . ( a ) Báwo la ṣe lè jẹ́ onígbọràn ká sì tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ Jóòbù ? 1 - 3 . ( a ) Kí ló máa jẹ́ ká jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí ? ( Ka Dáníẹ́lì 6 : ​ 7 - 10 . ) ( Ka Jóòbù 31 : ​ 24 - 28 . ) ( Ka Sáàmù 11 : 5 ; 26 : 4 . ) Wá bi ara rẹ pé , ‘ Ṣé mo mọ Jèhófà dáadáa bíi ti Nóà , Dáníẹ́lì àti Jóòbù ? ’ Jésù sọ pé : “ Ábúráhámù baba yín yọ̀ gidigidi nínú ìfojúsọ́nà fún rírí ọjọ́ mi . ” Àní sẹ́ , ayọ̀ tá a ní kọjá àfẹnusọ . ” Nítorí àwa ni Ọlọ́run ti ṣí wọn payá fún nípasẹ̀ ẹ̀mí rẹ̀ . ” Jésù sọ pé : “ Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín , kí ìdùnnú mi lè wà nínú yín , kí a sì lè sọ ìdùnnú yín di kíkún . ” ( 3 ) Tá a bá sapá láti ní “ èrò inú ti Kristi , ” báwo nìyẹn ṣe máa mú ká jẹ́ ẹni tẹ̀mí ? ( Ka 1 Kọ́ríńtì 2 : ​ 14 - 16 . ) Kí ni Bíbélì sọ nípa àwọn ẹni tẹ̀mí ? Kí la rí kọ́ lára Jékọ́bù ? Kí la rí kọ́ lára Màríà ? ( Ka Lúùkù 1 : ​ 46 - 55 . ) ( Ka Aísáyà 63 : 9 ; Máàkù 6 : 34 . ) Arábìnrin kan lórílẹ̀ - èdè Brazil tó ń jẹ́ Rachel sọ pé : “ Ọ̀pọ̀ ìgbà ni mo máa ń múra bíi tàwọn èèyàn ayé . Kí n sòótọ́ kò rọrùn , àmọ́ bí mo ṣe ń ṣe àwọn àyípadà yẹn , mò ń láyọ̀ , ìgbésí ayé mi sì nítumọ̀ . ” Torí náà , tá a bá fìwà jọ Jésù , ìyẹn á jẹ́ ká túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà . Abájọ tí wọ́n fi sọ pé : “ Àwa sì ni ẹlẹ́rìí gbogbo ohun tí ó ṣe . ” Tá a bá ń ronú bíi ti Kristi , báwo nìyẹn ṣe máa nípa lórí ìgbésí ayé wa ? Ó sọ pé : “ Kì í ṣe pé mo dẹ́ṣẹ̀ kankan , àmọ́ àwọn ohun tí mò ń ṣe nínú ìjọsìn Jèhófà ò dénú mi , mo kàn ṣáà ń ṣe wọ́n ni . Mo máa ń lọ sípàdé déédéé mo sì máa ń ṣe aṣáájú - ọ̀nà olùrànlọ́wọ́ láwọn oṣù mélòó kan lọ́dún , torí náà ṣe ló dà bíi pé ẹni tẹ̀mí ni mí . Robert sọ pé : “ Ṣe ló dà bíi pé mi ò mọ nǹkan kan . Mo sọ fúnra mi pé , ‘ Tí mo bá máa jẹ́ olórí ìdílé tó ń múpò iwájú nínú ìjọsìn Ọlọ́run , àfi kí n wá nǹkan ṣe ní kíá . ’ Ó sọ pé : “ Mo bẹ̀rẹ̀ sí í kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì , mo kẹ́kọ̀ọ́ , mo kẹ́kọ̀ọ́ títí , mi ò sì jẹ́ kó sú mi . Ju gbogbo ẹ̀ lọ , mo bẹ̀rẹ̀ sí í ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà . ” ( 3 ) Tá a bá jẹ́ ẹni tẹ̀mí , báwo nìyẹn ṣe máa ràn wá lọ́wọ́ nígbèésí ayé wa ? ( b ) Kí nìdí tá a fi ń dá kẹ́kọ̀ọ́ tá a sì ń ṣàṣàrò ? ( b ) Àpẹẹrẹ inú Bíbélì wo la lè fara wé ? 12 , 13 . ( a ) Kí ló máa jẹ́ ká fi ohun tó wà nínú Róòmù 15 : 5 sílò ? ( Ka 2 Pétérù 1 : ​ 5 - 8 . ) Tá a bá jẹ́ ẹni tẹ̀mí , báwo nìyẹn ṣe máa nípa lórí ìgbésí ayé wa ? Kí làwọn “ òkú iṣẹ́ ” tó yẹ ká yẹra fún ? Ṣé àwọn ìpinnu tí mò ń ṣe á mú kí n ní àwọn àfojúsùn tẹ̀mí ? Ṣó wù ẹ́ kó o túbọ̀ di ẹni tẹ̀mí ? Ní ọgọ́rùn - ún ọdún kìíní , àpọ́sítélì Pétérù sọ fáwọn Kristẹni pé : “ Ẹ ní ẹ̀mí aájò àlejò fún ara yín lẹ́nì kìíní - kejì . ” Dìde , kí a batisí rẹ . ” ​ — ÌṢE 22 : 16 . Kí ló yẹ káwọn òbí Kristẹni rí i dájú pé àwọn ọmọ wọn mọ̀ kí wọ́n tó ṣèrìbọmi ? Nígbà tó di December 31 , 1934 , mo ṣèrìbọmi . ” 5 , 6 . ( a ) Kí ni Bíbélì sọ nípa Tímótì , kí sì nìyẹn jẹ́ ká mọ̀ nípa ìgbà tó ṣèrìbọmi ? ( Ka Kólósè 1 : ​ 9 , 10 . ) Wọ́n sọ fún Jèhófà pé inú àwọn dùn pé ọmọ àwọn ti ya ara rẹ̀ sí mímọ́ fún un . ” ( Ka 1 Pétérù 3 : ​ 20 , 21 . ) Kí nìdí tí kò fi yẹ ká fipá mú ẹnikẹ́ni láti ṣèrìbọmi ? Tó o bá jẹ́ òbí , ó ṣeé ṣe kó o máa ronú pé : ‘ Ṣé lóòótọ́ lọmọ mi ti ṣe tán láti ṣèrìbọmi ? Ìbéèrè àkọ́kọ́ ni pé , “ Lọ́lá ẹbọ Jésù Kristi , ǹjẹ́ o ti ronú pìwà dà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ , ṣé o sì ti ya ara rẹ sí mímọ́ fún Jèhófà láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ? ” Báwo la ṣe lè fẹ̀mí aájò àlejò hàn nípàdé ? ( Ka 3 Jòhánù 5 - 8 . ) Ó ní : “ Mi ò kọ́kọ́ fẹ́ gbà wọ́n torí pé mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó ni àti pé ilé wa kéré . Àmọ́ inú wa dùn gan - an pé a gbà wọ́n . Èmi àtìyàwó mi rí i pé tí àwọn tọkọtaya bá jọ ń sin Jèhófà , tí wọ́n sì ní àfojúsùn kan náà , wọ́n á láyọ̀ . ” Kí nìdí tó fi yẹ kó o ṣaájò àwọn tó bá ṣẹ̀ṣẹ̀ dé ìjọ yín ? ( Ka Lúùkù 10 : ​ 41 , 42 . ) Nírọ̀lẹ́ ọjọ́ kan , ó tiẹ̀ ṣe ìyàwó mi bíi pé ká pa dà sílé , àmọ́ gbogbo bí mo ṣe gbìyànjú tó láti mára tù ú , pàbó ló já sí . Nígbà tó di nǹkan bí aago méje ààbọ̀ , ẹnì kan kan ilẹ̀kùn . Obìnrin kan tó ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló wá kí wa , ó sì kó ọsàn mẹ́ta dání fún wa . A ní kó wọlé , a sì fún un lómi . Lẹ́yìn náà , a po tíì fún un , a sì fún un ní ṣokoléètì . Ọ̀pọ̀ làyà wọn máa ń já láti gbàlejò , torí náà táyà ẹ bá ń já , fọkàn balẹ̀ . Alàgbà kan nílẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì sọ pé : “ Lóòótọ́ , àyà èèyàn lè máa já tó bá fẹ́ gbàlejò . Àmọ́ bíi tàwọn nǹkan míì tá à ń ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà , ayọ̀ téèyàn máa ń rí tó bá gbàlejò pọ̀ ju ohun tó ń náni lọ . Mo máa ń gbádùn kí n kàn jókòó pẹ̀lú àlejò , ká máa sọ̀rọ̀ , ká sì máa mu kọfí . ” Alàgbà míì sọ pé : “ Tí mo bá gba àwọn míì nínú ìjọ lálejò , ó máa ń jẹ́ kí n túbọ̀ mọ̀ wọ́n ju ti tẹ́lẹ̀ lọ , ó sì máa ń jẹ́ kí n mọ bí wọ́n ṣe kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ . ” Àmọ́ , ìyàwó ọ̀kan lára àwọn olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ náà fi mí lọ́kàn balẹ̀ . Ó sọ fún mi pé ọ̀sẹ̀ táwọn máa ń gbádùn jù lẹ́nu iṣẹ́ arìnrìn - àjò làwọn ọ̀sẹ̀ táwọn lò lọ́dọ̀ àwọn tí ò fi bẹ́ẹ̀ ní lọ́wọ́ àmọ́ tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ Jèhófà , tí wọ́n sì ń gbé ìgbésí ayé ṣe - bó - o - ti - mọ . Èyí mú kí n rántí ohun tí màmá mi máa ń sọ fún wa ní kékeré , wọ́n á ní : ‘ Ó sàn kéèyàn jẹ ewébẹ̀ , níbi tí ìfẹ́ wà . ’ ( Ka Òwe 25 : ​ 21 , 22 . ) Àwọn tó fẹ́ gbàlejò sábà máa ń ṣètò nǹkan sílẹ̀ fún àlejò wọn ( Wo ìpínrọ̀ 20 ) Dáfídì béèrè pé : “ Jèhófà , ta ni yóò jẹ́ àlejò nínú àgọ́ rẹ ? ” Àwọn kan máa ń sọ pé ‘ báyìí là ń ṣe nílẹ̀ wa , èèwọ̀ ibòmíì ni . ’ Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé ká máa fi ‘ ẹ̀mí aájò àlejò hàn sí ara wa lẹ́nì kìíní - kejì ’ ? Àwọn arákùnrin méjì ń wàásù fún kunlékunlé kan tó jókòó sórí afárá tó wà níwájú ilé tí wọ́n ń pè ní Kaštilac , nítòsí ìlú Split , ilé ọ̀hún ti wà láti ọgọ́rùn - ún ọdún kẹrìndínlógún ( Ka Títù 2 : ​ 11 - 14 . ) Alàgbà náà sọ pé : “ Ìgbéraga nìṣòro Graham . Ṣe ló ń ṣàríwísí àwọn alàgbà tó bójú tó ọ̀rọ̀ rẹ̀ nígbà tí wọ́n yọ ọ́ lẹ́gbẹ́ . Torí náà , mo jẹ́ kí àwọn ìkẹ́kọ̀ọ́ mélòó kan tá a ṣe lẹ́yìn yẹn dá lórí àwọn Ìwé Mímọ́ tó sọ̀rọ̀ nípa ìdí tí kò fi yẹ ká máa gbéra ga . Graham wá bẹ̀rẹ̀ sí í fi Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yẹ ara rẹ̀ wò , ó sì rí i pé àfi kóun ṣàtúnṣe . Ó rí i pé ìgbéraga ni ò jẹ́ kóun gba ìbáwí táwọn alàgbà fún òun , ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í yíwà pa dà . Ó bẹ̀rẹ̀ sí í wá sípàdé déédéé , ó ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì dáadáa , kò sì fọ̀rọ̀ àdúrà ṣeré . Ó ní : ‘ Ọjọ́ pẹ́ tí mo ti wà nínú òtítọ́ , kódà mo ti ṣe aṣáájú - ọ̀nà rí . Àpọ́sítélì Pétérù sọ pé : “ Ẹ máa ṣe olùṣọ́ àgùntàn agbo Ọlọ́run tí ń bẹ lábẹ́ àbójútó yín , kì í ṣe lábẹ́ àfipáṣe , bí kò ṣe tinútinú ; bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nítorí ìfẹ́ fún èrè àbòsí , bí kò ṣe pẹ̀lú ìháragàgà ; bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe bí ẹní ń jẹ olúwa lé àwọn tí í ṣe ogún Ọlọ́run lórí , ṣùgbọ́n kí ẹ di àpẹẹrẹ fún agbo . ” Báwo làwọn òbí ṣe lè tọ́ àwọn ọmọ wọn dàgbà nínú ìbáwí Jèhófà ? ( Ka Hébérù 12 : ​ 5 - 11 . ) Báwo ni ọmọ kan ṣe lè mọ béèyàn ṣe ń kóra ẹ̀ níjàánu ? 4 , 5 . ( a ) Kí nìdí tí ìkóra - ẹni - níjàánu fi ṣe pàtàkì téèyàn bá máa gbé “ àkópọ̀ ìwà tuntun ” wọ̀ ? Kí ló máa jẹ́ kó rọrùn fún wa láti máa kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ? Arákùnrin kan sọ pé : “ Inú mi dùn gan - an fún bí àwọn òbí mi ṣe tọ́ mi . ( b ) Báwo ni ìgbọràn ṣe ṣe ìdílé kan láǹfààní ? Ní ọdún díẹ̀ lẹ́yìn ìyẹn , wọ́n gba ọmọ náà pa dà . ( b ) Báwo la ṣe lè mú kí iṣẹ́ àwọn alàgbà túbọ̀ rọrùn ? Wọn kì í kàn mí lábùkù tàbí bẹnu àtẹ́ lù mí , kàkà bẹ́ẹ̀ ṣe ni wọ́n ń gbé mi ró tí wọ́n sì ń fún mi lókun . Kò sí bí ọwọ́ àwọn alàgbà ṣe dí tó , tá a bá parí ìpàdé ó kéré tán ọ̀kan lára wọn máa wá béèrè àlàáfíà mi . Ṣe ló máa ń ṣe mí bíi pé Ọlọ́run ò lè nífẹ̀ẹ́ mi torí àwọn nǹkan tí mo ti ṣe sẹ́yìn . Léraléra ni Jèhófà ti lo àwọn ará inú ìjọ àtàwọn alàgbà láti jẹ́ kí n mọ̀ pé òun nífẹ̀ẹ́ mi gan - an . Mo gbà á ládùúrà pé kí n má fi Jèhófà sílẹ̀ láé . ” Bí ìwọ bá yíjú sí ṣíṣe rere , ara rẹ kò ha ní yá gágá bí ? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá yíjú sí ṣíṣe rere , ẹ̀ṣẹ̀ lúgọ sí ẹnu ọ̀nà , ìfàsí - ọkàn rẹ̀ sì wà fún ọ ; ní tìrẹ , ìwọ yóò ha sì kápá rẹ̀ bí ? ” Torí náà , ẹ jẹ́ ká ‘ fetí sí ìbáwí ká lè di ọlọ́gbọ́n . ’ Gbogbo èèyàn láyé ló fẹ́ túbọ̀ lómìnira . 15 Máa Fúnni Níṣìírí Bíi Ti Jèhófà 8 : 36 . ( Ka 1 Kíróníkà 29 : ​ 11 , 12 . ) Táwa èèyàn bá fẹ́ gbádùn àwọn nǹkan ‘ rere ’ yẹn , a gbọ́dọ̀ gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run ká sì máa ṣègbọràn sí i . Tá a bá ṣàìgbọràn , á jẹ́ pé àwa fúnra wa là ń pinnu ohun tó dáa àtohun tí kò dáa . ’ Ó ní : “ Bí ẹ bá dúró nínú ọ̀rọ̀ mi , ọmọ ẹ̀yìn mi ni ẹ̀yin jẹ́ ní ti tòótọ́ , ẹ ó sì mọ òtítọ́ , òtítọ́ yóò sì dá yín sílẹ̀ lómìnira . ” Kí nìdí tá a fi gbà pé òmìnira tí Jésù ṣèlérí ló máa jẹ́ ká ní “ òmìnira ní ti gidi ” ? ( Ka Róòmù 8 : ​ 1 , 2 , 20 , 21 . ) ( d ) Àwọn ìbéèrè wo la máa dáhùn ? ( Wo abẹ́ ÌFỌ̀RỌ̀WÁNILẸ́NUWÒ ÀTI ÌRÍRÍ > BÍ A ṢE Ń FARA DA ÀDÁNWÒ . ) Ohun gbogbo ni ó bófin mu ; ṣùgbọ́n kì í ṣe ohun gbogbo ní ń gbéni ró . ” Àpẹẹrẹ wo ni Nóà àti ìdílé rẹ̀ fi lélẹ̀ fún wa ? Àárín àwọn èèyàn tó ń hùwà ipá tí wọ́n sì ń ṣèṣekúṣe ni wọ́n gbé . Bíbélì sọ pé : ‘ Nóà ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Ọlọ́run ti pa láṣẹ fún un . Kí ni Jèhófà pa láṣẹ pé káwa ìránṣẹ́ rẹ̀ máa ṣe lónìí ? ( Ka Lúùkù 4 : ​ 18 , 19 . ) Mo ti wá túbọ̀ lóye ohun tó wà nínú Jákọ́bù 4 : 8 tó sọ pé : ‘ Ẹ sún mọ́ Ọlọ́run , yóò sì sún mọ́ yín . ’ Ọkàn mi balẹ̀ , mo ní ìtẹ́lọ́rùn , ohun tí mo sì fẹ́ gan - an nìyẹn . ” Tọkọtaya kan tó jẹ́ aṣáájú - ọ̀nà àkànṣe ń wàásù ní abúlé kan nítòsí ìlú Balykchy ( b ) Báwo ni Jèhófà ṣe fún Ọmọ rẹ̀ níṣìírí ? Báwo ni Hesekáyà ṣe fún àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ ogun rẹ̀ àti gbogbo èèyàn Júdà níṣìírí ? Báwo ni Pétérù ṣe ‘ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ lókun ’ ? Ṣùgbọ́n èmi ti rawọ́ ẹ̀bẹ̀ nítorí rẹ , kí ìgbàgbọ́ rẹ má bàa yẹ̀ ; àti ìwọ , ní gbàrà tí o bá ti padà , fún àwọn arákùnrin rẹ lókun . ” ​ — Lúùkù 22 : ​ 31 , 32 . Àwọn wo ló yẹ ká máa fún níṣìírí lónìí , kí sì nìdí ? Báwo làwọn alàgbà ṣe lè fúnni ní ìbáwí lọ́nà tó ń gbéni ró ? Ẹ̀yin òbí , ṣé ẹ̀ ń kọ́ àwọn ọmọ yín láti máa fún àwọn míì níṣìírí ? Mo wá rí i pé èmi nìkan kọ́ nirú ẹ̀ ń ṣẹlẹ̀ sí , èyí sì mára tù mí . ” Ọba Sólómọ́nì sọ pé : ‘ Ọ̀rọ̀ tí ó bọ́ sí àkókò mà dára o ! Ìtànyòò ojú tàbí ọ̀yàyà a máa mú kí ọkàn - àyà yọ̀ ; ìròyìn tí ó dára a máa mú àwọn egungun sanra . ’ Nítorí pé ìwọ , Jèhófà , ti mú kí n máa yọ̀ nítorí ìgbòkègbodò rẹ ; mo ń fi ìdùnnú ké jáde nítorí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ . ” Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ pé : “ Ọlọ́run kì í ṣe aláìṣòdodo tí yóò fi gbàgbé iṣẹ́ yín àti ìfẹ́ tí ẹ fi hàn fún orúkọ rẹ̀ . ” Kò sí bó o ṣe kéré tó , tí o ò lè ní àfojúsùn nínú ìjọsìn Ọlọ́run . Òwe 21 : 5 sọ pé : “ Àwọn ìwéwèé ẹni aláápọn máa ń yọrí sí àǹfààní . ” Tó o bá ti tètè pinnu ohun tó o fẹ́ fayé rẹ ṣe , ọwọ́ rẹ á tètè tẹ ohun tó ò ń lé . Lóòótọ́ tí mo bá kàwé tí mo sì di lọ́yà , màá lówó rẹpẹtẹ , àmọ́ bóyá ni màá rí iṣẹ́ àbọ̀ṣẹ́ . ” 17 , 18 . ( a ) Kí ni Jèhófà fẹ́ fáwọn ọ̀dọ́ ? Inú ilé pákó kan ni wọ́n bí mi sí nílùú kékeré kan tó ń jẹ́ Liberty , ìpínlẹ̀ Indiana lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà . Nígbà tó yá , màámi tún bí ọmọ mẹ́ta míì , ọkùnrin méjì àti obìnrin kan . MO RÁNTÍ pé lágbègbè wa , àwọn tá a jọ bẹ̀rẹ̀ ilé ìwé náà la jọ parí ẹ̀ . Àwọn oko kéékèèké ló wà nílùú wa , oko àgbàdo ló sì pọ̀ jù nínú wọn . Torí náà , wọ́n máa ń kó gbogbo wa lọ sí Ìjọ Onítẹ̀bọmi ní gbogbo ọjọ́ Sunday . Ni wọ́n bá rán mi lọ sí Noncommissioned Officers Academy , ìyẹn ilé ẹ̀kọ́ àwọn ológun kémi náà lè di ọ̀gá nínú iṣẹ́ ológun . Mo rántí pé nígbà kan tí mo bi màmá mi pé kí ni wọ́n mọ̀ nípa àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà , wọ́n kàn sọ fún mi pé , “ Ṣáwọn yẹn , bàbá arúgbó kan tó ń jẹ́ Jèhófà ni wọ́n ń sìn . ” Àmọ́ ní báyìí , mo ti wá mọ ẹni tí Jèhófà jẹ́ gan - an . Ọdún tó tẹ̀ lé e ni mo bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ aṣáájú - ọ̀nà , ìyẹn ní 1958 . Èmi àti Gloria ṣègbéyàwó ní February 1959 . Ọ̀pọ̀ iṣẹ́ tá a ṣe ló jẹ́ pé dọ́là mẹ́ta péré ni wọ́n ń san fún wa lóòjọ́ . Mo rántí ìgbà kan tá a dúró ra epo nílé epo kan . Láìka gbogbo ìṣòro yẹn sí , a gbádùn àkókò tá a lò pẹ̀lú àwọn ará , a sì gbádùn iṣẹ́ ìwàásù gan - an . Lẹ́sẹ̀ kan náà , mo bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ pẹ̀lú ọmọbìnrin wọn àti ọkọ rẹ̀ . Inú wa dùn pé ìyàwó arákùnrin yẹn àti ọmọbìnrin rẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ , wọ́n sì ṣèrìbọmi . A tún láwọn ọ̀rẹ́ àtàtà ní ìjọ táwọn aláwọ̀ funfun wà . Ìdí ni pé ẹgbẹ́ kan wà nígbà yẹn tí wọ́n ń pè ní Ku Klux Klan ( ìyẹn KKK ) , ẹgbẹ́ yìí ló ń ṣagbátẹrù kẹ́lẹ́yàmẹ̀yà , torí pé wọ́n kórìíra àwọn aláwọ̀ dúdú gan - an . Lọ́dún 1962 , ètò Ọlọ́run pè mí fún Ilé Ẹ̀kọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ nílùú South Lansing , New York . Àmọ́ , iléeṣẹ́ tẹlifóònù kan wà ní Pine Bluff tó fẹ́ gbà mí síṣẹ́ . Tí wọ́n bá gbà mí , èmi ni màá jẹ́ aláwọ̀ dúdú àkọ́kọ́ tí wọ́n máa gbà sílé iṣẹ́ náà . Mi ò lówó tí mo lè fi rìnrìn - àjò lọ sí New York . Arábìnrin náà sọ fún mi pé : “ Mo fẹ́ kó o lọ gbẹ̀kọ́ dáadáa nílé ẹ̀kọ́ yẹn , kó o lè pa dà wá kọ́ wa tó o bá dé ! ” Mo rántí pé àsìkò yẹn náà ni wọ́n sọ Arákùnrin Leon Weaver di alábòójútó àyíká , àmọ́ ní báyìí , òun ni olùṣekòkáárí Ìgbìmọ̀ Ẹ̀ka ní Bẹ́tẹ́lì tó wà lórílẹ̀ - èdè Amẹ́ríkà . Ẹ̀rù kọ́kọ́ bà mí nígbà tí wọ́n ní ká bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ yìí . Inú mi sì dùn pé Arákùnrin Thompson ni alábòójútó àgbègbè tí mo kọ́kọ́ bá ṣiṣẹ́ torí pé ẹni tẹ̀mí ni , mo sì kẹ́kọ̀ọ́ gan - an lára rẹ̀ . Nígbà yẹn lọ́hùn - ún , ìdálẹ́kọ̀ọ́ tí alábòójútó àyíká máa ń gbà kì í tó nǹkan . Mo rántí pé mo sọ fún Gloria pé , “ Ṣé kò lè dúró díẹ̀ ni ? ” Ìgbà kan tiẹ̀ wà tí ẹgbẹ́ KKK ṣe ìwọ́de ní àgbègbè kan tá à ń bẹ̀ wò ní ìpínlẹ̀ Tennessee . Oṣù tó tẹ̀ lé e la sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ . Gloria ṣeyebíye ju iyùn lọ nígbà tí mo fẹ́ ẹ , bó sì ṣe rí títí dòní nìyẹn Nígbà tó sì dọdún 1999 , mo láǹfààní di ọ̀kan lára Ìgbìmọ̀ Olùdarí . Aísáyà 32 : 17 sọ pé : “ Iṣẹ́ òdodo tòótọ́ yóò sì di àlàáfíà ; iṣẹ́ ìsìn òdodo tòótọ́ yóò sì di ìdákẹ́jẹ́ẹ́ àti ààbò fún àkókò tí ó lọ kánrin . ” Ìkejì , a gbọ́dọ̀ gbàdúrà pé kí Jèhófà fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ . Tá a bá ṣe ohun tí Jésù sọ yìí , a ò ní bá ẹnikẹ́ni fa wàhálà , ó sì ṣeé ṣe kí ẹni tí kò gbọ́ wa lónìí tẹ́tí sí wa lọ́jọ́ míì . Torí pé mo gbọ́ èdè ìbílẹ̀ yẹn , èdè yẹn gan - an ni mo fi kí i . Ó yà á lẹ́nu gan - an , ó wá bi mí pé , ‘ Kí lẹ wá ṣe ? ’ Mo wá sọ fún un pé mo fẹ́ rí Kọmíṣọ́nnà Àgbà . Ó pe ọ̀gá rẹ̀ lórí fóònù , ọ̀gá náà sì jáde wá kí mi kódà èdè ìbílẹ̀ rẹ̀ ló fi kí mi . Lẹ́yìn ìyẹn , ó fara balẹ̀ tẹ́tí sí mi , mo sì ṣàlàyé iṣẹ́ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà fún un . ” ‘ Ní ti èyíinì tí ó wà lórí erùpẹ̀ àtàtà , ìwọ̀nyí ni àwọn tí ó jẹ́ pé wọ́n so èso pẹ̀lú ìfaradà . ’ ​ — LÚÙKÙ 8 : 15 . Kí láá mú ká máa so èso pẹ̀lú ìfaradà ? ( Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí . ) ( b ) Kí ni Jésù sọ nípa iṣẹ́ ìwàásù ní “ ìpínlẹ̀ ìbí ” rẹ̀ ? Òmíì sọ pé : “ Àpẹẹrẹ wọn máa ń jẹ́ kémi náà lè fara dà á , kí n sì jẹ́ onígboyà lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ mi . ” Àwọn ìbéèrè mẹ́ta wo la máa dáhùn , kí sì nìdí ? Ka Jòhánù 15 : ​ 1 - 5 , 8 . Iṣẹ́ ìwàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run ni . Ka Lúùkù 8 : ​ 5 - 8 , 11 - 15 . Báwo la ṣe ń “ so èso pẹ̀lú ìfaradà ” ? Nítorí mo jẹ́rìí wọn pé wọ́n ní ìtara fún Ọlọ́run ; ṣùgbọ́n kì í ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ìmọ̀ pípéye . ” Nígbà tá a pa dà síbẹ̀ , àwọn tó ń kọjá béèrè pé , ‘ Kí ló ṣẹlẹ̀ ? Kí nìdí tó o fi pinnu pé wàá máa “ so èso pẹ̀lú ìfaradà ” ? 15 : 8 . ( Ka Jòhánù 15 : ​ 1 , 8 . ) Jésù sọ fáwọn àpọ́sítélì rẹ̀ pé : “ A yin Baba mi lógo nínú èyí , pé ẹ ń bá a nìṣó ní síso èso púpọ̀ . ” ( b ) Báwo ló ṣe rí lára rẹ pé o láǹfààní láti sọ orúkọ Ọlọ́run di mímọ́ ? ( a ) Kí ni Jòhánù 15 : ​ 9 , 10 sọ tó fi hàn pé ó yẹ ká máa wàásù ? Kí la gbọ́dọ̀ ṣe tá a bá fẹ́ dúró nínú ìfẹ́ Kristi ? Àpẹẹrẹ ẹnì kan tó ṣe bẹ́ẹ̀ ni Nóà tí Bíbélì pè ní “ oníwàásù . ” ( a ) Bó ṣe wà ní Mátíù 22 : ​ 39 , kí nìdí míì tá a fi ń wàásù ? 13 , 14 . ( a ) Ẹ̀bùn wo ni Jòhánù 15 : 11 mẹ́nu kàn ? ( a ) Ẹ̀bùn wo ni Jòhánù 14 : 27 mẹ́nu kàn ? ( a ) Ẹ̀bùn wo ni Jòhánù 15 : 15 mẹ́nu kàn ? ( b ) Kí ló yẹ káwọn àpọ́sítélì ṣe tí wọ́n bá fẹ́ máa jẹ́ ọ̀rẹ́ Jésù nìṣó ? ( Ka Jòhánù 15 : ​ 14 - 16 . ) Ó dá wa lójú pé Jèhófà máa dáhùn àwọn àdúrà wa ( Wo ìpínrọ̀ 18 ) Àpọ́sítélì Pétérù fi Sátánì Èṣù wé “ kìnnìún tí ń ké ramúramù , ” Jòhánù pè é ní “ ejò , ” ó sì tún pè é ní “ dírágónì . ” Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ wọn , a máa borí ọ̀tá wa . Àwọn tó gba irọ́ yìí gbọ́ máa ń fi ojoojúmọ́ ayé wọn lépa “ Ọrọ̀ ” dípò kí wọ́n máa ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run . Ó yẹ ká mọ ọ̀tá wa , àmọ́ kò sídìí tó fi yẹ ká bẹ̀rù rẹ̀ . Tá a bá kọjú ìjà sí Èṣù , ó dájú pé ó máa sá kúrò lọ́dọ̀ wa . Àwọn nǹkan wo ló para pọ̀ di ìhámọ́ra ogun tẹ̀mí tó yẹ ká gbé wọ̀ ? Àwọn òbí mi àtàwọn ọ̀rẹ́ mi sì fọkàn tán mi . ” Síbẹ̀ , àǹfààní tó o máa rí kì í ṣe kékeré , lára ẹ̀ ni pé : Wàá nígboyà , wàá túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà , àwọn tó nífẹ̀ẹ́ rẹ sì máa bọ̀wọ̀ fún ẹ . ” Abẹ́nú tí a fi òtítọ́ dì lámùrè ( Wo ìpínrọ̀ 3 - 5 ) Èyí mú kí n rẹ̀wẹ̀sì nígbà kan , mi ò sì mọ ohun tí màá ṣe . ” Àwọn ọmọléèwé mi kan bẹ̀rẹ̀ sí í lo oògùn olóró , àwọn míì sì fi iléèwé sílẹ̀ . Ó ní : “ Mo máa ń rán ara mi létí pé mò ń jẹ́ orúkọ mọ́ Jèhófà àti pé Sátánì ló ń lo àwọn ìdẹwò yẹn kó lè dẹkùn mú mi . Inú mi máa ń dùn gan - an tí mo bá ti borí ìdẹwò kan . ” Àwo ìgbàyà ti òdodo ( Wo paragraphs 6 - 8 ) Ìyẹn máa ń jẹ́ kí n mọ bí mo ṣe lè ràn wọ́n lọ́wọ́ . Ọ̀pọ̀ ìgbà ni mo máa ń sọ àwọn nǹkan táá ṣe wọ́n láǹfààní torí pé mo ti múra sílẹ̀ . ” Mo rí i dájú pé mo ti ka gbogbo àwọn ìtẹ̀jáde tí wọ́n ṣe fáwa ọ̀dọ́ . Èyí máa ń jẹ́ kí n lè lo Bíbélì tàbí àwọn àpilẹ̀kọ orí ìkànnì jw.org láti ran àwọn ẹgbẹ́ mi lọ́wọ́ . ” Ẹsẹ̀ tí ó wà ní ìmúratán ( Wo ìpínrọ̀ 9 - 11 ) Kí ni díẹ̀ lára àwọn “ ohun ọṣẹ́ oníná ” tí Sátánì máa ń lò ? Àmọ́ ní báyìí , mo máa ń múra ìpàdé sílẹ̀ dáadáa , mo sì máa ń sapá láti dáhùn lẹ́ẹ̀mejì tàbí ẹ̀ẹ̀mẹta . Kì í rọrùn fún mi , àmọ́ ara máa ń tù mí tí mo bá ṣe bẹ́ẹ̀ . Yàtọ̀ síyẹn , àwọn ará ò fi mí sílẹ̀ . Kí n sòótọ́ , gbogbo ìgbà tí mo bá lọ sípàdé ni mo máa ń rí i pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ mi . ” Apata ńlá ti ìgbàgbọ́ ( Wo ìpínrọ̀ 12 - 14 ) Àṣíborí ìgbàlà ( Wo ìpínrọ̀ 15 - 18 ) Mo ti rí i pé àwọn èèyàn máa ń fẹ́ gbọ́rọ̀ wa tí wọ́n bá rí i pé a lóye Bíbélì dáadáa , a sì fẹ́ ran àwọn lọ́wọ́ . ” Idà ẹ̀mí ( Wo ìpínrọ̀ 19 - 20 ) Ó dájú pé lọ́lá ìtìlẹ́yìn Jèhófà , a máa dúró gbọin - in , Èṣù ò sì ní rí wa gbé ṣe .